< Ndu Manzaniba 16 >
1 Bulus ngame aye ni Derbe mba ni Lystra, niki vrenko wu huuri wa ndema hi Timotia he, vren wa Yahudawa ri, wa a kpanyime niwu, ama tima ana ndji Greek.
Ó sì wá sí Dabe àti Lysra: sí kíyèsi i, ọmọ-ẹ̀yìn kan wà níbẹ̀, tí a ń pè ní Timotiu, ọmọ obìnrin kan tí í ṣe Júù, tí ó gbàgbọ́; ṣùgbọ́n Giriki ní baba rẹ̀.
2 Mri vayi wa bana he ni Lystra mba Iconium bata tre ndindi ni tuma.
Ẹni tí a ròhìn rẹ̀ ní rere lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin tí ó wà ní Lysra àti Ikoniomu.
3 Bulus ata son du zren huu ni tuki, a bau njinda gen-mbru niwu, ni du Yahudawa wa ba he ni bubu baki du ba toh, nitu bana toh ndi tima ana Greek.
Òun ni Paulu fẹ́ kí ó bá òun lọ; ó sì mú un, ó sì kọ ọ́ ní ilà, nítorí àwọn Júù tí ó wà ní agbègbè wọ̀nyí, nítorí gbogbo wọn mọ̀ pé, Giriki ni baba rẹ̀.
4 Niwa ba hu nkon si hi zu nimi gba ba, basia zren nihu nkon tsatsra wa manzani ba mba bi ninkon biwa ba he ni Urushelima ba m'ha yo duba hu.
Bí wọn sì ti ń la àwọn ìlú lọ, wọ́n ń fi àwọn àṣẹ, tí a tí pinnu láti ọ̀dọ̀ àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tí ó wà ní Jerusalẹmu, lé wọn lọ́wọ́ láti máa pa wọ́n mọ́.
5 Niki ekklisiya ba ba kpa ti ngbengblen ni kri gbangban nitu hu nkon'a nda du kri mbru mba a si hon chachu.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìjọ sì fẹsẹ̀múlẹ̀ ní ìgbàgbọ́, wọn sí ń pọ̀ sí i ní iye lójoojúmọ́.
6 Bulus mba bi zren niwu ba zren zu ni ngbran Phrygia mba Galatia, nitu Ruhu Tsatsra ana ti gbuchu ndi du ba na d'bu lan tre'a ni ngbran Asia na.
Wọ́n sì la agbègbè Frigia já, àti Galatia, nítorí tí Ẹ̀mí Mímọ́ kọ̀ fún wọn láti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Asia.
7 Niwa ba zren ye ti weiweire ni Mysia, ba yo sron zuni Bithynia, ama Ruhu Yesu a zuba.
Nígbà tí wọ́n dé ọ̀kánkán Misia, wọ́n gbìyànjú láti lọ sí Bitinia, ṣùgbọ́n Ẹ̀mí Jesu kò gbà fún wọn.
8 Niki ba vu Mysia y'ba nda grjiye ni gbu Troas.
Nígbà tí wọ́n sì kọjá lẹ́bàá Misia, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Troasi.
9 Bulus a toh ni mira ni chu; ndji ri wu Macedonia a kri ki nda si bre'u nda ni tre ndi, “Ye nita ni Macedonia ni ye zota.”
Ìran kan si hàn sì Paulu ni òru, ọkùnrin kan ará Makedonia dúró, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Rékọjá wá sí Makedonia, kí o sí ràn wá lọ́wọ́!”
10 Niwa wa Bulus a hrara toki, ki krilu si wa nkon wuhi ni Macedonia, nitu ki ban ndi Irji mba yo ta du ta ki hi bla tre ndindi ni bawu.
Nígbà tí ó sì tí rí ìran náà, lọ́gán ó múra láti lọ sí Makedonia, a ka á sí pé, Ọlọ́run tí pè wá láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
11 Ki kuu zren hu ni nkon ma rhini Troas, ki hu trime nkon wa ani njita zu ni Samothrace, nda duta ka rhini Neapolis ni mbewa aka wu vi kima.
