< 2 Царе 12 >
1 Тогава Господ прати Натана при Давида. И той като дойде при него, каза му: В един град имаше двама човека, единият богат, а другият сиромах.
Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
2 Богатият имаше овци и говеда твърде много;
Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 а сиромахът нямаше друго освен едно малко женско агне, което бе купил и което хранеше; а то бе пораснало заедно с него и чадата му, от залъка му ядеше, от чашата му пиеше, и на пазухата му лежеше; и то ме беше като дъщеря.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
4 И един пътник дойде у богатия; и нему се посвидя да вземе своите овци и от своите говеда да сготви за пътника, който бе дошъл у него, но взе агнето на сиромаха та го сготви за човека, който бе дошъл у него.
“Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
5 Тогава гневът на Давида пламна силно против тоя човек; и той каза на Натана: В името на живия Господ, човекът, който е сторил това, заслужава смърт;
Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
6 и ще плати за агнето четверократно, понеже е сторил това дело, и понеже не се е смирил.
Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
7 Тогава Натан каза на Давида: Ти си тоя човек. Така казва Господ Израилевият Бог: Аз те помазах за цар над Израиля, и те избавих от Сауловата ръка;
Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
8 и дадох ти дом на господаря ти, и жените на господаря ти в пазухата ти, и дадох ти Израилевия и Юдовия дом; и ако това беше малко, приложил бих ти това и това.
Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
9 Защото презря ти словото на Господа, та стори зло пред очите Му? Ти порази с меч хетееца Урия, и си взе за жена неговата жена, а него ти уби с меча на амонците.
Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
10 Сега, прочее, няма никога да се оттегли меч от дома ти, понеже ти Ме презря, та взе жената на хетееца Урия, за да ти бъде жена.
Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
11 Така казва Господ: Ето, отсред твоя дом ще подигна против тебе злини, и ще взема жените ти пред очите ти, та ще ги дам на ближния ти; и той ще лежи с жените ти пред това слънце.
“Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
12 Защото ти си извършил това тайно; но Аз ще извърша туй нещо пред целия Израил и пред слънцето.
Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
13 Тогава Давид каза на Натана: Съгреших Господу, А Натан каза на Давида: И Господ отстрани греха ти; няма да умреш.
Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
14 Но понеже чрез това дело ти си дал голяма причина на Господните врагове да хулят, затова детето което ти се е родило, непременно ще умре.
Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
15 И Натан си отиде у дома си. А Господ порази детето, което Уриевата жена роди на Давида, и то се разболя.
Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
16 Давид, прочее, се моли Богу за детето; и Давид пости, па влезе та пренощува легнал на земята.
Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
17 И старейшините на дома му станаха и дойдоха при него, за да го дигнат от земята; но той отказа, нито вкуси хляб с тях.
Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
18 И на седмия ден детето умря. И слугите на Давида се бояха да му явят, че детето бе умряло, защото думаха: Ето, докато детето бе още живо говорехме му, и той не слушаше думите ни; колко, прочее, ще се измъчва, ако му кажем, че детето е умряло!
Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
19 Но Давид, като видя че слугите му шепнеха помежду си, разбра, че бе умряло детето; затова Давид каза на слугите си: Умря ли детето? А те рекоха: Умря.
Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
20 Тогава Давид стана от земята, уми се и се помаза, и като промени дрехите си, влезе в Господния дом та се помоли. После дойде у дома си; и, понеже поиска, сложиха пред него хляб, и той яде.
Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
21 А слугите му му казаха: Що е това, което ти стори? Ти пости и плака за детето, докато беше живо; а като умря детето, ти стана и яде хляб!
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
22 А той рече: Докато детето беше още живо, постих и плаках, защото си рекох: Кой знае? може Бог да ми покаже милост, и детето да остане живо.
Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
23 Но сега то умря. Защо да постя? Мога ли да го върна надире? Аз ще ида при него, а то няма да се върне при мене.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
24 След това, Давид утеши жена си Витсавее, и влезе при нея та лежа с нея; и тя роди син, и нарече го Соломон. И Господ го възлюби,
Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
25 и прати чрез пророка Натана та го нараче Едидия, заради Господа.
Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
26 А Иоав воюва против Рава на амонците и превзе царския град.
Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
27 И Иоав прати вестители до Давида, да кажат: Воювах против Рава, и даже превзех града на водите.
Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
28 Сега, прочее, събери останалите люде та разположи стана си против града и завладей го, да не би аз да завладея града, и той да се нарече с моето име.
Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
29 Затова Давид събра всичките люде та отиде в Рава, би се против нея, и я завладя.
Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
30 И взе от главата на царя им короната му, която тежеше един златен талант, и бе украсена със скъпоценни камъни; и положиха я на главата на Давида. И той изнесе из града твърде много користи.
Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
31 Изведе и людете, които бяха в него, та го тури под триони и под железни дикани и под железни брадви, и преведе ги през пещта за тухли; и така постъпи с всички градове на амонците. Тогава Давид се върна с всичките люде в Ерусалим.
Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.