< Езекил 23 >
1 Господното слово пак дойде към мене и рече:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Сине човешки, имаше две жени, дъщери на една майка.
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Те блудствуваха в младостта си; там бяха налягани гърдите им, и там бяха стискани девствените им съсци.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Имената им бяха Оола на по-голямата, и Оолива на сестра й; и те станаха Мои, и родиха синове и дъщери. А колкото за имената им, Оола е Самария, а Оолива Ерусалим.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Но когато беше Моя Оола блудствува, и залудя за любовниците си, съседите си асирийците,
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 синьо облечени управители и началници, всички привлекателни младежи, конници възсядали на коне.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 И тя извърши блудствата си с тях, с всичките най-отбрани между асирийците; и за които да било залудяваше, с всички техни идоли тя се оскверни.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 И тя не остави блудството си научено от Египет; защото лежеха с нея в младостта й, изтискаха девствените й съсци, и изливаха върху нея блудството си.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 Затова, предадох я в ръцете на любовниците й, в ръцете на асирийците, за които залудяваше.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 Те откриваха голотата й; откараха синовете и дъщерите й, а нея убиха с меч; и тя стана за посмешище между жените, защото извършиха съдби над нея.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 А когато сестра й Оолива видя това, в полудата си разврати се повече от нея, и в блудствата си надмина блудствата на сестра си.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Залудя за съседите си асирийците светло облечени управители и началници, конници, възсядали на коне, всички привлекателни младежи.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 И видях, че тя се оскверни; и двете тръгнаха в един път.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Тя даже притури на блудствата си; защото щом видя мъже изрисувани на стената, изрисувани с киновар образи на халдейци,
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 опасани с пояси около кръста си, носещи шарени гъжви на главите си, и всички с княжески изглед, прилични на вавилоняните от Халдейската земя, родината им,
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 щом ги видя, тя залудя за тях, и изпрати посланици при тях в Халдея.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 И вавилоняните дойдоха при нея в любовното легло и я оскверниха с блудството си; тя се оскверни с тях; и душата й се отврати от тях.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Така тя още откриваше блудствата си, откриваше голотата си; тогава душата Ми се отврати от нея, както беше се отвратила душата Ми от сестра й.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 При все това, тя блудствуваше още повече, като си спомняше за дните на младостта си, когато блудствуваше в Египетската земя.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 И залудя за любовниците си измежду тях, чиято плът е като плътта на осли, и семеизливането им като семеизливане на коне.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Така ти си ламтяла за невъздържаността на младостта си, когато гърдите ти се налягаха от Египтяните заради младите ти съсци.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 Затова, Ооливо, така казва Господ Иеова: Ето, Аз ще подигна любовниците ти против тебе, от които се е отвратила душата ти, и ще ги докарам против тебе от всякъде;
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 вавилоняните и всичките халдейци, Фекод и Сое и Кое, и с тях всичките асирийци, - всички привлекателни младежи, управители и началници, пълководци и именити, всички възсядали на коне.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 Те ще дойдат против тебе с оръжия и с колесници, с коли и с много племена, и ще се опълчат против тебе от всяка страна с щитове, щитчета и шлемове; и Аз ще им поверя съдба, и те ще съдят според своите съдби.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 И като насоча против тебе ревнивостта Си, те ще постъпят с тебе яростно, ще отрежат носа ти и ушите ти; и останалите от тебе ще паднат от нож; те ще хванат синовете ти и дъщерите ти; и останалите от тях между тебе ще бъдат поядени от огън.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 Ще съблекат и дрехите ти, и ще отнемат лъскавите ти накити.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Така ще направя да престане твоят разврат, и блудството ти, научено от Египетската земя; ти няма вече да подигнеш очи към тях, нито ще си наумиш вече за Египет;
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 Защото така казва Господ Иеова: Ето, ще те предам в ръката на ония, които мразиш, в ръката на ония, от които се е отвратила душата ти.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 Те ще постъпят с омраза към небе, и като отнемат всичките ти трудове, ще те оставят гола и непокрита; и голотата на блудствата ти ще се открие, както разврата ти тъй и блудствата ти.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 Това ще ти се направи понеже си блудствувала всред езичниците, и понеже си се осквернила с идолите им.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Така си ходила в пътя на сестра си; затова ще дам в ръката ти нейната чаша.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Така казва Господ Иеова: Ще изпиеш дълбоката и широка чаша на сестра си; ще бъдеш за присмех и поругание повече, отколкото можеш да понесеш.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Ще се изпълниш с пиянство и скръб, с чашата на смайването и на запустението, с чашата на сестра си Самария.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Ще я изпиеш и изцедиш, ще гризеш черепките й, и ще разкъсаш гърдите си; защото Аз го изрекох, казва Господ Иеова;
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Затова, така казва Господ Иеова: Понеже си Ме забравила, и си Ме отхвърлила зад гърба си; затова понеси и ти възмездието на разврата си и блудствата си.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 При това, Господ ми рече: Сине човешки, ще се застъпиш ли за Оола и Оолива? Тогава изяви им мерзостите им,
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 че прелюбодействуваха, че има кръв в ръцете им, да! че прелюбодействуваха с идолите си, и че, за да бъдат изядени от тях, превеждаха през огън чадата, които Ми родиха;
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 още че това Ми сториха, - в същия ден оскверниха светилището Ми и омърсиха съботите Ми;
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 защото когато бяха заклали чадата си на идолите си, тогава в същия ден влизаха в светилището Ми, та го омърсиха; и, ето, така струваха всред дома Ми.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 И още пратихте за мъже да дойдат от далеч, до които като се проводи пратеник, ето, дойдоха; и за тях си се окъпала, вапсала си очите си, и украсила си се с накити,
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 седнала си на великолепна постелка, с трапеза приготвена пред нея, и на нея си положила Моя темян и Моето масло.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 И чуваха се гласове на едно множество, което живееше безгрижно при нея; и заедно с мъжете от простолюдието се въвеждаха пияници из пустинята; и туриха гривни на ръцете на тия две жени, и красиви венци на главите им.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Тогава рекох за престарялата в прелюбодействува: Сега ли ще блудствуват с нея, дори с нея!
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 И те влизаха при нея както влизат при блудница; така влизаха при тия невъздържани жени, при Оола и при Оолива.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 Затова, справедливи мъже ще ги съдят както съдят прелюбодейците и както съдят жени, които проливат кръв; защото те са прелюбодейци, и има кръв в ръцете им.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 Защото така казва Господ Иеова: Ще доведа множество против тях, и ще ги предам да бъдат тласкани и разграбени.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 Множеството ще ги убие с камъни, и ще ги съсече със сабите си; ще избият синовете им и дъщерите, и ще изгорят къщите им с огън.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Така ще направя да престане разврата от земята, за да се научат всичките жени да не вършат разврат като вашия.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 И ще въздадат върху вас развратните ви дела; и ще понасяте възмездието на греховете, извършени с идолите си; и ще познаете, че Аз съм Господ Иеова.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”