< Ndu Manzaniba 7 >

1 Ninko Prist a tre ndi, “ikpi biyi ba janji?”
Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
2 Istifanus a tre ndi “mir ya ni bati, wo me'. Irjhi wu shulu a tsro kpama ni timbu Ibrahim, niwa ana he ni Mesopotamia, ri nda ka son ni Haran;
Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
3 A lha wu ndi “Don ngbran meme me baba mir vayime, ni rhu hini ngbran meme wandi mi tsro wu.
Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
4 Mle, a lu don ngran meme Chaldeans nda ka kru ni Haran, rhi niki, ni wa tima a qu'a, Irjh i a njiwu ye ni ngbran meme yi, wa bi ki nituma'a.
“Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
5 Ana fon nklan bubu nu du kpa zi ni h'pu mana, a'an, ko wa ani kaza satuma me. Ama, a shirhi, ko da shike Ibrahim ana he ni vivren rhina-andi ani nu bubu ti uma du mba h'puma du k'ma tiwumba kasai-kasai.
Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
6 Irjhi a si a tre niwu tyi, andi h'puma ba son ki ni gbu ndi bari u ndhi bi bgukima ba vu ba ti grand nda du ba tiya wu se derinzia.
Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
7 Ama mi sharanta ni dhi bi wa ba tindu gran nibawua, kpe wa irji tre'a hu gon kima, ba rhu don bubuki nda ye kuqungba rhu nda gbresan ni mu ni bubu yi.
Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
8 Niki Irji a nu Ibrahim shirhi wu hanbru ni duta tika, rhini kima, Ibrahim a ngrjhi Ishaku nda hanbru ma ni riwu tandra baya ngrjhi. Ishaku ngame a ngrjhi Yakubu, u Yakubu a ye ngrjhi bacimbu Wlondoha ba.
Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
9 Bacimbu ba ti ngu ni Yusufu, ba banwu le hi ni masar ama Irjhi a he ni wu.
“Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
10 nda kpa' chuwo ni ya wa a hon tuma'a. A kpayem ni Yusufu mba mren wu tondindi ni shishi kikle Ichu Firona wu Masar wa a ban wu sa ni ruron gomna wu Masar mba nitu koma wawu.
ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
11 Ni ntukima, meme iyon a ri kagon Masar mba Canaan, ni meme ya wa a du ba timbu ba wa biri hamma.
“Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
12 Niwa Yakubu a wo ndi wlo biri he ni Masar a ton ba timbu hi ni zrenmba wu mumla.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
13 Ni zren wu ha, Yusufu a tsro tuma ni ba mirvayima, u firona a mla to mmla Yusufu nikima.
Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
14 Yusufu a ton mir vayima du ba k'ma hi hla ni timba du vu mmla wawu, ndhi saba'in don ton mba, nda ye ni Masar.
Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
15 Nituki, Yakubu a grjhi hi ni Masar nda ka que niki, ni wawu ba timbu ngame.
Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
16 Ba vu ba hi ni Shekem, nda ka rhu'ba ni ibe wa titi Ibrahim a le nitu nkle silva ni wo mir Hamor wu Shekem.
A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
17 Niwa nton wa shirhi a ye weiweire, shirhi wa Irjhi a ti ni Ibrahim. Indhi ba ba ki bran gbugbuwu ni masar.
“Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
18 Da a tsra wa kikle chu ri a hon ni ruron wu masar wa ana to njo nitu Yusufu na.
Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
19 A kyurh ndhimbu nda yo ba ni gbengble du ba rhuni mir nhanha lilon mbu ni duba que.
Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
20 Ni nton kima ba ngrhi Musa, wa ka bi kpokpome ni Rji ba lura ti wua tra ni ko tima.
“Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
21 Niwa ba banwu ka zi ni ra, vrenwa Firona a ban'u ti wuma nda njiwu ti vren ma.
Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
22 Ba yo Musa ni bubu tsro mba, niki a mla to tsro ndindi nitu kpi kankan wu bi U bi masarawa ba, ndu ni he ma ba bi hikima.
A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
23 Niwa isema wu ngrjhi ba ti weiweire ni tso-tra-don nza (arbain), a kpre suron du zren hi ni mir vayi ma, ih'pu Isra'ila.
“Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
24 A krito basi ndhi Israila ri ya'. Musa alu kpa nyu ni ndhi wa basia tiwu ya'a nda wru gu masar wuh.
Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
25 A yotrendi vayima ba mla to ndhi a hi Irjhimba ni tindu ni wu du ba bguc'bu ni womba, ama ba ka'a na mla to na.
Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
26 Nivi wuhama, a to ndhi harhi ba si tsi, wa ay'e gaba nda tre ndhi, 'Lilon, be mir vayi; a hi ngye du yi ni tsi kpambi?
Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
27 Irimba wandi wa wuhi a kpa la ni kpanma'a, a tru yo kosan nda tre ndi “A nha banwu sa nitumbu ichu, wu ga tre nitawu?
“Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
28 Wu son wu U me to wandi wu wuu gu masra laren'a?
Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
29 Niwa Musa a tre yi'a, a vu tsu wru nda ka son tindi u tsir ni kasa Midian, niki a ka ngrjhi mri lon ha.
Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
30 Niwa ise tso-tsra-don-nzang ati ka hi, U malaika a tsro tuma niwu ni ngbranmiji ni kikle ngblu Sinai, ni lu ni miji.
“Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
31 Niwa Musa a to ilu'a, a ti sisir kpe wa a to ni shishima, nda lu si zren hi weiweire du ni mla ya, a kri wo ilan Baci ni tre ndi,
Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
32 Mmyi mi Irjhi wu ba timbi, Irjhi wu Ibrahim, mba Ishaku, mba wu Yakubu” Musa kri si tsenzankpa nda na la vu suron nda ya ngana.
wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
33 Baci a lhawu ndi, jhu lagban wa ahe ni za me rhu domin bubu wa wu kri mba ahi tsatra bubu.
“Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
34 Mi to iyawa basi nu ndhimu ni masra mi wo gran yimba, m'ba mi grjhiye ye chubachuwo. ye zizan, mi ton hi ni masra.
Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
35 Musa yi, wa bana kamba niwu, niwa bana tre ndi, “a nha yo tituchu mba wu ga'atre nitawu'a?” a hi wawuyi wa Irjhi a ton du hi ti chu mba wu chubachuwo. Irjhi a ton wu hi zuni wo malaika wa a tsro tuma ni Musa ni miji'a.
“Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
36 Musa njiba rhuni masra, kima a hu gon ti kpi bi wa ndhi ba kaahon to tuma, baba bi tron yani masra mba kikle ma wu Reeds, mba ni tsutsu miji niwa ba ti se tsro-tra-don-nza (arbain).
Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
37 Ahi Musa kima wa a lhani ndhi bi Israila ndi, “Irjhi ni nzu anabi ri hon yiwu rhinimi vahimbi, anabi ton me”.
“Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
38 Ndhi yi yi a he niba ni tsutsu miji mba malaika wa atre niwu nitu kikle ngblu Sinai, wa ahe niba timbu, mba wa a kpa lantre wu sisren ye nota.
Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
39 Ama ba timbu ba kamba ni hutrema, ba tru lhega wru ni kpamba, du ni misuron mba k'ma hi ni masra.
“Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
40 Ni nton kima ba lha ni Hasuna, “La' mir rjhi ni tawu wa a ni njita zren hi. Musa yi, a njita wru rhini meme masra, kina toh ikpe wa a ka tiwu a na
Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
41 Niki ba la' vrenlando ni ri baki nda nji ba hadaya (ton?) ni gunki waba la'a, nda ngiri nitu ndu wu womba.
Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
42 Irjhi a kaba chuwo du ba boata ni tsitse ni shulu, tohwa bana nha ni mi vunvu wu ba anabawaba. “Bi gon nimu nma miji mba haday ni ise tso-tsra-don-nza wa bi na he ni tsutsu miji'a ko mri Isra'ila?
Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
43 Bi kpa ka'che' molech mba ntse wu vi irjhi Rephan, mba whi ki ba biti ni du yi kugungbarhu ni nzub hon. Nikima, mi vu yi vra zan gbran Babylon.
Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
44 Ba timbu bana he ni ka'che' wu kpewa ba to ni shishimba ni tsutsumiji, me wa Irjhi a noba niwa a tre ni Musa'a, andi du ti tsra ni wa a toa.
“Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
45 Hu kima, ba timbu ni wo Joshua ana njiba to ninkomba, ba kpa ka'achea nda njiwu hu kpamba niwa ba vu meme a kpa. Irjhi a kpa meme ni wo gbungblu bi bubuki nda zu ba wru ni shishi ba timbu. kaachea a son ni meme'a ye ni nton Dawuda.
Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
46 Wa Irjhi a kpanyme ni wu nda lhawu ni du wa bubu son ni ko Yakubu.
Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
47 Ana Suleimanu mba amme ko ni Irjhi.
Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
48 Ama kitoh ndi kikle wushu na son ni ko wa wondhi mme na, toh wa anabawaba ba tre.
“Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
49 “Shulu mbahi bubu son tu chu mu, u meme mba hi kpran roro saza mu. A bibi ko rime wa bi mme ni mu inj Baci, ka a ngye bubu u kusi mu?
“‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
50 Ana womu mba ti kpi biyi wawu na?
Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
51 Biyi bi sen tu, biwa bana he kacia surona mba iton mba na, chachu bi kan bi ruhu tsatsra, bi ti to ba tumbi bana ti.
“Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
52 Ahi anabi rime wa ba timbu bana tibayana. Ba wuh anabawa wa ba wru guci ni ye ndi wa ba yo wu di 'Analatre na', u zizan biyiyi bibi le ni wu dini wu'u ngame.
Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
53 Biyi wa bi kpa doka wa malaika mba ba mla yowozi, ama bina kpa ti dun na.
Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
54 Niwa bi niko bawo kpi biyi wa ka ri ba ni suron baka tan nyren ni Istifanus.
Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
55 Don a shu ni Ruhu tsatsra, a nzu ya shulu nda toh dokaka Rji, nda to Yesu kri ni wo korhi wu Irjhi.
Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
56 Istifanus a tre ndi. “Toh, mi si to ni shishimu, shulu bwu, U vren Ndhi a kri ni worhi wu Irjhi
Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
57 Nitu ki, biwaba son ni tra son bi ninkoa ba ka tonmba, nda yo gro ni kikle lan, nda lu honwu nitu kpe riri.
Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
58 Ba gbi'e wru ni mi gbu'a, nda ni ta ni tita. Bi wa ba toh zren kpeyi ba ju nklonba wu kora nda kazi ni za vrenze ri wa ndema a hi shawulu.
wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
59 Niwa basia ta Istifanus ni tita, a sia yo baci nda ni tre ndi “Baci Yesu, kpa viri mu.
Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
60 A kuqungbarhu nda yo ni kikle lan Baci, na vule nitu latre wa ba ti yi na” Niwa a tre kle, a ku rhoku kruna
Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.

< Ndu Manzaniba 7 >