Nítorí náà nígbà tí àwa ṣíkọ̀ ní Troasi a ba ọ̀nà tààrà lọ sí Samotrakea, ni ọjọ́ kejì a sì dé Neapoli;
12 Rhiniki, ki hi ni Philippi, wandi ana kikle gbu wu Macedonia, gbu wa a zan bi ni ndu wu ngbran kima mba wa aheni wo bi tuchu wu Romawa; ki ki niki wu vi wa a fon bran.
láti ibẹ̀ àwa sì lọ si Filipi, tí í ṣe ìlú Makedonia, olú ìlú ìhà ibẹ̀, ìlú lábẹ́ Romu, àwa sì jókòó ní ìlú yìí fún ọjọ́ mélòó kan.
13 Ni vi Sabbath (Chachu Sati), ki zren rhu ni kikle nkontra gbu'a wa a he ni kosan ba'a, bubu wa ki ban ndi ani bi wu bre. Ki kukhi ni tre ni mmba wa ba ye zontu ki'a.
Lọ́jọ́ ìsinmi, àwa sí jáde lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà, lẹ́bàá odò kan, níbi tí a rò pé ibi àdúrà wà; àwa sí jókòó, a sì bá àwọn obìnrin tí o péjọ sọ̀rọ̀.
14 Iwari wu nde Lydia, wa a ta le ni ikpi nklon sru, rhi ni gbu Thyatira, wa ata hu nkon Irji, a yo ton si wota. Bachi a bwu sron ma ni du mla wo kpe wa Bulus asia tre'a.
Àti obìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Lidia, elése àlùkò, ará ìlú Tiatira, ẹni tí ó sin Ọlọ́run, ó gbọ́ ọ̀rọ̀ wa, ọkàn ẹni tí Olúwa ṣí láti fetísí ohun tí a tí ẹnu Paulu sọ.
15 Niwawu mba bi koma, ba kpa batisma, nda bre ta ndi, “Bita kpanyme ni me ndi mi kri gbangban ni hu nkon Bachi, bi ka ye ni komu.” Nikima a weireta du ta kpanyme.
Nígbà tí a sí bamitiisi rẹ̀, àti àwọn ara ilé rẹ̀, ó bẹ̀ wá, wí pé, “Bí ẹ̀yin bá kà mí ni olóòtítọ́ sí Olúwa, ẹ wá si ilé mi, kí ẹ sí wọ̀ níbẹ̀!” O sí rọ̀ wá.
16 Niwa ki sia hi bubu bre, vrenwa ri wa ana gran, nda he ni brji wu toh kpe nda nran, a ye zontu nita. A ta nji nklen gbugbuwu ye ni ti ko ma nitu ndu nran wa ata ti'a.
Bí àwa tí n lọ sí ibi àdúrà náà, ọmọbìnrin kan tí o ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ, pàdé wa, ẹni tí ó fi àfọ̀ṣẹ mú èrè púpọ̀ wá fún àwọn ọ̀gá rẹ̀.
17 Iwa yi a zren si huba Bulus nda d'bu si hla ndi, “Biyi bi mri koh wu Irji wa a zan nzu hon. Ba ki bla nkon wu kpachuwo ni yiwu.”
Òun náà ni ó ń tọ Paulu àti àwa lẹ́hìn, ó sì ń kígbe, pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ń kéde ọ̀nà ìgbàlà fún yin!”
18 Asi ti toyi wu vi gbugbuwu. Ama Bulus, nitu vrenwa a yo nfu branbran, a k'ma nda hla ni brji'a ndi, “Mi mmha'u ni nde Yesu Kristi, rju ni kpa ma.” Mle a rju ni nton kima.
Ó sì ń ṣe èyí lọ́jọ́ púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí inú Paulu bàjẹ́, tí ó sì yípadà, ó wí fún ẹ̀mí náà pé, “Mo pàṣẹ fún ọ ní orúkọ Jesu Kristi kí o jáde kúrò lára rẹ̀!” Ó sí jáde ni wákàtí kan náà.
19 Niwa bi ti koma ba toh ndi nkon kubu mba a kle, ba vu Bulus mba Sila nda gbi ba hi ni tsutsu bubu wa ba le ni kpi, niwa bi ninkon gbu ba ki'a.
Nígbà tí àwọn ọ̀gá rẹ̀ sì rí i pé, ìgbẹ́kẹ̀lé èrè wọn pin, wọ́n mú Paulu àti Sila, wọn sì wọ́ wọn lọ sí ọjà tọ àwọn aláṣẹ lọ.
