< Luge 1 >
1 Amo sia: , na da di Diobalase, dima dedei. Ninima masu hou olelema: ne, dunu bagohame da logo hogoi helele, dedei.
Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa,
2 Am hou musa: ba: su dunu amola Gode Ea sia: olelesu dunu amo ilia adoi, ilia dedei.
àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́.
3 Amaiba: le, amo hou ea bai na musa: amola fa: no hogoi helebeba: le, na da sia: moloiwane dima dedemusa: dawa: i galu.
Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ,
4 Amo hou huluane dia nabi, amo di noga: le dawa: ma: ne, na da amo meloa dedesa.
kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.
5 Yudia soge hina bagade dunu, ea dio amo Helode, amo dunu esalebe galu, gobele salasu dunu fi Abaidia amo ganodini, gobele salasu dunu ea dio amo Segalaia esalu. Ea uda ea dio amo Ilisabede. Amo ea fi da Elane gobele salasu fi.
Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti.
6 Ela da Gode ba: ma: ne, eso huluane hou ida: iwane hamosu. Gode Ea Sema huluane ela nabawane hamosu.
Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn.
7 Ilisabede da aligimeba: le amola ela da da: i hamoiba: le, ela da mano hame galu.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.
8 Eso afaega, Abaidia fi ilia Debolo ouligisu hawa: hamonanu. Segalaia da ea ilegei esoha amoga gobele salasu hawa: hamonanu.
Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀.
9 Gobele salasu hina dunu da ema ilegeiba: le, e da oloda da: iya gabusiga: manoma gobemusa: , Hina Gode Ea Debolo Diasu ganodini golili sa: i.
Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
10 Dunu bagohame da gabusiga: manoma gobele salasu dawa: ma: ne, gadili sia: ne gadosa lelefulu.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.
11 Amalalu, Gode Ea a: igele dunu misini, gobele salasu oloda ea lobodafa la: didili amoga dafulili lelebe ba: i.
Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí.
12 Segalaia da a: igele dunu ba: loba, fofogadigili, bagadewane beda: i.
Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á.
13 Be a: igele da ema amane sia: i, “Segalaia! Di mae beda: ma! Gode da dia sia: ne gadoi nababeba: le, Ilisabede da dunu mano lalelegemu. Ema Yone dio asulima.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu.
14 E da lalelegesea, di da hahawane bagade ba: mu. E lalelegebeba: le, dunu bagohame da nodone sia: mu.
Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ, ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ.
15 E da Hina Gode ba: ma: ne, gasa bagade hamomuyo. E da adini amola wadela: i hano hamedafa manu. E lalelegesea, hedolowane Gode Ea A: silibu amoga ea dogo da nabaiwane ba: mu.
Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá.
16 Ea sia: nababeba: le, Isala: ili fi dunu bagohame ilia sinidigili, ilia Hina Godema buhagimu.
Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
17 E da Hina Godema bisili masunu. E da Elaidia ea gasa bagade hou agoane hamomuyo. Isala: ili eda amola ilia mano da ea sia: nababeba: le bu gousa: mu. Hame nabasu dunu da moloidafa dawa: su logoga buhagimu. Hina Gode da misunu. Amaiba: le, Yone da Gode Ea fi dunu Ema hahawane gousa: musa: , e da ili momagemu.”
Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”
18 Segalaia da a: igele dunuma amane sia: i, “Amo sia: da dafawaneyale na da habodane dawa: ma: bela: ? Na amola na uda, ani da da: i hamoi wea!”
Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Àmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”
19 A: igele da bu adole i, “Na dio da Ga: ibeliele. Na da Gode midadi Ea hawa: hamosa lela. E da amo sia: dima olelema: ne, na asunasi.
Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá.
20 Gode da amo sia: Ea ilegei eso dafawane hamomu. Be amo sia: di da dafawaneyale hame dawa: i. Amaiba: le, di da wali sia: hamedei esalumu. Di da ouiya: le esalu, na dima ilegei sia: i da dafawane doaga: sea fawane bu sia: baoumu.”
Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”
21 Amalaloba, gadili esafulu dunu huluane, Segalaia bu misa: ne bagadewane ouesalebeba: le, e da Debolo Diasu ganodini abuliba: le bagadewane esalala: ? ilia agoane dadawa: lalu.
Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili.
22 E da ganodini ga ahoanebe ba: loba, sia: hamedei ba: beba: le, e da ganodini musa: hame ba: su liligi ba: i, ilia dawa: i galu. Sia: hamedeiba: le, e da ilima ea loboga fawane ado boba: su.
Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.
23 Ea Debolo Diasu hawa: hamosu dagoloba, Segalaia da ea diasuga buhagi.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀.
24 Amalalu, fa: no ea uda Ilisabede da abula aguni, oubi biyale gala ea diasu mae fisili, ganodini esalu.
Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún,
25 E amane sia: i. “Hina Gode da na noga: le fidi. Na da aligimeba: le, gogosia: i, be Hina Gode da na gogosia: i fadegai dagoi.”
Ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó síjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”
26 Ilisabede da abula aguni, oubi gafeyale esaloba, Gode da a: igele dunu Ga: ibeliele amo Ga: lili soge moilai Na: salede, amoma asunasi.
Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti,
27 Amo moilaiga, a:fini dunuga hamedafa dawa: digi, ea dio amo Meli, esalu. Meli da Yousefe, (Da: ibidi aowa) ema sia: sili esalu. A: igele dunu da amo a: finima sia: musa: misi.
sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria.
28 Doaga: le, e da Melima amane sia: i, “Olofosu da dima diala! Gode da di noga: le ouligisa! E dima hahawane hou bagade iaha.”
Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”
29 Amo sia: nababeba: le, Meli da fofogadigili, beda: iwane amo sia: ea bai dawa: lalu.
Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí.
30 Be a: igele dunu da bu adole i, “Meli! Mae beda: ma! Gode da dima hahawane hamoi dagoi.
Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria, nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
31 Di da abula aguni, dunu mano lalelegemu. Di da amo manoma Yesu dio asulimu.
Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu.
32 E da gasa bagade hamomuyo. E da Gode Gadodafa Ea Egefedafa Dio lamu. Hina Gode da Ema Hina Bagade Hou, Ea siba osobo bagade fi eda Da: ibidi ea hou agoane, Ema imunu.
Òun ó pọ̀, ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é, Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún.
33 E da eso huluane mae fisili, Ya: igobe egaga fi, ilima Hinawane esalumu. Ea Hinadafa Hou da hamedafa dagomu.” (aiōn )
Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.” (aiōn )
34 Be Meli da bu adole ba: i, “Abolebela: ? Na da dunu hame fiba: le, na da habodane mano lama: bela: ?”
Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”
35 A: igele dunu da bu adole i, “Gode Ea A: silibu Hadigidafa da dima misini, di da Gode Ea gasa bagade hou dawa: mu. Amasea, mano dudubu dia hagomo ganodini hamoi da lalelegesea, ilia da Ema Gode Egefedafa dio asulimu.
Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò síji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é.
36 Diaba Ilisabede dawa: ma. E da aligime, amola mano lamu hamedei ilia sia: daha. Be e da wali oubi gafeyale gala abula agui ba: i dagoi.
Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀, èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn.
37 Liligi afae Gode da hahamomu hamedei da hamedafa gala.”
Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”
38 Amalalu, Meli da amane sia: i. “Na da Hina Gode Ea hawa: hamosu a: fini. Dia sia: i defele amo nama doaga: mu da defea.” Amalalu, a:igele dunu da fisili, asi.
Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
39 Fonobahadi ouesalu, Meli da ea liligi momagele, moilai amo da Yudia goumi soge ganodini galu amoga asi.
Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea;
40 Segalaia ea diasuga doaga: le, ganodini golili sa: ili, e da Ilisabede gousa: le nonogoi.
Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti.
