< Езекил 7 >

1 При това, Господното слово дойде към мене и казваше:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 А ти, сине човешки, слушай. Така казва Господ Иеова към Израилевата земя: Край! краят дойде На четирите краища на страната.
“Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
3 Сега е дошъл краят върху тебе; Защото ще изпратя гнева Си върху тебе, Ще те съдя според постъпките ти, И ще възвърна върху тебе всичките ти мерзости.
Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
4 Окото ми не ще те пощади, Нито ще ти покажа милост; Но ще възвърна върху тебе постъпките ти, И въздаянията ти за твоите мерзости ще бъдат всред тебе; И ще познаете, че Аз съм Господ.
Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
5 Така казва Господ Бог Иеова: Зло, едно небивало зло, ето, иде;
“Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
6 Краят дойде, краят дойде, Бди против тебе; ето, настъпи.
Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
7 Присъдата ти дойде върху тебе, който живееш в тая земя; Времето дойде, денят наближи, Ден на смущение по планините, а не на възклицание.
Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
8 Сега скоро ще излея върху тебе яростта Си, И ще изчерпя гнева Си върху тебе; Ще те съдя според постъпките ти, И ще възвърна върху тебе всичките ти мерзости,
Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
9 Окото Ми няма да пощади, Нито ще покажа милост; Ще ти въздам според постъпките ти, И въздаянията за твоите мерзости ще бъдат всред тебе; И вие ще познаете, че Аз, Който ви поразявам, съм Господ.
Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
10 Ето, денят, ето, иде! Твоята присъда се яви! Жезълът се разцъфтя, гордостта поникна!
“‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
11 Насилието порасна в тояга за беззаконието им; Нищо не ще остане от тях, Нито от това множество, Нито от имота им; И няма да остане великолепие между тях.
Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
12 Времето дойде, денят наближи; Който купува, да се не радва; И който продава, да не жали; Защото има гняв върху цялото това множество.
Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
13 Защото продавачът няма да притежава наново продаденото от него, Ако и да е останал жив; Понеже видението относно цялото това множество няма да се отмени, Нито ще утвърди някой себе си Чрез беззаконния си живот.
Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
14 Затръбиха и приготвиха всичко, Но никой не отива на боя; Защото Моят гняв е върху цялото това множество.
“‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
15 Ножът е вън, а морът и гладът вътре; Който е на нивата ще умре от нож; А който е в града, глад и мор ще го погълнат.
Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
16 А ония от тях, които избягнат, като се избавят Ще бъдат по планините като гълъбите по долините, Всичките плачещи, всеки за беззаконието си.
Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
17 Всички ръце ще ослабват, И всички колена ще станат като вода.
Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
18 Ще се препашат с вретище, И ужас ще ги покрие; Срам ще има по лицата на всичките, И плешивост по главите на всички тях.
Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
19 Среброто си ще хвърлят по улиците, И златото им ще им бъде като нечисто нещо; Среброто и златото им не ще могат да ги избавят В деня на гнева Господен; Те няма да наситят душите си, нито да напълнят червата си; Защото о тях се спънаха и паднаха в беззаконието си.
“‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
20 Господ постави славното Си украшение, за да се гордеят с него; Но те направиха в него образите на своите мерзости, На омразните си идоли; Затова, Аз го обръщам в нещо нечисто за тях.
Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
21 Ще го предам в ръцете на чужденци за плячка, И на нечестивите на земята за корист; И те ще го омърсят;
Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
22 И като отвърна лицето Си от тях, Те ще омърсят светилището Ми, И грабители ще влязат в него и ще го омърсят.
Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
23 Направи верига; Защото земята е пълна с кървави престъпления, И градът е пълен с насилие.
“‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
24 Затова, ще докарам най-злите от народите, И те ще се завладеят къщите им; Ще направя да престане и гордостта на силните; И светите им места ще се омърсят.
Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
25 Погибел иде; Ще потърсят мир, но не ще има.
Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
26 Бедствие след бедствие ще дохожда, И слух след слух ще пристига; Тогава ще поискат видение от пророк; Но поуката ще се изгуби от свещеника, И съветът от старейшините.
Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
27 Царят ще жалее, Първенецът ще се облече в смайване, И ръцете на людете на страната ще ослабват. Според постъпките им ще им направя, И според заслужването им ще ги съдя; И ще познаят, че Аз съм Господ.
Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”

< Езекил 7 >