< Езекил 29 >

1 В десетата година, в десетия месец, на дванадесетия ден от месеца, Господното слово дойде към мене и рече:
Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Сине човешки, насочи лицето си против египетския цар Фараона, и пророкувай против него и против целия Египет.
“Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
3 Говори и речи: Така казва Господ Иеова: Ето, Аз съм против тебе, Фараоне египетски царю, великото чудовище, което лежиш всред реките си, което си рекло: Реката ми е моя; аз я направих за себе си.
Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
4 Аз ще туря въдици в челюстите ти, и рибите в реките ти ще прилепя за люспите ти; и ще те извлека изсред реките ти с всичките риби в реките ти, прилепнали при люспите ти.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
5 И ще те изхвърля в пустинята, тебе и всичките риби в реките ти; ще паднеш на отвореното поле; не ще се събереш нито прибереш; дадох те на земните зверове и на небесните птици за храна.
Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
6 И всичките египетски жители ще познаят, че Аз съм Господ; защото бяха жезъл от тръстика за Израилевия дом.
Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
7 Когато те взеха в ръка, ти се счупи, и промуши рамото на всички тях; и когато се облегнаха на тебе, ти се сломи и разклати кръста на всички тях.
Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
8 Затова, така казва Господ Иеова: Ето, ще докарам меч върху тебе, и ще отсека от тебе и човек и животно.
“‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
9 И Египетската земя ще бъде опустошена и пуста; и ще познаят, че Аз съм Господ, защото рече: Реката е моя, и аз я направих.
Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
10 Затова, ето, Аз съм против тебе и против реката ти; и ще обърна Египетската земя на пустота, разорение и опустошение, от Мигдол до Сиина и до границата на Етиопия.
nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
11 Човешка нога не ще да мине през нея, нито нога на животно ще мине през нея, нито ще бъде населена за четиридесет години.
Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
12 И ще обърна Египетската земя на пустиня между опустошените страни, и градовете й ще бъдат пусти за четиридесет години между разорените градове; и ще разсея Египтяните между народите и ще ги разпръсна по страните.
Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
13 Но така казва Господ Иеова: На края на четиридесетте години ще събера Египтяните от племената, между които бяха разпръснати;
“‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
14 и ще доведа Египетските пленници, ще ги върна в земята Патрос, в родната земя, и ще бъдат там унижено царство.
Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
15 Ще бъде най-униженото царство от царствата, и няма да се издигне вече над народите; защото ще ги намаля, за да не владеят вече над народите.
Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
16 На Египет не ще уповае вече Израилевият дом, щото да му напомня беззаконието, когато погледнат към тях за помощ; и те ще познаят, че Аз съм Господ Иеова.
Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
17 И в двадесет и седмата година, в първия месец, на първия ден от месеца, Господното слово дойде към мене и рече:
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 Сине човешки, вавилонският цар Навуходоносор накара войската си да извърши една толкова голяма работа против Тир, щото всяка глава стана плешива и всяко рамо ожулено; но пак не получи заплатата за Тир, ни той, нито войската му, за работата, която извърши против него.
“Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
19 Затова, така казва Господ Иеова: Ето, Аз давам Египетската земя на Вавилонския цар Навуходоносора; той ще откара многото й население, ще я обере, и ще вземе користи от нея; и това ще бъде заплатата на войската му.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
20 Дадох му Египетската земя срещу труда, който положи; понеже се трудиха за Мене, казва Господ Иеова.
Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 В оня ден ще направя да израсте рог на Израилевия дом, и ще ти дам да отвориш уста всред тях; и ще познаят, че Аз съм Господ.
“Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Езекил 29 >