< Luke 3 >
1 Ni mi ise u tso don tra wa Tiberia Caesar - Chu, u, Pontiyus Bilatus ana gomna Judiya, Hiridus ka Chu ni Galili, vayima Filibus ka chu ni Ituriyada Tarakunitas, mba Lasaniyas ana Chu ni Abaliya.
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún ìjọba Tiberiu Kesari, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ baálẹ̀ Judea, tí Herodu sì jẹ́ tetrarki Galili, Filipi arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ tetrarki Iturea àti ti Trakoniti, Lisania sì jẹ́ tetrarki Abilene,
2 Ni nton wa Hanana ba kayafa bana bi ninkoh bitun tre Irji kaye ni Yahaya vren Zakariya ni miji.
tí Annasi òun Kaiafa ń ṣe olórí àwọn àlùfáà, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Johanu ọmọ Sekariah wá ní ijù.
3 Sei ka zren kagon gbugbulu mi yie'u nei u urdu, dani hla tre Irji ni bawu, a yo'u ba duba ye kpa Irji nda dun ba sukpa ni ba wu, duba wru lah tre mba hle ni bawu.
Ó sì wá sí gbogbo ilẹ̀ aginjù Jordani, ó ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀,
4 Na wa ba na nha nvunvu u tre Anabi Ishaya ndi llan di ri si yo ni miji, mlan koh Bachi tie dun koh ma hi yreyre.
bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah pé, “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ mú ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
5 Ko san ngbulu ba shu, u ngbulu ba ba gble tita ba kma ti fime, u nkoh bi tie memme ba kma bi ba ba shu, ni ngbulu baba tita ba ba yra ba nda kma me nkoh ni bubu biwa be gblegble me'a.
Gbogbo ọ̀gbun ni a yóò kún, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni a ó tẹ́ pẹẹrẹ. Wíwọ́ ni a ó ṣe ní títọ́, àti ọ̀nà gbọ́ngungbọ̀ngun ni a o sọ di dídán.
6 U bi he nimi kpa ba to Ceto u Irji.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì rí ìgbàlà Ọlọ́run.’”
7 Sai Yohana a hla ni gbugbu ndji wa ba si ye dun sukpa bawu'a. Yohana yo ba ndi “biyi mri iwan, anha hla ni yiwu dun yi tsutsu ni nfu wa ani ye ni yiwu'a?”
Nígbà náà ni ó wí fún ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn tí ó wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fún un yín láti sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
8 Nitu kii, kma tie klo kunkro wa ndi ba bre dun ba wru lla tre hle bawu dana ta tre ni kpamba ndi ki he ni Ibrahim wa a iti mbu, mi hla niwu Irji hei ni gbengble wa ani zu titi biyi kma tie mri ni Ibrahim rji ni tita bi yi.
Nítorí náà kí ẹ̀yin kí ó so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà, kí ẹ má sì ṣe sí í wí nínú ara yín pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Kí èmi kí ó wí fún un yín, Ọlọ́run lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu nínú òkúta wọ̀nyí.
9 Ko zizan ba mlan gla tie nitu nja bi ba kunkro. U wawu kunkro bi wandi bana klo bi na ba gen ba nda vu ba sru ni lu.”
Àti nísinsin yìí pẹ̀lú, a fi àáké lé gbòǹgbò igi náà, gbogbo igi tí kò bá so èso rere, a óò ge lulẹ̀, a sì wọ jù sínú iná.”
10 U gbugbu ndji baki mye'u ndi, “Zizan ki tie ni he?”
Àwọn ènìyàn sì ń bi í pé, “Kí ni kí àwa kí ó ṣe?”
11 A kasa nda tre “Indji wandi a he ni nklon ha, ka ban rhi ni ndji wandi ana he ni rhi na, u ndji wa ahe ni lah ka tie naki ngame.
Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹni tí ó bá ní ẹ̀wù méjì, kí ó fi ọ̀kan fún ẹni tí kò ní; ẹni tí ó bá sì ní oúnjẹ, kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
12 Bi kpa ban ba ye du ba sukpa ni bawu, nda tre, “Ndji-u-tsro, ki tie ni he?”
Àwọn agbowó òde sì tọ̀ ọ́ wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì bi í pé, “Olùkọ́, kí ni àwa ó ha ṣe?”
13 A hla ni bawu ndi, “Nata kpa inklen zan kpe wandi ba tre dun yi kpa na.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe fi agbára gbà jù bí a ti rán yín lọ mọ́.”
14 Sojoji bari ngame ba mye, ndi, “U kita na? Ki tie ni he?” A bla hla ni bawu, “Na kpa nkleh niwo njo ni gbengble na, ndi na tie ce ti ndrjo na. Nji kpe-andi bi u mbi dun mla yi.”
Àwọn ọmọ-ogun sì béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Àti àwa, kí ni àwa ó ṣe?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe hùwà ipá sí ẹnikẹ́ni, kí ẹ má sì ṣe ka ẹ̀sùn èké sí ẹnikẹ́ni; kí òwò ọ̀yà yín tó yín.”
15 Zizan wa ba ndji ba si ya nkoh ye u Kristi'a, wawu mba ba si rhimre ni suron mba nitu Yohana, ko wawu mba hi Kristi'a.
Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Johanu, bí òun ni Kristi tàbí òun kọ́;
16 Yohana a kasa ni bawu nda tre ndi, “Ime mi si sukpa ni yiwu ni mma, u ndji waa si ye ni koshi mu, a zan me ni gbengble, u mina tsra wa mi sie rjirji lagban u zama na. Wawu ni sukpa ni yiwu ni Ruhu Tsratsra ni lu.
Johanu dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ń bọ̀, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú, Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
17 Ahei ni mumu ni wo ma wandi ani tie ndu niwu nda zen memme bie nda ka waa bi zi nimi iwron. U ani gon biwa ba tie meme'a ni lu wa ana y'bi na.”
Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tó tó, kí ó sì kó alikama rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
18 Ni mi tsro mba Yohana a hla tre ndindi ni ndji ba.
Johanu lo oríṣìíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
19 Hiridus wa ana Chu, a son gran wa vayi ma Hiridiya, ni mbru meme kpie wa Hiridus azi tie'a,
Ṣùgbọ́n nígbà ti Johanu bú Herodu tetrarki, tí ó bá wí nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Herodu tí ṣe,
20 a ka biyi suru nhaa, ndi a ka Yohana tro ni brusuna.
Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ nígbà tí ó fi Johanu sínú túbú.
21 Inton wa ba sukpa ba ndji wawu, Yesu me ba sukpa'a niwu ngame, wa asi he ni mi bre wa ka toh shulu bu'u,
Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
22 wa toh Ruhu Tsatsar ka grji ye son nitu ma na ngyu, wa ka wo lan Irji ni shu, “Iwu yi wu vren mu wandi isuron mu a kpa wu. Suron mu ku si ni wu.”
Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
23 Yesu ahe ni sei wlon nkpu tra nda vu tie ndu Irji. Nimi kpa, Yesu hi vren Isuwu wa ba yo tima ndi Heli,
Jesu tìkára rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Eli,
24 ivren Matat, ivren u Levi, ivren u Melki, ivren u janai, ivrn u Isuwu.
tí í ṣe ọmọ Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi, tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Janai, tí í ṣe ọmọ Josẹfu,
25 Isuwu ana vren Mattatiyas, ivren Amos, Ivren Nahum, ivren Esli, ivren Naggai,
tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Amosi, tí í ṣe ọmọ Naumu, tí í ṣe ọmọ Esili, tí í ṣe ọmọ Nagai,
26 ivren u Maat, ivren u Mattatiyas, ivren u Semein, ivren u Josech, ivren u Joda.