20 Niwa ba nji ba ye nu bi blatre (Alkali), ba tre ndi ndji biyi ba nji iya rini kikle gbumbu. Ba Yahudawa.
Nígbà tí wọ́n sì mú wọn tọ àwọn onídàájọ́ lọ, wọ́n wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí tí í ṣe Júù, wọ́n ń yọ ìlú wa lẹ́nu jọjọ,
21 Ba bla tre njo wa ana he nitu nkon wa Romawa ba kpanyme duta hu na.
wọ́n sì ń kọ́ni ní àṣà tí kò yẹ fún wa, àwa ẹni tí í ṣe ara Romu, láti gbà àti láti tẹ̀lé.”
22 Niki kpaandji ba lu hon wawu mba, nitu Bulus mba Sila; Alkali ba ba y'ba ba nklon mba ju nda mmha duba hloba ni kunkron j'bo.
Ọ̀pọ̀ ènìyàn sí jùmọ̀ dìde sì Paulu àti Sila. Àwọn olórí sí fà wọ́n ní aṣọ ya, wọ́n sí pàṣẹ pé, ki a fi ọ̀gọ̀ lù wọ́n.
23 Niwa ba hloba ni wo gbugbu nitu mba, ba tru ba sru ni ko wu tru nda mmha ndji wu tro'a du mla yo shishi nda na du ba gbuj'bu na.
Nígbà tí wọ́n sì lù wọ́n púpọ̀, wọ́n sọ wọ́n sínú túbú, wọ́n kìlọ̀ fún onítúbú kí ó pa wọ́n mọ́ dáradára.
24 Hu gon kpa mmha yi, ndji wu tro'a, a tru ba sru ni tra wu komi nda vu ba za mba lo nha ni kunkron gbangban.
Nígbà tí ó gbọ́ irú ìkìlọ̀ bẹ́ẹ̀, ó sọ̀ wọ́n sínú túbú tí inú lọ́hùn, ó sí kan àbà mọ wọ́n lẹ́sẹ̀.
25 Mla tsutsu chu, Bulus mba Sila ba sia bre Irji nda ni yo se wu nzu Irji hon, i mbru biwa ba tro ba ngame'a ba sia sren ton niba.
Ṣùgbọ́n láàrín ọ̀gànjọ́ Paulu àti Sila ń gbàdúrà, wọ́n sì ń kọrin ìyìn si Ọlọ́run, àwọn ara túbú sì ń tẹ́tí sí wọn.
26 Niki, kikle grju meme a lu ti, nda du nchimeme wu ko tro a grju, mlee nkon ba wawu ba bwu yo hwo, mba ba sraka wa ba lo ba niwu'a ba si hle.
Lójijì ilẹ̀ mímì ńlá sì mi, tó bẹ́ẹ̀ tí ìpìlẹ̀ ilé túbú mì tìtì: lọ́gán, gbogbo ìlẹ̀kùn sì ṣí, ìdè gbogbo wọn sì tú sílẹ̀.
27 Igu wu troba'a a lu sh'me ni nna nda toh nkontra kotro ba ba bwu kri ni hwo, a gbron guglo Inji wu nduma ndani wuutuma, nitu a ban ndi biwa ba troba ba rju nawo ye.
Nígbà tí onítúbú si tají, tí o sì ri pé, àwọn ìlẹ̀kùn túbú tí ṣí sílẹ̀, ó fa idà rẹ̀ yọ, ó sì fẹ́ pa ara rẹ̀, ó ṣe bí àwọn ara túbú ti sálọ.
28 Bulus a yo gro ni kikle lan nda tre ndi, “Na ti kpame kpe na, nitu wawu mbu ki he ni wayi.”
Ṣùgbọ́n Paulu gbé ohun rẹ̀ sókè, wí pé, “Má ṣe pa ara rẹ lára: nítorí gbogbo wa ń bẹ níhìn-ín yìí!”
29 Igu wu troba a yo duba nji ilu kpan njiwu, nda tsutsu ri ni tsenza kpa mba sissri nda ka kukru ni shishi Bulus mba Sila.
Nígbà tí ó sì béèrè iná, ó bẹ́ wọ inú ilé, ó ń wárìrì, ó wólẹ̀ níwájú Paulu àti Sila.
