< 2 Pita 1 >

1 sima Bitru igra nivren u tondu yesu kristi ba yarson christi ni bi aw kikpa. yosron ni mi ti ndi ndi trsimbu ni yesu almasihu.
Simoni Peteru, ìránṣẹ́ àti aposteli Jesu Kristi, Sí àwọn tí ó gba irú iyebíye ìgbàgbọ́ kan náà pẹ̀lú wá nínú òdodo Ọlọ́run wa àti ti Jesu Kristi Olùgbàlà:
2 ni ndu ti ndindi ndu sisron bi nho nigon u toh ijri ni yesu bachiimbu.
Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sí i fún yín nínú ìmọ̀ Ọlọ́run àti ti Jesu Olúwa wa.
3 didi ikpi bi sisenri ndidima a nota ntu toh irji wadi a ota zu ni gbiresan u bima.
Bí agbára rẹ̀ bí Ọlọ́run ti fún wa ní ohun gbogbo tí a nílò fún ṣe ti ìyè àti ti ìwà-bí-Ọlọ́run, nípa ìmọ̀ ẹni tí ó pè wá nípa Ògo àti ìṣeun rẹ̀.
4 ni tuki a yo nyu bi rigmar didima nita wu du khi kpande ubu ni irji. wa khi dju nimi memeteh u ibrji ni gbublua wa a ii ye u sorkpa
Nípa èyí tí ó fi àwọn ìlérí rẹ̀ tí ó tóbi púpọ̀ tí ó ṣe iyebíye fún wa: pé nípa ìwọ̀nyí ni kí ẹ̀yin lè di alábápín nínú àbùdá ti Ọlọ́run, nígbà tí ẹ̀yin bá ti yọ kúrò nínú ìbàjẹ́ tí ó ń bẹ nínú ayé nípa ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
5 ni tu naki bi ka ti mi gbengbene bi ni ndu tie ndi ndi ni tie ndindi ni yosron bi ndu nho.
Àti nítorí ìdí èyí, ẹ máa ṣe àìsimi gbogbo, ẹ fi ìwà rere kún ìgbàgbọ́, àti ìmọ̀ kún ìwà rere;
6 ni vutu ni tu yotutya bi be ka yotutya nivu sonyo ni mi vu sonro bi ka yotu ni hwu irji.
àti àìrékọjá kún ìmọ̀; àti sùúrù kún àìrékọjá; àti ìwà-bí-Ọlọ́run kún sùúrù.
7 ni mi hwu irji br ka yotu ni son bebeh umrivyayi ni tu son bebe u mrivayi ni tu son bebe u umrivayi be ka yoyu ni son kpabi.
Àti ìfẹ́ ọmọnìkejì kún ìwà-bí-Ọlọ́run; àti ìfẹ́ni kún ìfẹ́ ọmọnìkejì.
8 ikpi beyi ba ta he nimi bi; u ba gbronni mi bi indji ribi na kudjur na ni tui toh u irji bu yesu Almasihu sun ni krju ko ka sun hanma ni ngrji na ni toh bachrimbr yesu.
Nítorí bí ẹ̀yin bá ní nǹkan wọ̀nyí tí wọ́n bá sì pọ̀, wọn kì yóò jẹ́ kí ẹ ṣe ọ̀lẹ tàbí aláìléso nínú ìmọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.
9 indji wa a wabi kpi yi hanama ani ya ikpe wa ahe whiwhir mi gen kawa yar shishi. a kpa ri su andi ba ngwala rju ni mi min chiche latre mba
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe aláìní nǹkan wọ̀nyí, kò lè ríran ní òkèèrè, ó fọjú, ó sì ti gbàgbé pé a ti wẹ òun nù kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àtijọ́.
10 nit kima mrivaye bi ka te ni gbegble bi wawu de toh ni yao bia ni chur bia beta ti kpi beyi be na kubuza na
Nítorí náà, ará ẹ túbọ̀ máa ṣe àìsimi láti sọ ìpè àti yíyàn yín di dájúdájú, nítorí bí ẹ̀yin bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, ẹ̀yin kì yóò ṣubú.
