< Езекил 11 >
1 При това духът ме дигна та ме отнесе на източната порта на Господния дом, която гледа към изток; и ето във входа на портата двадесет и пет мъже, между които видях Яазания Азуровия син и Фелатия Венаиевия син, първенци между людете.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 И Господ ми реч: Сине човешки, тия са мъжете, които измислюват неправда, и които дават нечестив съвет в тоя град, като казват:
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 Времето не е близо да съградим къщи; тоя град е котел, а ние месо.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Затова, пророкувай против тях, пророкувай, сине човешки.
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 И Господният Дух слетя върху мене и рече ми: Говори. Така казва Господ: Това е що сте рекли, доме Израилев; Защото Аз зная размишленията на духа ви.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Убихте мнозина в тоя град, И напълнихте улиците му със заклани.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Затова, така казва Господ Иеова: Избитите от вас, които постлахте всред него, Те са месо, а тоя град е котел; Обаче Аз ще ви извадя изсред него.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 От ножа се боехте; И нож ще докарам върху вас, казва Господ Иова.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Ще ви извадя изсред града, И ще ви предам в ръцете на чужденци, И ще извърша съдби всред вас.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 От меч ще паднете; В Израилевите предели ще ви съдя; И ще познаете, че Аз съм Господ.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 Тоя град не ще ви бъде котел, Нито ще бъдете вие месо всред него; В Израилевите предели ще ви съдя;
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 И ще познаете, че Аз съм Господ; Понеже не ходихте в повеленията Ми, Нито извършихте съдбите Ми, Но постъпвахте според постановленията на околните вам народи.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 А като пророкувах, Фелатия Венаиевия син умря. Тогава паднах на лицето си, и като извиках с висок глас, рекох: Горко, Господи Иеова! ще довършиш ли Ти останалите от Израиля?
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 И Господното слово дойде към мене и рече:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 Сине човешки, братята ти, да! твоите братя, сродните ти мъже, и целият Израилев дом, те всички са ония, на които Ерусалимските жители рекоха: Отдалечете се от Господа; нам се даде тая земя за владение.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 Затова речи: Така казва Господ Иеова: Понеже ги преместих далеч между народите, И понеже ги разпръснах по разни страни, И съм бил на тях за малко време светилище В страните гдето са отишли,
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 Затова речи: Така казва Господ Иеова: Ще ви събера от народите, Ще ви прибера от страните гдето сте разпръснати, И ще ви дам Израилевата земя.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 И като дойдат там, Ще махнат от нея всичките й гнусотии И всичките й мерзости.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 Аз ще им дам едно сърце, И ще вложа вътре във вас нов дух; И като отнема каменното сърце от плътта им, Ще им дам крехко сърце,
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 За да ходят в повеленията Ми, И да пазят наредбите Ми и да ги вършат. И те ще бъдат Мои люде, и Аз ще бъда техен Бог.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 А колкото за ония, чието сърце постъпва По гнусните им и мерзостни желания, Ще възвърна постъпките им върху главите им, Казва Господ Иеова.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 Тогава херувимите подигнаха крилата си, и колелата се издигнаха край тях; и славата на Израилевия Бог бе отгоре им.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 И Господната слава се издигна изсред града та застана на хълма, който е на изток от града.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 И Духът като ме издигна отнесе ме чрез видение, с Божия Дух, в Халдейската земя, при пленниците. Тогава видението, което бях видял, си отиде от мене.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 После, казах на пленниците всичките думи, които Господ беше ми показал.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.