30 Nda nji ba rju nda tre ndi, “Mi nuyi ninkon, mi ti ngye ni dumi kpa tumu chuwo?”
Ó sì mú wọn jáde, ó ní, “Alàgbà, kín ni ki èmi ṣe ki n lè là?”
31 Ba tre ndi, “kpanyme ni Bachi Yesu, niki wu kpa kpachuwo, ni wu baba biwa ba he ni ko me.”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Gbá Jesu Kristi Olúwa gbọ́, a ó sì gbà ọ́ là, ìwọ àti àwọn ará ilé rẹ pẹ̀lú.”
32 Ba hla lan tre wu Bachi niwu, baba ni ko nha ni mi koma.
Wọ́n sì sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un, àti fún gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀.
33 Niki, igu wu tro'a a vu ba ni nton kima wu chu'a, nda ka ngla mkpan mba, niki wawu mba bi koma wawu ba ti batisma ni bawu.
Ó sì mú wọn ní wákàtí náà lóru, ó wẹ ọgbẹ́ wọn; a sì bamitiisi rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ lójúkan náà.
34 Niwa a nji ba Bulus mba Sila hon hi ni koma nda ka nuba biri, a ta kpe kpukpome, ni ndji biwa ba he ni koma'a, nitu a kpanyme ni Irji.
Ó sì mú wọn wá sí ilé rẹ̀, ó sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú wọn, ó sì yọ̀ gidigidi pẹ̀lú gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, nítorí ó gba Ọlọ́run gbọ́.
35 Zizan, niwa mble a nhran, alkali ba ba ton du hi ni bi gben'a, ndi “Du ndji bi mba hi kpamba.”
Ṣùgbọ́n nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn onídàájọ́ rán àwọn ọlọ́pàá pé, “Tú àwọn ènìyàn náà sílẹ̀.”
36 Igu wu tro a vu lan tre ba bla ni Bulus mba Sila andi, “Alkali baba ton lan tre ye ni me ndi du mi du yi hi. Zizan nikima, ye rju hi yi ni si sron.”
Onítúbú sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Paulu, wí pé, “Àwọn onídàájọ́ ránṣẹ́ pé kí á da ìwọ àti Sila sílẹ̀. Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jáde kí ẹ sì máa lọ ní àlàáfíà.”
37 Ama Bulus a hla bawu ndi, “Ba vuta hlo tsi ni shishi ndji, hamma ni tsra ta toh, niwa me ki mri son meme Roma, nda tru ta sru ni kotro, zizan ba son juta rju ni rhiri? A'a! Du ba ye kimba nda ye njita rju.”
Ṣùgbọ́n Paulu wí fún wọn pé, “Wọ́n lù wá ni gbangba, wọ́n sì sọ wá sínú túbú ni àìjẹ̀bi, àwa ẹni tí ì ṣe ara Romu. Ṣe nísinsin yìí wọ́n fẹ́ tì wá jáde níkọ̀kọ̀? Rara! Ṣùgbọ́n kí àwọn tìkára wọn wá mú wa jáde!”
38 Bi gben ba baka vu tre biyi bla ni ba alkali ba, niwa ba wo ndi Bulus mba Sila ba mri gbungblu Roma, ikpe'a anuba sissri.
Àwọn ọlọ́pàá sì sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn onídàájọ́: ẹ̀rù sì bà wọ́n, nígbà tí wọ́n gbọ́ pé ará Romu ni Paulu àti Sila.
39 Alkali ba ba ye bre ba nda nji ba rju, nda bre du ba rju ni gbu'a hi kpamba.
Wọ́n sì wá, wọ́n ṣìpẹ̀ lọ́dọ̀ wọ́n, wọn sì mú wọn jáde, wọ́n sì bẹ̀ wọ́n pé, ki wọn jáde kúrò ni ìlú náà.
40 Niki, Bulus mba Sila ba rju ni ko tro'a nda ye ni ko Lydia. Niwa ba Bulus mba Sila ba to mri vayi ba, ba nhronba duba ki gbangban, nda mle, rju hi kpamba rji ni gbu'a.
Paulu àti Sila sì jáde nínú túbú, wọ́n sì wọ ilé Lidia lọ, nígbà tí wọn sì tí rí àwọn arákùnrin, wọ́n tù wọ́n nínú, wọn sì jáde kúrò.