11 naki u be ka sami ri ni ko irji bu wa a kpatata chuwoa yesu yesu almasihu (aiōnios g166)
Nítorí báyìí ni a ó pèsè fún yín lọ́pọ̀lọ́pọ̀ láti wọ ìjọba àìnípẹ̀kun ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jesu Kristi. (aiōnios g166)
12 ni tu nakima me son si gbeh chachu de ti yi kaa ni yu kpi be yi me toh de be toh mba naki u be ka tigbegble ni najaaji u zezah.
Nítorí náà, èmi ó máa rán yin létí àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ti mọ̀ wọ́n, tí ẹsẹ̀ yín sì múlẹ̀ nínú òtítọ́ tí ẹ ní báyìí.
13 ime me rimeren naki du mi chon yi du yi tika ni kpi be yi u me rihe ni mi kpayi.
Èmi sì rò pé ó tọ́ láti máa mú wọn wá sí ìrántí yín, níwọ̀n ìgbà tí èmí ba ń bẹ nínú àgọ́ ara yìí.
14 mi toh ni vi nton tsa me mi ka ikpa yi don na wa yesu Almasihu a tsoro me.
Bí èmi ti mọ̀ pé, bíbọ́ àgọ́ ara mi yìí sílẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀, àní, bí Olúwa wa Jesu Kristi ti fihàn mí.
15 me ti ni gbegble mu chachu du yi kata tika ikpi beyi a u meta kayi don.
Èmi ó sì máa ṣaápọn pẹ̀lú, kí ẹ̀yin lè máa rántí nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo lẹ́yìn ikú mi.
16 ni tu khita khi na hwu ibaltre u wuri mba na u khi hla ni yiwa gbegble ni ye irji bu yesu Almasihu u khta khto gbegble ma.
Nítorí kì í ṣe bí ẹni tí ó ń tọ ìtàn asán lẹ́yìn tí a fi ọgbọ́nkọ́gbọ́n là sílẹ̀, nígbà tí àwa sọ fún yín ní ti agbára àti wíwá Jesu Kristi Olúwa, ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí ọláńlá rẹ̀ ni àwa jẹ́.
17 na kima a kpah gibresan u bima ni irji ite bu niton wa nlan a ye ni mi gegble u gbiresan da tere e wayi wa weh a hi iveremu u sonmu wa ani sime sonro u njaaji.
Nítorí tí Ó gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba, nígbà tí irú ohùn yìí fọ̀ sí i láti inú ògo ńlá náà wá pé, “Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
18 ki wo lan yirji shu niton wa ki na he baba ni tita u tsatsra.
Àwa pẹ̀lú sì gbọ́ ohun yìí tí ó ti ọ̀run wá nígbà tí àwa wà pẹ̀lú rẹ̀ ní orí òkè mímọ́ náà.
19 khi he ni ilan tere wa khi toh ani ye njaaji khi ta yo soron ni mba ani he na ilu wa a ni kpah ni bua na tsitse wa ani kpah ni buu ble ani kpah ni mi sunron bi.
Àwa sì ní ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì dunjúdunjú sí i, èyí tí ó yẹ kí ẹ kíyèsi gẹ́gẹ́ bí fìtílà tó ń mọ́lẹ̀ níbi tí òkùnkùn gbé wà, títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, tí ìràwọ̀ òwúrọ̀ yóò sì yọ lọ́kàn yín.
20 bika to wayi arjini mumla mu andi be toh kima ni mumlamu ba idi. wawuu a tozu na he ni tu kpeiri zan indji mla du toh ba hla itereri wa ani na ye ni kpakyeme u idi u idi tu tere
Ju gbogbo rẹ̀ lọ, kí ẹ ní òye yìí pé kò sí àsọtẹ́lẹ̀ ìwé mímọ́ kankan tí ó wáyé nípa ìtumọ̀ wòlíì fún rara rẹ̀.
21 ba nati bre tozu ni sonsron ni tu irji wa mba he niibrji u tsa indji na ni ndu he naki a hi a hi brji tsatsra mba ni yo ba ni ndu ba latre rii.
Nítorí àsọtẹ́lẹ̀ kan kò ti ipá ìfẹ́ ènìyàn wá rí; ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ń sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bí a ti ń darí wọn láti ọwọ́ Ẹ̀mí Mímọ́ wá.

< 2 Pita 1 >