< 4 Царе 5 >
1 А Нееман, военачалникът на сирийския цар, беше човек велик и почитан пред господаря си, понеже чрез него Господ бе дал избавление на Сирия; при това, беше човек силен и храбър, но беше прокажен.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 И сирийците бяха излезли на чети, и бяха довели от Израилевата земя една малка мома пленница; и тя слугуваше на Неемановата жена.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 И рече на Господарката си: Ако беше господарят ми при пророка, който е в Самария, и той би го изцелил от проказата му!
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Тогава влезе Нееман та съобщи на господаря си, казвайки: Така и така рече момата, която е от Израилевата земя.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 И рече сирийският цар: Стани, иди, и ще пратя писмо до Израилевия цар. И тъй, той отиде, вземайки в ръката си десет таланта сребро, шест хиляди жълтици, и десет премени дрехи.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 И донесе писмоо на Израилевия цар, в което се казваше: Като пристигне това писмо до тебе, ето, същевременно пратих до тебе слугата си Неемана, за да го изцелиш от проказата му.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 А Израилевият цар, като прочете писмото, раздра дрехите си и рече: Бог ли съм аз за да умъртвявам и да съживявам, та праща до мене да изцеря човека от проказата му? Моля, прочее, разсъдете и вижте как търси повод за скарване с мене.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 А Божият човек Есей, като чу, че Израилевият цар раздрал дрехите си, прати до царя да рекат: Защо си раздрал дрехите си? Нека дойде сега при мене, и ще познае, че има порок в Израиля.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 И така, Нееман дойде с конете си и с колесниците си та застана при вратата на Елисеевата къща.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 И Елисей прати до него човек да каже: Иди, окъпи се седем пъти в Иордан; и ще се обновят месата ти, и ще се очистиш.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 А Нееман се разгневи, та си отиде, като казваше: Ето, аз мислех, че той непременно ще излезе при мене, ще застане, и ще призове името на Господа своя Бог, и ще помаха ръката си върху мястото, и така ще изцери прокажения.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Реките на Дамаск, Авана и Фарфар, не струват ли повече от всичките води на Израиля? Не мога ли да се окъпя в тях и да се очистя? Затова, той се обърна и си отиде много разгневен.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 А слугите му се приближиха та му говориха, казвайки: Татко мой, ако ти беше заръчал пророкът нещо голямо, не би ли го извършил? Колко повече, прочее, като ти казва! Окъпи се и очисти се!
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Тогава той слезе та се потопи седем пъти в Иордан, според думите на Божия човек; и месата му се обновиха, като месата на малко дете, и очисти се.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Тогава той се върна при Божия човек с цялата си дружина, и като дойде та застана пред наго рече: Ето, сега узнах, че няма Бог в целия свут освен в Израиля; затова, моля, приеми сега подарък от слугата си.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 А той каза: Заклевам се в живота на Господа, Комуто слугувам, не ща да приема. А той го принуждаваше да приеме; но отказа.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Тогава Нееман рече: Ако не то нека се даде, моля, на слугата ти товар за две мъски от тая пръст; защото слугата ти не ще вече да принася ни всеизгаряне, нито жертва на други богове освен на Господа.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 Господ да прости това нещо на слугата ти, ако, когато влиза господарят ми в къпищато на Ромона, за да се поклони там, и се подпира на ръката ми, се навеждам и аз в къпището на Римона; като се навеждам в капището на Римона, Господ да прости това нещо на слугата ти!
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 И рече му: Иди с мир. И така, той отиде от него известно растояние.
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Но Гиезий, слугата на Божия човек Елисей, си рече: Ето, господарят ми си посвени, та не взе от ръката на тоя сириец Нееман това, което донесе; но в името на живия Господ, аз ще се завтека подер него и ще взема нещо от него.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 И тъй, Гиезий се завтече подир Неемана. А нееман, когато видя, че тича подир него, скочи от колесницата да го посрещне и рече: Добре ли и с всички ви?
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Той рече: Добре. Господарят ми ме прати да река: Ето тъкмо сега дойдоха у мене от хълмистата земя на Ефрема двама младежи от пророческите ученици; дай им, моля, един талант сребро и премени дрехи.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 И рече на Нееман: Благоволи да вземеш два таланта. И като го принуди, върза двата таланта сребро в два мешеца заедно с две премени дрехи, и натовари ги на двама от слугите си, които ги носеха пред него.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 И когато стигна до хълма, взе ги от ръцете им та ги скри в къщата; и отпусна човеците, та си отидоха.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Тогава влезе та застана пред господаря си. И Елисей му рече: От где идеш, Гиезие? А той рече: Слугата ти не е ходил никъде.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 А Елисей му каза: Не отиде ли сърцето ми с тебе, когато се върна човекът от колесницата си за да те посрещне? Време ли е да приемеш пари и да приемеш дрехи, маслини и лозя, овци и говеда, слуги и слугини?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Затова Неемановата проказа ще се засили за тебе и за рода ти до века. И той излезе от присъствието му прокажен, бял като сняг.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.