< Второзаконие 2 >
1 Тогава се върнахме та пътувахме в пустинята през пътя за Червено море, след както Господ беше ми говорил; и дълго време обикаляхме поляната Сиир.
Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
2 После Господ ми говори казвайки:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
3 Доволно се обикаляли тая поляна; върнете се към север.
“Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
4 И заповядай на людете, като им кажеш: Ще минете през пределите на братята си исавците, които живеят в Сиир, и те ще се убоят от вас. За това, внимавайте добре;
Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
5 да се не биете с тях, понеже няма да ви дам от земята им ни една стъпка от нога, защото на Исава дадох поляната Сиир за владение.
Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
6 С пари да купувате от тях храна за ядене, още и с пари да купувате от тях вода за пиене;
Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
7 защото Господ твоят Бог те благослови във всичките дела на ръцете ти; познал е пътуването ти през тая голяма пустиня; през тия четиридесет години Господ твоят Бог е бил с тебе; не си останал лишен от нищо.
Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
8 Така минахме покрай братята си исавците, които живееха в Сиир, през пътя по полето от Елат и от Есион-гавер. Върнахме се та минахме през пътя по Моавската пустиня.
Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
9 Тогава Господ ми каза: Да не досаждате на моавците, нито да воювате с тях, защото няма да ти дам да владееш нищо от земята им, понеже на Лотовите потомци дадох Ар за владение.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
10 (А по-напред живееха там емимите, люде велики и многочислени и високи като енакимите.
(Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
11 И те, като енакимите, се считаха исполини; но моавците ги наричаха емими.
Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
12 Също и хорейците живееха по-напред в Сиир; но исавците ги заместиха, изтребиха ги от пред себе си и се заселиха на мястото им, както направи Израил в земята на своето наследство, която им даде Господ.)
Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
13 Станете сега та преминете потока Заред. И така, преминахме потока Заред.
Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
14 Времето, през което пътувахме от Кадис-варни догде преминахме потока Заред, беше тридесет и осем години, догде се довърши изсред стана цялото поколение на воюващите мъже, както им се кле Господ.
Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
15 Още Господната ръка беше против тях, за да ги изтреби изсред стана догде се довършиха.
Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
16 А като се довършиха и измряха всички воюващи мъже изсред людете,
Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
17 Господ ми говори казвайки:
Olúwa sọ fún mi pé,
18 Днес ти ще преминеш Ар, моавската граница;
“Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
19 и като се приближиш срещу амонците, не им досаждай нито да воюваш с тях, защото няма да владееш нищо от земята на амонците, понеже на Лотовите потомци я дадох за владение.
Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
20 (Също и тя се считаше земя на исполините: исполини по-напред живееха там, а амонците ги наричаха замзумими;
(A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
21 люде велики и многочислени и високи, като енакимите; но Господ ги изтреби от пред тях; и те ги заместиха и заселиха се на мястото им;
Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
22 за тях направи, както направи за исавците, които живееха в Сиир, когато изтреби хорейците от пред тях, и те ги заместиха и заселиха се на мястото им, гдето са и до днес;
Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
23 и кафторците излязоха из Кафтор та изтребиха авейците, които живееха в села дори до Газа, и заселиха се на мястото им.)
Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
24 Станете, тръгнете и преминете потока Арнон; ето, предавам в ръката ти асорееца Сион, цар на Есевон, и земята му; почни да я завладяваш, и бий се с него.
“Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
25 Днес ще почна да всявам трепет и страх от тебе върху всичките племена под цялото небе; като чуят за тебе те ще се разтреперят и ще се ужасяват от тебе.
Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
26 И изпратих посланици от пустинята Кедемот при есевонския цар Сион с мирни думи, да кажат:
Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
27 Нека замина през земята ти; право из друма ще вървя; няма да се отбия ни надясно ни наляво.
“Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
28 С пари ще ми продаваш храна, за да ям, и с пари ще ми дадеш вода до пия; само с нозете си да замина,
Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
29 (както ми сториха исавците, които живеят в Сиир, и моавците, които живеят в Ар), догде мина през Иордан в земята, която Господ нашият Бог ни дава.
gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
30 Обаче есевонският цар Сион не склони да заминем през земята му; понеже Господ твоят Бог закорави духа му и вкамени сърцето му, за да го предаде в ръцете ти, както е и до днес.
Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
31 А Господ ми рече: Ето, започнах да ти предавам Сиона и земята му; почни да превземаш земята му, за да я наследиш.
Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
32 Тогава Сион излезе против нас, той и всичките му люде, на бой в Яса.
Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
33 И Господ нашият Бог го предаде в ръцете ни; поразихме него, синовете му и всичките му люде.
Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
34 В онова време превзехме всичките му градове, и във всеки град изтребихме мъжете, жените и децата; не оставихме да оцелее ни един.
Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
35 Пленихме за себе си само добитъка и користите на градовете, които превзехме.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
36 От Ароир, при устието на потока Арнон, и от града, който е в долината, дори до Галаад не се намери град, който можа да устои против нас; Господ нашият Бог предаде всичките пред нас.
Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
37 Само към земята на амонците ти не си се приближил, ни към местата край потока Явок, ни към планинските градове, ни към коя да е страна, която Господ нашият Бог ни бе запретил.
Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.