< 2 Летописи 24 >
1 Иоас беше на седем години, когато се възцари, и царува четиридесет години в Ерусалим; а името на майка му бе Савия, от Вирсавее.
Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
2 И Иоас вършеше това, което бе право пред Господа, през всичките дни на свещеник Иодай.
Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
3 И Иодай му взе две жени; и той роди синове и дъщери.
Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
4 След това, Иоас си науми да обнови Господния дом.
Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
5 И тъй събра свещениците и левитите, та им рече: Излезте по Юдовите градове, та съберете от целия Израил пари за да се поправя дома на вашия Бог от година до година, и гледайте да побързате с работата. Обаче, левитите не побързаха.
Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
6 Тогава царят повика началника на работата Иодай, та му рече: Защо не си изискал от левитите да съберат от Юда и Ерусалим данъка, определен от Господния слуга Моисей да се събира от Израилевото общество, за шатъра на свидетелството?
Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
7 (Защото нечестивата Готолия и синовете й бяха разстроили Божия дом; още и всичките посветени неща в Господния дом бяха посветили на ваалимите).
Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
8 Прочее, по царската заповед направиха един ковчег, който туриха извън, при вратата на Господния дом.
Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
9 И прогласиха в Юда и в Ерусалим да принасят Господу данък наложен върху Израиля от Божия слуга Моисей в пустинята.
A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
10 И всичките първенци и всичките люде се зарадваха и донасяха и туряха в ковчега догде се напълнеше.
Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
11 И когато левитите донасяха ковчега при царските настоятели, и те виждаха, че имаше много пари, царският секретар и настоятелят на първосвещеника дохождаха та изпразваха ковчега, и пак го занасяха и поставяха на мястото му. Така правеха от ден на ден, и събираха много пари.
Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
12 И царят и Иодай ги даваха на ония, които вършеха делото на служенето в Господния дом; и тези наемаха зидари и дърводелци за да обновят Господния дом, още и ковачи и медникари за да поправят Господния дом.
Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
13 И така, работниците вършеха работата, и поправянето успяваше с работенето им, тъй че възстановиха Божия дом в първото му състояние и го закрепиха.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
14 И когато свършиха, донесоха останалите пари пред царя и Иодай, и с тях направиха съдове за Господния дом, съдовете за служене и за принасяне жертви, темянници, и други златни и сребърни съдове. Така, непрестанно принасяха всеизгаряния в Господния дом през целия живот на Иодая.
Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
15 Но Иодай остаря и стана сит от дни, и умря; сто и тридесет години бе на възраст когато умря.
Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
16 И погребаха го в Давидовия град между царете, понеже бе извършил добро в Израиля, и пред Бога, и за дома Му.
Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
17 А след смъртта на Иодая, Юдовите началници дойдоха та се поклониха на царя, Тогава царят ги послуша;
Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
18 и те оставиха дома на Господа Бога на бащите си, и служиха на ашерите и на идолите; и гняв дойде върху Юда и Ерусалим поради това тяхно престъпление.
Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
19 При все това, Бог им прати пророци за да ги обърнат към Господа, които заявяваха против тях; но те не послушаха.
Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
20 Тогава Божият Дух дойде на Захария, син на свещеник Иодай, та застана на високо място над людете и рече им: Така казва Бог: Защо престъпвате Господните заповеди? Няма да успеете; понеже вие оставихте Господа, то и Той остави вас.
Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
21 Обаче, те направиха заговор против него и с царска заповед го убиха с камъни в двора на Господния дом.
Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
22 Цар Иоас не си спомни доброто, което му беше показал Иодай, неговият баща, но уби сина му; а той, като умираше рече: Господ да погледни и да издири.
Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
23 И в края на годината, сирийската войска възлезе против Иоаса; и като дойде в Юда и Ерусалим, изтребиха всичките народни първенци изсред людете, и изпратиха всичките користи, взети от тях, до царя на Дамаск.
Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
24 При все, че сирийската войска, която дойде, беше малолюдна, пак Господ предаде в ръката им едно твърде голямо множество, понеже те бяха оставили Господа Бога на бащите си. Така сирийците извършиха съдба против Иоаса.
Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
25 А като заминаха от него, (и го оставиха страдащ с тежки рани, собствените му слуги направиха заговор против него, поради кръвта на сина на свещеник Иодай, и убиха го на леглото му, та умря; и погребаха го в Давидовия град, но не го погребаха в царските гробища.
Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
26 А ония, които направиха заговор против него, бяха: Завад, син на амонката Симеата и Иозавад, син на моавката Самарита.
Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
27 А колкото за синовете му, и за тежките товари за откуп наложени върху него, и за поправяне на Божия дом, ето, писано е в повестите на Книгата на царете. И вместо него се възцари син му Амасия.
Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.