< Езекил 31 >
1 И в единадесетата година, в третия месец, на първия ден от месеца, Господното слово дойде към мене и рече:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Сине човешки, кажи на египетския цар Фараона и на множеството му: На кого си се уподобил ти във величието си?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Ето, асириецът бе кедър в Ливан, с хубави клонове, с дебела сянка, и с висок ръст; и върхът му бе всред гъсти клончета.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Водите го хранеха, бездната го отрастваше с реките си, които течеха около посаждението му; и изпращаше каналите си по всичките дървета на полето.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Затова, ръстът му се издигна над всичките дървета на полето, клоновете му се умножиха, и като растеше клончетата му се разпростряха поради изобилните води.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Всичките небесни птици правеха гнезда в клончетата му; и всичките полски животни раждаха под клоновете му; а под сянката му живееха всичките големи народи.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Така бе красив по големината си и по дължината на клоновете си; защото корените му бяха при много води.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Кедрите в Божията градина не можеха да го скрият; елхите не се сравняваха с клоновете му, и яровите не приличаха на клончетата му; никакво дърво в Божията градина не се сравняваше с него по красотата му.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Направих го красив с многото му клонове; тъй щото всичките едемски дървета, които бяха в Божията градина, му завиждаха.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 Затова, така казва Господ Иеова: Понеже ти си се издигнал високо, и понеже си дигнал върха си между гъстите клончета, и сърцето му се надигна поради височината му,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 затова, ще го предам в ръката на силния от народите, който непременно ще се разправи с него; изпъдих го поради нечестието му.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 Чужденци, страшните между народите, отсякоха го и го оставиха; клончетата му паднаха по планините и по всичките долини, и клоновете му се строшиха по всичките потоци на земята; и всичките народи на света слязоха от сянката му и го оставиха.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 На трупа му ще си починат всичките небесни птици, и върху клоновете му ще бъдат всичките животни от полето,
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 за да не се възвиси във височината си никое от дърветата край водите, нито да издигне върха си между гъстите клончета, и за да се не надигат поради височината си, техните великани, да! всички, които се поят с вода; защото те всички са предадени на смърт, подобно на всички други човешки синове, с ония, които слизат в ямата.
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Така казва Господ Иеова: В деня, когато той слезе в преизподнята причиних жалеене; покрих бездната за него, и направих да престанат реките й, така щото големите води се спряха; и направих да жалее за него Ливан, и всичките дървета на полето повяхнаха за него. (Sheol )
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol )
16 Направих народите да потреперят при шума на падането му, когато го свалих в преизподнята с ония, които слизат в ямата; и всичките едемски дървета, отбраните и добрите ливански дървета, всичките пиещи води, се утешиха в най-дълбоките места на света. (Sheol )
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol )
17 И те и ония, които бяха негова мишца, които живееха под сянката му всред народите, слязоха в преизподнята подобно на него, при убитите от нож. (Sheol )
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol )
18 На кого си се уподобил така по слава и по величие между едемските дървета? При все това, ще бъдеш свален, както всичките други едемски дървета, в най-дълбоките места на света; ще лежиш всред необрязаните, с убитите от нож. Тъй ще стане с Фараона и цялото му множество, казва Господ Иеова.
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”