< Ludi 4 >

1 Boua: se e sia: sa: imusa: gilisibi sogebi amoga asili amola logo gadenene amogai esalu. Amogai esaloba amola Ilimelege ea gadenene fi dunu (bu bidi lasu fi dunu ilia da sia: su - da: i sia: da ‘kinsman-redeemer) amo mafiadalebe ba: i. Amola Boua: se ea e wele sia: i, “Na na: iyado! Di fila misa. Na da sia: fonobahadi sia: mu gala.” Amalalu, e da misini fi.
Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
2 Amanoba, Boua: se e bu bidi lasu dunu amo e da musa: sia: i ema amane sia: i, “Di gui fila misa.” Amanoba, e da misini bulagi.
Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
3 Amalalu, Boua: se da moilai ouligisu dunu nabuane lale, Ilimelege ea bu bidi lasu fi dunu ema amane sia: i, “Na: ioumi da waha Moua: be soge yolesili, misi dagoi. E da ania sosogo fi dunu Ilimelege amo ea soge bidi lamu hanai galebe.
ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
4 Amaiba: le, na dima sia: be goea, be di hanai galea, goe soge di lama. Fada: i dunu nabuane agoane ilia dia sia: nabima: ne sia: ma. Be higa: i galea amo higa: i fawane sia: ma. Bai di da hanai galea, di da lamu defele gala. Be dia higasea, na da lamu defele gala.” Ilimelege ea bu bidi lasu fi dunu e da amane sia: i, “Na da lamu!”
Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
5 Boua: se e amane sia: i;, “Defeadafa! Be dia Na: ioumi ea soge lasea, di da Ludi (Moua: be uda didalo) amola bidiga lasa. Amasea, amo soge da bogoi ea sosogo fi amo ganodini dialumu.
Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
6 Amanoba, bu bidi lasu fi dunu da amane sia: i, “Amai galea, na amola soge agoe bidiga lamu, be amo da agoane, na mano ilia soge hame galumu. Amaiba: le dia lama. Be Na da bu hame lamu.”
Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
7 Amo esoha ilia da hou agoane hamosu. Isala: ili ilia sia: sa: imusa: o bu afadenemusa: ilia amola da hou agoane hamosu. Dunu afae da ea emo salasu gisa: le, dunu eno igili iasu. Amo hou da Isala: ili fi dunu ilia hou. Ilia da bidi lasu hou ilegema: ne agoane hamosu.
Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
8 Amabeba: le, amola Ilimilege ea bu bidi lasu fi dunu da Boua: se ema amane sia: i, “Di bidiga lama!” E da ea emo salasu gisa: le amola Boua: sema i.
Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
9 Amalalu, Boua: se e dunu fada: i ilima amola oda esalebe dunu ilima amane adoi, “Dilia huluane ba: ma! Amola waha da na Na: ioumi ea soge amo Ilimelege amola ea mano Gilione amola Malone ilia soge, amo na bidiga lai dagoi.
Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
10 Amola na da sia: fonobahadi sia: mu gala. Na agoane dawa: Ludi e da na uda esalumu da defea. Ludi amo uda da Moua: be dunu fi amola Malone ea lai galu, be Malone e bogobeba: le yolesi. Na da Ludi lamu hanai galebe, amola Malone ea sosogo fi da ea soge gaguiwane dialumu. Amola egaga fi da ea fidafa amola ea moilaidafa amo ganodini fifi lamu. Amola amo hou hahamoi amo dili huluane ba: i ama.
Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
11 Dunu huluane ilia amane sia: i, “Defea! Amo ilegele hou ninia da ba: i dagoi.” Amola fada: i dunu huluane da amane sia: i, “Goe uda waha dia diasu ganodini misi, amo da Hina Gode amo Hi fawane da La: isele amola Lia elea esoa: fi Isala: ili fi ganodini hamoi defele ema hamomu. Ela da Ya: igobema mano bagohame lai. Ludi da ela defele hamomu da defea. Amola difawane da liligi bagade gagui agoane hamoma. Efala: de fi amo ganodini amola di da Bedeleheme moilai fi ganodini fada: i dunu agoane esaloma.
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
12 Amola dia sosogo fi da bagadewane heda: mu da defea. Di da amo a: fini didalo lasea, Hina Gode da alima mano bagohame imunu da defea. Amasea, dia sosogo fi da Yuda amola Da: ima elea mano Bilese amo ea sosogo fi hamoi amo defele ba: mu.
Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
13 Amanoba Boua: se ea Ludi lale, ea diasuga oule asi. Be Hina Gode da ema hahawane dogolegele amola asigili hamobeba: le, e abula agui ba: i amola dunu mano lalelegei.
Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
14 Uda ilia da misini, Na: ioumima amane sia: i, “Hahawane Hina Godema nodoma! E da waha dia aowa lalelegei amo da di ouligima: ne. Amola amo mano da Isala: ili fi amo ganodini gasa bagade esaluma: mu.
Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
15 Disoa: ea amola da dima asigisa amola ea dima fidisu hou da dunu mano fesuale gala ilia fidisu hou baligi dagoi. Amola e da wali dima aowa i dagoi. Amo da dia da: i hamobe amo ganodini e da di noga: le ouligimu.”
Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
16 Na: ioumi ea mano amo seba: le, amola noga: le fofoi.
Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
17 Amola uda gadenene fi misini, mano ea dio Oubede asuli. Ilia dunu huluane ilima adoi, “Na: ioumi e da dunu mano lalelegei dagoi!” Amola Oubede da asigilale amola mano ea dio amo Yesi lai. Yesi da Da: ibidi lalelegei.
Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
18 Goe da Bilese ea sosogo fi asili Da: ibidima doaga: i hou. Bilese amo da Heselone ea ada, Heselone e da Lame ea ada, Lame da A: minada: be ea ada, A:minada: be e da Nasone ea ada, Nasone da Sa: lamone ea ada, Sa: lamone da Boua: se ea ada, Oubede da Yesi ea ada, amola Yesi e da Da: ibidi ea ada. Amo fi da amane fifi misi goa. Sia: ama dagoi
Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.

< Ludi 4 >