< Второзаконие 9 >
1 Слушай, Израилю; днес ти преминаваш да завладееш народи по-големи и по-силни от тебе, градове големи и укрепени до небето,
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 люде велики и високи, Енаковите потомци, които познаваш, и за които си слушал да се казва: Кой може да устои пред Енаковите потомци?
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 Знай, прочее, днес, че Иеова твоят Бог е, Който върви пред тебе; като огън пояждащ Той ще ги изтреби и ще ги свали пред тебе; така ще ги изгониш и скоро ще ги погубиш, според както Господ ти каза.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 А след като Господ твоят Бог ще ги е изгонил от пред тебе, да не говориш в сърцето си като казваш: Поради моята правда ме въведе Господ да завладея тая земя; защото поради нечестието на тия народи Господ ги изгонва от пред тебе.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Не поради твоята правда, нито поради правдата на твоето сърце, влизаш ти да притежаваш земята им; но поради нечестието на тия народи Господ твоят Бог ги изгонва от пред тебе и за да утвърди думата, за която Господ се е клел на бащите ти, на Авраама, Исаака и Якова.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Знай, прочее, че Господ твоят Бог не ти дава да притежаваш тая добра земя поради твоята правда; защото сте коравовратни люде.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Помни и да не забравиш, колко си раздразнявал Господа твоя Бог в пустинята; от деня, когато излязохте из Египетската земя, догдето стигнахте на това място, вие сте били непокорни Господу.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 А на Хорив раздразнихте Господа; и Господ, като се разгневи на вас, щеше да ви изтреби.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Когато се качих на планината, за да взема каменните плочи, плочите на завета, който Господ направи с вас, тогава преседях на планината четиридесет дена и четиридесет нощи, без да ям или да пия вода.
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 И Господ ми даде две каменни плочи, написани с Божия пръст; всичките думи, които Господ ви изговори на планината изсред огъня, в деня, когато се събрахте там, бяха написани на тях.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 (В края на четиридесетте дена и четиридесетте нощи Господ ми даде двете каменни плочи, плочите на завета).
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 А Господ ми рече: Стани, слез скоро от тук; защото твоите люде, които ти изведе из Египет, се развратиха, скоро се отклониха от пътя, който им зоповядах; направиха си изваян идол.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Господ още ми говори, казвайки: Видях тия люде, и, ето, те са коравовратни люде;
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 остави Ме, за да ги изтребя и да излича името им под небето, а тебе ще направя народ по-силен и по-голям от тях.
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 И тъй, като се обърнах слязох от планината; а планината гореше в огън, и двете плочи на завета бяха в двете ми ръце.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 Погледнах, и, ето, бяхте съгрешили против Господа вашия Бог, бяхте си направили излеяно теле, бяхте се отклонили скоро от пътя, който Господ беше ви заповядал.
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Тогава взех двете плочи та ги хвърлих из двете си ръце, и ги строших пред очите ви.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 После припаднах пред Господа, както първия път, четиридесет дена и четиридесет нощи; хляб не ядох и вода не пих поради всичкия грях, чрез който съгрешихте като извършихте зло пред Господа та Го раздразнихте.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Защото се уплаших от гнева и яростта, с които Господ се беше разгневил на вас да ви изтреби. Но тоя път Господ ме послуша.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Господ много се разгневи и на Аарона, когото щеше да погуби; но аз същевременно се помолих и за Аарона.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 И взех гнева ви, телето, което направихте, изгорих го с огън, счуках го и го стрих догде стана ситно като прах; и хвърлих праха му в потока, който тече от планината.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 Също в Тавера, в Маса и в Киврот-атаава разгневихте Господа.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 После, когато Господ ви изпрати от Кадис-варни и рече: Вървете наред та завладейте земята, която ви давам, тогава вие не се покорихте на заповедта на Господа вашия Бог, и не Му повярвахте, нито послушахте гласа Му.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 От първия ден, откак ви познавам, вие сте били непокорни Господу.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 И тъй, припадах пред Господа през ония четиридесет дена и четиридесет нощи, през които бях припаднал; защото Господ възнамеряваше да ви изтреби.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 Молех се Господу, както казвах: Господи Иеова, не изтребвай людете Си и наследството, което си изкупил с величието Си и което си извел из Египет със силна ръка.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Спомни слугите си Авраама, Исаака и Якова; не се взирай в упоритостта на тия люде, нито в нечестието им, нито в греха им,
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 да не би да рекат жителите на земята, из която си ни извел: Понеже Господ не можа да ги въведе в земята, която им бе обещал и понеже ги мразеше, за това ги изведе да ги погуби в пустинята.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 А пък те са Твои люде и Твое наследство, които си извел с голямата Си сила и с издигнатата Си мишца.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”