< Второзаконие 7 >
1 Когато Господ твоят Бог те въведе в земята, в която отиваш да я притежаваш, и изгони много народи от пред тебе, хетейците, гергесейците, аморейците, ханаанците, ферезейците, евейците и евусейците, седем народа по-големи и по-силни от тебе,
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
2 и когато Господ твоят Бог ги предаде на тебе та ги поразиш, тогава ги изтреби, като на Бога обречени; да не правиш договор с тях, нито да ги пожалиш;
nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
3 да се не жениш между тях, и да не даваш дъщеря си на сина му, нито да вземаш неговата дъщеря за своя син;
Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
4 защото ще отвърнат синовете ти от да Ме следват, за да служат на други богове, и така ще пламне против вас гневът на Господа, който скоро ще те изтреби.
torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
5 Но така да им направите: жертвениците им да разорите, кумирите им да изпотрошите, ашерите им да изсечете и изваяните им идоли да изгорите с огън.
Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
6 Понеже вие сте люде свети на Господа вашия Бог; вас избра Господ вашият Бог да бъдете Нему собствен народ измежду всичките племена, които са по лицето на земята.
Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
7 Господ не ви предпочете нито ви избра, за гдето сте по-многочислени от всичките други племена; защото вие сте най-малочислени от всичките племена.
Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
8 Но понеже ви възлюби Господ и за да опази клетвата, с който се е клел на бащите ви, за това Господ ви изведе със силна ръка и ви изкупи от дома на робството, от ръката на египетския цар Фараона.
Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
9 И тъй, да знаеш, че Господ твоят Бог, Той е Бог, верният Бог. Който пази до хиляда поколения завета и милостта към ония, които Го любят и пазят заповедите Му;
Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
10 а на ония, които Го мразят, въздава им в лице и ги изтребва; няма да забавя наказанието на онзи, който Го мрази, но ще му въздаде в лице.
Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
11 За това, пази заповедите, повеленията и съдбите, които днес ти заповядвам, за да ги вършиш.
Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
12 И ако слушате тия съдби и ги пазите и вършите, Господ твоят Бог ще пази за тебе завета и милостта, за която се е клел на бащите ти;
Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
13 и ще те възлюби, ще те благослови и ще те умножи; ще благослови и плода на утробата ти и плода на земята ти, житото ти, виното ти и маслото ти, и рожбите от говедата ти и малките от овците ти, в земята, за която се е клел на бащите ти да я даде на тебе.
Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
14 Ще бъдеш благословен повече от всичките племена; не ще има неплоден или неплодна между вас или между добитъка ви.
A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
15 Господ ще отстрани от тебе всяка болест и няма да докара върху тебе ни една от злите египетски болести, които познаваш; но ще ги наложи върху всички ония, които те мразят.
Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
16 За това, да изтребиш всичките племена, които Господ твоят Бог ти предава; окото ти да ги не пожали; и на боговете им да не служиш, защото това ще ти бъде примка.
Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
17 И ако речеш в сърцето си: Тия народи са по-многочислени от мене, как ще мога да ги изгоня?
Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
18 да се не уплашиш от тях; да помниш добре що направи Господ твоят Бог на Фараона и на всичките египтяни;
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
19 големите изпитни, които очите ти видяха, знаменията и чудесата, силната ръка и издигнатата мишца, с който Господ твоят Бог те изведе. Така ще направи Господ твоят Бог на всичките племена, от които ти се плашиш.
Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
20 Още Господ твоят Бог ще изпрати и стършели върху тях, догде бъдат изтребени останалите, които са се скрили от тебе.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
21 Да са не уплашиш от тях, защото Господ твоят Бог е всред, тебе, Бог велик и страшен.
Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
22 И Господ твоят Бог малко по малко ще изгони тия народи от пред тебе; не бива да ги изтребиш изведнъж, за да се не умножат върху тебе полските зверове.
Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
23 Но Господ твоят Бог ще ти ги предаде и ще ги разстройва с голямо разстройство, догде се изтребят.
Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
24 Ще предаде и царете им в ръката ти, и ще заличиш името им под небето; никой не ще може да устои пред тебе догде не ги изтребиш.
Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
25 Кумирите на боговете им изгаряйте с огън; да не пожалиш да вземеш на себе си среброто или златото, което е върху тях, за да се не впримчиш в него, понеже това е мерзост пред Господа твоя Бог.
Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
26 И да не внасяш в дома си никаква мерзост, за да не станеш обречен на изтребление като нея; съвършено да я мразиш и съвършено да се отвращаваш от нея, защото е обречена на изтребление.
Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.