tí í ṣe ọmọ Maati, tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Ṣimei, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Joda,
27 Joda ana vren u Jowanan, ivren u Resa, ivren u Zerubabel, ivren u Salatiyel, ivren u Neri,
tí í ṣe ọmọ Joana, tí í ṣe ọmọ Resa, tí í ṣe ọmọ Serubbabeli, tí í ṣe ọmọ Ṣealitieli, tí í ṣe ọmọ Neri,
28 ivren u Melki, ivren u Addi, ivren u Cosam, ivren u Elmadam, ivren u Er,
tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Adi, tí í ṣe ọmọ Kosamu, tí í ṣe ọmọ Elmadamu, tí í ṣe ọmọ Eri,
29 ivren u Joshuwa, ivren u Eliyeza, ivren u Jorim, ivren u Mattat, ivren u Levi.
tí í ṣe ọmọ Joṣua, tí í ṣe ọmọ Elieseri, tí í ṣe ọmọ Jorimu, tí í ṣe Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi,
30 Levi ana vren Simiyon, ivren Judah, ivren Isuwu, ivren Jonam, ivren Eliakim,
tí í ṣe ọmọ Simeoni, tí í ṣe ọmọ Juda, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Jonamu, tí í ṣe ọmọ Eliakimu,
31 ivren Meliya, ivren Menna, ivren Mattata, ivren Natan, ivren Dawuda,
tí í ṣe ọmọ Melea, tí í ṣe ọmọ Menna, tí í ṣe ọmọ Mattata, tí í ṣe ọmọ Natani, tí í ṣe ọmọ Dafidi,
32 ivren Jessi, ivren Obed, ivren Bowaz, ivren Salmon, ivren Nahshon.
tí í ṣe ọmọ Jese, tí í ṣe ọmọ Obedi, tí í ṣe ọmọ Boasi, tí í ṣe ọmọ Salmoni, tí í ṣe ọmọ Nahiṣoni,
33 Nahshon ana vren Amminadab, ivren Admin, ivren Arni, ivren Hezron, ivren Perez, ivren Judah,
tí í ṣe ọmọ Amminadabu, tí í ṣe ọmọ Ramu, tí í ṣe ọmọ Hesroni, tí í ṣe ọmọ Peresi, tí í ṣe ọmọ Juda.
34 ivren Yakubu, ivren Isuwa, ivren Ibrahim, ivren Terah, ivren Nahor,
Tí í ṣe ọmọ Jakọbu, tí í ṣe ọmọ Isaaki, tí í ṣe ọmọ Abrahamu, tí í ṣe ọmọ Tẹra, tí í ṣe ọmọ Nahori,
35 ivren Serug, ivren Riyu, ivren Peleg, ivren Eba, ivren Shelah.
tí í ṣe ọmọ Serugu, tí í ṣe ọmọ Reu, tí í ṣe ọmọ Pelegi, tí í ṣe ọmọ Eberi, tí í ṣe ọmọ Ṣela.
36 Shelah ana vren Cayinan, ivren Arfakza, ivren Shem, ivren Noah, ivren Lamech,
Tí í ṣe ọmọ Kainani, tí í ṣe ọmọ Arfaksadi, tí í ṣe ọmọ Ṣemu, tí í ṣe ọmọ Noa, tí í ṣe ọmọ Lameki,
37 ivren Metuselah, ivren Enok, ivren Jared ivren Mahalaleel, ivren Cainan,
tí í ṣe ọmọ Metusela, tí í ṣe ọmọ Enoku, tí í ṣe ọmọ Jaredi, tí í ṣe ọmọ Mahalaleli, tí í ṣe ọmọ Kainani.
38 ivren Enos, ivren Seit, ivren Damu, Ivren Irji.
Tí í ṣe ọmọ Enosi, tí í ṣe ọmọ Seti, tí í ṣe ọmọ Adamu, tí í ṣe ọmọ Ọlọ́run.