< Амос 8 >
1 Това е, което Господ Иеова ми показа: - Ето кошница с узряло (Еврейски: лятно) овощие.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 И рече: Що виждаш Амосе? И рекох: Кошница с узряло (Еврейски: лятно) овощие. Тогава Господ ми рече: - Людете ми Израил узряха; (Еврейски: Дойде краят на людете ми Израил) Занапред няма вече да ги щадя.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 И в оня ден, казва Господ Иеова, Храмовите песни ще бъдат виения; Защото труповете ще бъдат много, Навсякъде ще ги изхвърлят мълчешком.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 Слушайте това, вие, които бихте поглъщали бедните, И бихте погубвали сиромасите на тая земя,
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 Казвайки: Кога ще мине новолунието, за да продадем жито, И съботата, за да изложим на продан пшеница, Като смалим ефата, уголемим сикъла, И мамим с лъжливи къпони?
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 За да купим сиромасите с пари, И бедният за един чифт обуща, И да продадем отсевките на пшеницата?
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Господ се закле в Оня, с когото Яков се слави, като рече: Наистина няма никога да забравя кое да било от делата им.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 Не ще ли се поклати земята за това, И всеки, който живее на нея да жалее? Така! И тя цяла ще се издига като Нил, Ще се развълнува и спада пак като Египетската река.
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 В оня ден казва Господ Иеова, Ще направя да залезе слънцето на пладне, И ще помрача земята всред бял ден.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Ще обърна пируванията ви в жалеене, И всичките ви песни в плач; Ще туря вретище на всички кръстове, И плешивост на всяка глава; И ще причиня жалеене като за единороден син, И скончанието му да бъде като края на горестен ден.
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 Ето, идат дни, казва Господ Иеова, Когато ще пратя глад на земята, - Не глад за хляб, нито жажда за вода, Но за слушане думите Господни.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Те ще се скитат от море до море Да търсят словото Господне, И ще обикалят от север до изток, Но няма да го намерят.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 В оня ден красивите девици И юношите ще премират от жажда.
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Ония, които се кълнат с престъплението на Самария, Като казват - Заклеваме се в живота на бога ти, Дане! И - Заклеваме се в живота на обичайния бог у Вирсавее! - Те ще паднат, и никога няма да станат вече.
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”