< Езекил 20 >

1 А в седмата година, в петия месец, на десетия ден от месеца, някои от Израилевите старейшини дойдоха да се допитат до Господа, и седнаха пред мене.
Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
2 И Господното слово дойде към мене и рече:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
3 Сине човешки, говори на Израилевите старейшини и кажи им: Така казва Господ Иеова: Да се допитате до Мене ли сте дошли? Заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, не приемам да се допитате до мене.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
4 Ще се застъпиш ли за тях, сине човешки? ще се застъпиш ли за тях? Покажи им мерзостите на техните бащи, като им речеш:
“Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
5 Така казва Господ Иеова: В деня, когато избрах Израиля, и се заклех към рода на Якововия дом, и им се открих в Египетската земя, и им се заклех като рекох: Аз съм Господ вашият Бог,
kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
6 в оня ден заклех им се, че ще ги изведа из Египетската земя и ще ги доведа в земя, която бях промислил за тях, земя дето тече мляко и мед, с която се хвалят всички страни.
Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
7 И рекох им: Отхвърлете всеки мерзостите, които е поставил пред очите си, и не се осквернявайте с египетските идоли; Аз съм Господ вашият Бог.
Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
8 Те обаче въстанаха против Мене и не искаха да Ме послушат; не отхвърлиха всеки мерзостите, които бе поставил пред очите си, нито оставиха египетските идоли. Тогава рекох да излея яростта Си върху тях, за да изчерпя гнева Си против тях всред Египетската земя.
“‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 Но подействувах заради името Си, да се не оскверни то пред народите, между които бяха, и пред които им се открих като ги изведох из Египетската земя,
Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Затова като ги изведох из Египетската земя, заведох ги в пустинята.
Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
11 И дадох им повеленията Си и започнах ги със съдбите Си, които като извършва човек ще живее чрез тях.
Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
12 Дадох им и съботите Си да бъдат знак между Мене и тях, за да познаят, че Аз Господ ги освещавам.
Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
13 Но Израилевият дом въстана против Мене в пустинята; не ходиха в повеленията Ми, но отхвърлиха съдбите Ми, които като извършва човек ще живее чрез тях, и твърде много оскверниха съботите Ми. Тогава рекох да излея яростта Си върху тях в пустинята, за да ги изтребя.
“‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
14 Но подействувах заради името Си, да се не оскверни то пред народите, пред които бях ги извел.
Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
15 При това, Аз им се заклех в пустинята, че не ще ги заведа в земята, която им бях дал, земя, гдето тече мляко и мед, с която се хвалят всичките страни,
Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
16 защото отхвърлиха съдбите Ми, не ходиха в повеленията Ми, и оскверниха съботите Ми; понеже сърцата им отиваха след идолите им.
Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
17 Обаче, окото Ми ги пощади, та не ги изтребих, нито ги довърших в пустинята.
Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
18 И рекох на чадата им в пустинята: Не ходете по повеленията на бащите си, нито се осквернявайте с идолите им.
Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
19 Аз съм Господ вашият Бог; в Моите повеления ходете, и Моите съдби пазете и извършвайте ги;
Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
20 освещавайте още и съботите Ми, и нека бъдат знак между Мене и вас, за да познаете, че Аз Господ съм ваш Бог.
Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
21 Обаче, чадата въстанаха против Мене; не ходиха в повеленията ми, нито опазиха съдбите ми да ги вършат, които ако извършва човек, ще живее чрез тях, и оскверниха съботите Ми. Тогава рекох да излея яростта Си върху тях, за да изчерпя гнева Си против тях в пустинята.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
22 Но оттеглих ръката Си, и подействувах заради името Си, да се не оскверни то пред народите, пред които ги бях извел.
Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
23 При това, Аз им се заклех в пустинята, че ще ги разпръсна между народите, и ще ги разсея по разни страни,
Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
24 защото не извършиха съдбите Ми, но отхвърлиха повеленията Ми, оскверниха съботите Ми, и очите им бяха към идолите на бащите им.
nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
25 Затова, и Аз им дадох повеления, които не бяха добри, и съдби, чрез които не щяха да живеят,
Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
26 и оставих ги да се осквернят в приносите си, дето превеждаха през огън всяко първородно, за да ги запустя, та да познаят, че Аз съм Господ.
mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
27 Затова, сине човешки, говори на Израилевия дом, като им речеш: Така казва Господ Иеова: Още и в това Ме охулиха бащите ви, дето вършиха престъпления против Мене.
“Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
28 Защото, като ги доведох в земята, която бях се заклел да им дам, тогава разгледаха всеки висок хълм и всяко сенчесто дърво, и там принасяха жертвите си, там представяха оскърбителните си приноси, там полагаха благоуханията си, и там изливаха възлиянията си.
Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
29 Тогава им рекох: Що е това високо място, на което отивате, та да се нарича Вама и до днес?
Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
30 Затова, кажи на Израилевия дом - Така казва Господ Иеова: Като се осквернявате по примера на бащите си, и блудствувате с мерзостите им,
“Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
31 и до днес се осквернявате с всичките си идоли, като принасяте даровете си и превеждате синовете си през огъня, то до Мене ли ще се допитате, доме Израилев? Заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, не приемам да се допитате до Мене.
Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
32 И онова, което размишлявате, никак няма да се сбъдне, дето казвате: Ще станем като народите, като племената на другите страни; ще служим на дървета и на камъни.
“‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
33 Заклевам се в живота Си, казва Господ Иеова, непременно с мощна ръка, с издигната мишца, и с излеяна ярост ще царувам над вас.
Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
34 Като ви изведа измежду племената, и ви събера от страните, в които сте разпръснати с мощна ръка, с издигната мишца, и с излеяна ярост,
Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
35 ще ви заведа в пустинята на заточение между племената, и там ще се съдя с вас лице с лице.
Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
36 Както се съдих с бащите ви в пустинята на Египетската земя, така ще се съдя с вас, казва Господ Иеова.
Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
37 Ще ви прекарам под жезъла и ще ви заведа във връзките на завета.
Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
38 И ще изчистя отсред вас бунтовниците и ония, които вършат престъпления против Мене; ще ги извадя из земята, гдето пришелствуват; но те няма да влязат в Израилевата земя; и ще познаете, че Аз съм Господ.
Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
39 А вие, доме Израилев, така казва Господ Иеова: Ако не искате да слушате Мене, идете, служете и за напред всеки на идолите си; но не осквернявайте вече светото Ми име с даровете си и с идолите си.
“‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
40 Защото на Моя свят хълм, на Израилевия висок хълм, казва Господ Иеова, там целият Израилев дом, всичките в страната, ще Ми служат; там ще ги приема, и там ще поискам приносите ви и първаците на даровете ви, както и всичките ви свети неща.
Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
41 Ще ви приема като благоухание, когато ви изведа изсред племената и ви събера от страните, в които бяхте пръснати; и ще се осветя във вас пред народите.
Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
42 И ще познаете, че Аз съм Господ, когато ви доведа в Израилевата земя, в страната, която се заклех да дам на бащите ви.
Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
43 Там ще си спомните за постъпките си, и за всичките си дела, в които се осквернихте; и ще се погнусите сами от себе си поради всичките злини, които сторихте.
Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
44 И ще познаете, че Аз съм Господ, когато така постъпя с вас заради името Си, а не според злите ви постъпки нито според развратните ви дела, доме Израилев, казва Господ Иеова.
Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
45 И Господното слово дойде към мене и рече:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
46 Сине човешки, насочи лицето си към юг и направи да капне словото ти към юг и пророкувай против леса на южното поле.
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
47 Кажи на южния лес: Слушай Господното слово. Така казва Господ Иеова: Ето, Аз ще запаля огън в тебе, който ще изяде всяка зелено дърво в тебе, и всяко сухо дърво; пламтящият пламък не ще угасне, а от него ще изгори цялата повърхност от юг до север.
Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
48 Всяка твар ще види, че Аз Господ го запалих; няма да угасне.
Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
49 Тогава рекох: Горко, Господи Иеова! Те казват за мене: Този не говори ли притчи?
Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”

< Езекил 20 >