< 2 Летописи 16 >
1 В тридесет и шестата година от царуването на Аса, Израилевият цар Вааса, като възлезе против Юда, съгради Рама, за да не остави никого да излиза от Юдовия цар Аса, нито да влиза при него.
Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
2 Тогава Аса извади сребро и злато из съкровищницата на Господния дом и на царската къща та прати при сирийския цар Венадад, който жевееше в Дамаск, да рекат:
Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
3 Нека има договар между мене и тебе, както е имало между баща ми и твоя баща; ето пратих ти сребро и злато; иди, развали договора си с Израилевия цар Вааса, за да се оттегли от мене.
“Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
4 И Венадад послуша цар Аса та прати началниците на силите си против Израилевите градове; и те поразиха Иион, Дан, Авел-маим и всичките Нефталимови житници-градове.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
5 И Вааса, като чу това, престана да гради Рама, и преустанови работата си.
Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6 Тогава цар Аса взе целия Юда, та дигнаха камъните на Рама и дърветата й, с които Вааса градеше; и с тях съгради Гава и Масфа.
Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
7 А в това време гледачът Ананий отиде при Юдовия цар Аса та му рече: Понеже си уповал на сирийския цар, а не си уповавал на Господа своя Бог, затова войската на сирийския цар избегна и ръката ти.
Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
8 Етоипяните и ливийците не бяха ли огромно множество, с твърде много колесници и конници? Но пак, понеже ти упова на Господа, Той ги предаде в ръката ти.
Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
9 Защото очите на Господа се обръщат насам-натам през целия свят, за да се показва Той мощен в помощ на ония, чиито сърца са съвършенно разположени към Него. В това ти си постъпил безумно, защото от сега нататък ще имаш войни.
Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
10 По това, Аса се разгневи на гледача та го тури в затвор, защото се разсърди против него за туй нещо. И в същото време Аса притесни някои от людете.
Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
11 И, ето, делата на Аса, първите и последните, ето, написани са в Книгата на Юдовите и Израилевите царе.
Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
12 А в тридесет и деветата година от царуването си, Аса се разболя от болест в нозете; обаче, макар болестта му да ставаше твърде тежка, пак в болестта си той не потърси Господа, но лекарите.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
13 И Аса заспа с бащите си; и умря в четиридесет и първата година от царуването си.
Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
14 И погребаха го в гроба, който се бе изкопал в Давидовия град, и положиха го на легло пълно с благоухания и с различни аптекарски аромати; и изгориха за него твърде много аромати.
wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.