< Mark 16 >
1 niwa i vi u asabarchi a wuce Maryamu ba magadaliya mba salome ba ka nji izyi kpa ye nde ba gban ni yesu nikpa
Nígbà tí ọjọ́ ìsinmi sì kọjá, Maria Magdalene, Maria ìyá Jakọbu, àti Salome mú òróró olóòórùn dídùn wá kí wọn bá à le fi kun Jesu lára.
2 ni bwubwu ble ni vi mule u satia u ba hi ni beh ni nza hongan
Ní kùtùkùtù ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, wọ́n wá sí ibi ibojì nígbà tí oòrùn bẹ̀rẹ̀ sí yọ,
3 u ba myen kpamba a di a nhan ni nyiu tita rju ni tawu ni yiu beh hia?
wọn sì ń bi ara wọn léèrè pé, “Ta ni yóò yí òkúta náà kúrò ní ẹnu ibojì fún wa?”
4 u ba nzu shishi ya na toh ba nyiu tita rju ye tita a ki kle ma gbenme
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn sì wò ó, wọ́n rí i pé a ti yí òkúta tí ó tóbi gidigidi náà kúrò.
5 u ba luri ni mi na toh vren nze ri sur nklo kinkle son ni wo kori uba bwu yiu
Nígbà tí wọ́n sì wo inú ibojì náà, wọ́n rí ọ̀dọ́mọkùnrin kàn tí ó wọ aṣọ funfun, ó jókòó ní apá ọ̀tún, ẹnu sì yà wọn.
6 wa hla ni bawu na bwu yiu na bi si wa yesu ba nazaraten wa ba giciye niwu alude n a na hei na ya ige bubu wa ba kah yo yi
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má bẹ̀rù: ẹ̀yin ń wá Jesu tí Nasareti, tí a kàn mọ́ àgbélébùú. Ó jíǹde! Kò sí níhìn-ín yìí mọ́, ẹ wo ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.
7 ama bika hi kpambi ni ha ni almajere ma nie Bitrus a hei koshishi si hi ni galilis ni mun bi toh nawa a hla ni yiua
Ṣùgbọ́n ẹ lọ sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ títí kan Peteru wí pé, ‘Òun ti ń lọ síwájú yín sí Galili. Ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti rí i, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ fún yín.’”
8 u ba dorju ni mi beh ni wi likpa ni bwuyiu bana ya tre kpieri me ni kpambana nitu sisir
Wọ́n sáré jáde lọ kánkán, kúrò ní ibi ibojì náà, nítorí tí wọ́n wárìrì; ẹ̀rù sì bà wọn gidigidi; wọn kò wí ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni, nítorí ẹ̀rù bá wọ́n.
9 (note: The most reliable and earliest manuscripts do not include Mark 16:9-20.) nta shime ni bwumble ni vi u mumlan u satia da guchi ye rju ni mary magadaliya na ju meme ibrji tar gban rju niwu
(note: The most reliable and earliest manuscripts do not include Mark 16:9-20.) Nígbà tí Jesu jíǹde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, ó kọ́ fi ara hàn fun Maria Magdalene, ni ara ẹni tí ó ti lé ẹ̀mí Èṣù méje jáde.
10 wa hi na kah bla nibi wa ba hei ni wua da katsira ba si ta mre da ni yi
Òun sì lọ sọ fún àwọn tí ó ti ń bá a gbé, bí wọn ti ń gbààwẹ̀, tí wọ́n sì ń sọkún.
11 i ba wo da hei ni rei u wawu toh ni shishima ama u bana kpa nyeme na
Àti àwọn, nígbà tí wọ́n sì gbọ́ pé Jesu wa láààyè, àti pé, òun ti rí i, wọn kò gbàgbọ́.
12 wa rju ni babwu ha mba ni kon rimu kan yada ba rju nigbua zren sihi kpamba
Lẹ́yìn èyí, ó sì fi ara hàn fún àwọn méjì ní ọ̀nà mìíràn, bí wọ́n ti ń rìn ní ọ̀nà, tí wọ́n sì ń lọ sí ìgbèríko.
Nígbà tí wọ́n sì mọ ẹni tí i ṣe, wọ́n sì lọ ròyìn fún àwọn ìyókù, síbẹ̀, àwọn ìyókù kò gbà wọ́n gbọ́.
14 ni ko ngo ki yesu lu rju ni wolon don ri uba si rila ni tu tebru wa pwa ba tre nitu wa bana kpanyemena da nsei tu da na kpanyemen ni biwa da toh shishi nishishi na hla ba hi wu a ndi alude na
Lẹ́yìn náà, Jesu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn mọ́kànlá níbi tí wọ́n ti ń jẹun papọ̀; Ó sì bá wọn wí fún àìgbàgbọ́ àti ọkàn líle wọn, nítorí wọn kò gba ẹ̀rí àwọn tí ó ti rí i lẹ́yìn àjíǹde rẹ̀ gbọ́.
15 a hla bawu ndu ba hi na hla tre ma ni ndi bi rgbungbulu ba kagon wawusu
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí gbogbo ayé, kí ẹ sì máa wàásù ìyìnrere mi fún gbogbo ẹ̀dá.
16 indi wa a kpa nyeme na ndu ba yi batisma niwua ani nawo indi wa ana kpa nyemen na ani rilu
Ẹni tí ó bá gbàgbọ́, tí a sì tẹ̀bọmi yóò là. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kọ̀ tí kò gbàgbọ́ yóò jẹ̀bi.
17 ba toh tie bi yii ni biwa ba kpatre rji ba zu brji ni nde mu ba tre lme sama
Àmì wọ̀nyí yóò sì máa bá àwọn tí ó gbàgbọ́ lọ. Ní orúkọ mi ni wọ́n yóò máa lé ẹ̀mí èṣù jáde. Wọn yóò máa fi èdè tuntun sọ̀rọ̀.
18 ba ya vuwam ni wo ana tie ba kpie na ko ba so meme gbugbulu ana tie ba kpie na
Wọn yóò sì gbé ejò lọ́wọ́, bí wọ́n bá sì jẹ májèlé kò nípa wọ́n lára rárá. Wọ́n yóò gbé ọwọ́ lé àwọn aláìsàn, ara wọn yóò sì dá.”
19 yesu tre kle ni ba wu uba ban hi ni shulu waka son ni wo ko ri irji
Nígbà tí Jesu Olúwa sì ti bá wọn sọ̀rọ̀ báyìí tan, á gbé e lọ sí ọ̀run, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
20 u baluri blatre rji kango gbungbulu a irji ni zo ba na kpanyeme ni tre mba nikpii wa a tre ba tie baa
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì jáde lọ. Wọ́n ń wàásù káàkiri. Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, ó sì ń fi ìdí ọ̀rọ̀ rẹ̀ múlẹ̀ nípa àwọn àmì tí ó tẹ̀lé e.