< Idisu 24 >
1 Be wali, Ba: ila: me da Hina Gode da Ea Isala: ili dunu ilima hahawane dogolegele aligima: ne ilegemu fawane hanai, amo e dawa: i galu. Amaiba: le, ea musa: hou defele hame hamoi. E da dawa: digima: ne olelesu liligi amo hogomusa: hame asi. E da hafoga: i soge ba: musa: sinidigili,
Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
2 Isala: ili dunu ilia fisisu ba: i. E da ilia sosogo fi afae afae dafulili esalebe ba: i. Gode Ea A: silibu Hadigidafa da ema aligila sa: ili,
Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3 e da amo ba: la: lusu sia: i, “Ba: ila: me, Bio ea mano, da moloiwane ba: sa. Ea sia: da agoane gala.
ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
4 Nowa da Gode Ea sia: dalebe nababela: ? Na da si godonasini agoane sosodosa. Na da esala ba: lala, Gode Bagadedafa da nama olelesa.
àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
5 Isala: ili ilia abula diasu da isisima: goi ba: sa.
“Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
6 Ilia da gumudi yobo dadalei sedade defele. O ifabi hano bega: bugi agoane ba: sa. Ilia da gabusiga: ifa Hina Gode Ea bugi defele, o dolo ifa, hano bega: lelebe agoane ba: sa.
“Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
7 Ilia da gibu dabe bagade ba: mu. Ilia da hawa: amo nasegagi hano bagade soge ganodini bugimu. Ilia hina bagade da A: iga: ge ea hou bagadewane baligimu. Ea ouligisu hou da soge bagohame amoga heda: mu.
Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 Gode da ili Idibidi sogega fisili masa: ne, oule misi. E da sigua bulamagau defele, ili fidima: ne gegenana. Ilia da ilia ha lai dunu amo na dagosa. Ilia da ilia gasa goudasa amola ilia dadi wadela: lesisa.
“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
9 Isala: ili fi da gasa bagade laione wa: me agoane. E da golai dialea, dunu eno da beda: iba: le, hamedafa didilisisa. Nowa da Isala: ili hahawane dogolegelewane aligima: ne ilegesea, da Gode Ea hahawane dogolegesu ba: mu. Amola nowa da Isala: ili ilima gagabusu aligima: ne ilegesea, da amo gagabusu sinidigili hihima aligima: ne ilegei dagoi ba: mu.”
Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Ba: ila: ge da ougili ea lobo usuna gaguli, Ba: ila: mema amane sia: i, “Na da di na ha lai dunu amo gagabusu aligima: ne ilegema sia: i. Be udiana agoane di da amo mae hamone, ilima Gode Ea hahawane dogolegesu hou aligima: ne sia: i dagoi.
Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
11 Dia diasuga masa! Na da dima bidi bagade imunu sia: i. Be Hina Gode da dia amo bidi lama: ne logo hedofai dagoi.”
Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
12 Ba: ila: me da bu adole i, “Na da sia: ne iasu dunu di nama asunasi ilima olelei, amane,
Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
13 ‘Ba: ila: ge da silifa amola gouli ea hina bagade diasu ganodini gala amo huluanedafa nama ia: noba, na da ni hanaiga Hina Gode Ea hamoma: ne sia: i fonobahadi nama sia: i amo giadofamu da hamedela: loba. Na da Hina Gode Ea nama sia: i liligi fawane bu sia: mu.”
‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
14 Ba: ila: me da Ba: ila: gema amane sia: i, “Na da wali na fidafa amoga buhagimu. Be hidadea, na da dima sisasu sia: mu. Amalu da fa: no Isala: ili dunu ilia hou dia fi dunuma hamomu, amo na da dima sia: mu.”
Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
15 Amalalu, e da amo ba: la: lusu amane sia: i, “Ba: ila: me, Bio ea mano, da moloiwane ba: sa. Ea sia: da agoane gala.
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 Na da Gode Ea sia: dalebe naba. Na da si godonasini agoane sosodosa. Na da esalebe ba: lala, Gode Bagadedafa da nama olelesa.
ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
17 Na da hobea misunu hou ba: la: lala. Na da Isala: ili fi ba: sa. Hina Bagade dunu, hadigi bagade gasumuni agoai, amo fi ganodini heda: lebe ba: mu. E da ofa: su gasumuni defele Isala: ili sogega misunu. E da Moua: be ouligisu dunu famu amola Sede soge dunu amo banenesimu.
“Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 E da ea ha lai dunu Idome sogega esala amo hasalili, ilia soge huluane suguli lamu. Amola Isala: ili dunu da hasaliliwane masunu.
Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Isala: ili fi dunu da ilia ha lai amo osa: le heda: le, dunu hame bogoi esalebe, amo huluane fane legemu.”
Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20 Amalalu, Ba: ila: ge da ea esala ba: su amo ganodini A: malege fi ba: lalu, amane ba: la: lusu sia: i, “A: malege ea gasa bagade hou da eno fi huluane baligi dagoi. Be fa: no e da gugunufinisi dagoi ba: mu.”
Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Amalalu, Ba: ila: ge da ea esalebe ba: su amo ganodini, Ginaide dunu fi ba: i. E da amo ba: la: lusu sia: i, “Dia esalebe sogebi da gaga: i dagoi. Sio ea bibi da gafulu bagade amoga bibiba: le, eno liligiga wadela: lesimu hamedei.
Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 Be dilia Ginaide dunu da gugunufinisi dagoi ba: mu. Bai Asilia dunu da dili doagala: le, suguli lamu.”
síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
23 Ba: ila: me da eno ba: la: lusu amane sia: i, “Dunu da gadili (north) amogawi gilisilalebe da nowa dunula: ?
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Doagala: su golili dasu dunu da Saibalase sogega, dusagai ganodini manebe ba: mu. Ilia da Asilia amola Ibe amo hasalimu. Be Saibalase dunu amola da fa: no gugunufinisi dagoi ba: mu.”
Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Amalalu, Ba: ila: me da momagele, hi diasuga buhagi. Amola Ba: ila: ge da hi logoga asi.
Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.