41 Meli ea asigi sia: nababeba: le, mano dudubu Ilisabede ea hagomo ganodini dialu da liligilalebe ba: i. Gode ea A: silibu Hadigidafa da Ilisabede ea dogo nabala misi.
Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́,
42 Ilisabede da ha: giwane wele sia: i, “Di da eno uda ilia hahawane hou baligi dagoi. Dia mano lalelegemu da hahawane bagade.
Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí.
43 Na Hina Gode Ea eme nama gousa: la misunu, na da defele hame galebe.
Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá?
44 Be dia asigi sia: na nababeba: le, mano dudubu na hagomo ganodini diala da hahawaneba: le liligilalebe ba: i.
Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀.
45 Gode Ea dima sia: i da dafawane ba: mu. Dia amo dafawaneyale dawa: beba: le, di da hahawane bagade uda!”
Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́, nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”
46 Meli e amane sia: i, “Na asigi dawa: su amoga na da Godema nodosa.
Maria sì dáhùn, ó ní: “Ọkàn mi yin Olúwa lógo.
47 Gode na Gaga: su Dunu na dawa: beba: le, na a: silibu da hahawane bagade.
Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
48 E da na, Ea fonoboi hawa: hamosu uda dawa: iba: le, na da hahawane bagade. Waha winini dunu huluane da na da hahawane bagade, ilia da sia: mu.
Nítorí tí ó síjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀ ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀. Sá wò ó, láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
49 Bai Gasa Bagadedafa Gode da nama gasa bagade hou hamoi dagoiba: le. Gode Ea Dio da Hadigidafa.
Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi; Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.
50 Musa dunu fi bogole, eno fi dialu, dunu fi huluane Ea hou ilia nodone hamosea, ilima E da Ea gogolema: ne olofosu hou olelesa.
Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, láti ìrandíran.
51 Ea lobodafa molole, E da gasa fi dunu huluane eno sogega sefasi dagoi.
Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀; o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.
52 E da gasa fi hina dunu banenesi dagoi. Be hou fonoboi dunu E da gaguia gadoi.
Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.
53 Dunu ha: i ilima E da ha: i manu ida: iwane iasu. Be bagade gagui dunu amo E da da: i nabadowane hamone, sefasi.
Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.
54 Ninia aowalali ilima E da hahawane dogolegele imunusa: sia: beba: le, amo hahawane hou huluane E da hahamoi dagoi. E da Ea hawa: hamosu fi Isala: ili amo fidimusa: misi dagoi.
Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;
55 E da A: ibalaha: me amola ea fi huluane ilima Ea asigi amola gogolema: ne olofosu hou olelei. Amo hou E da mae fisili, eso huluane hamonanumu.” (aiōn )
sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.” (aiōn )
56 Meli da Ilisabede ea diasuga oubi udianawane ouesalu, ea diasuga buhagi.
Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
57 Amalalu, Ilisabede ea mano lamu eso doaga: beba: le, e da dunu mano lalelegei.
Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.
58 Ilisabede ea fi amola na: iyado da Hina Gode Ea ema fidisu hou nababeba: le, ilia da huluane gilisili nodoi.
Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.
59 Mano da lalelegele, hi afae aligili, ilia amo mano ea gadofo damuni fasimusa: misi. Ilia ea eda dio (Segalaia) amo ema asulimusa: dawa: i galu.
Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.
60 Be ea ame amane sia: i, “Hame mabu! Ninia Yone dio ema asulimu.”
Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”
61 Ilia bu adole i, “Abuliga! Dia fi amo ganodini, dunu amo da Yone dio asuli da hamedafa.”
Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”
62 Amalalu, ea eda da ema dio asulima: ne, ilia loboga adole ba: i.
Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.
63 Amalalu, Segalaia da ilima meloa lale ima: ne ado ba: i. Amoga e amane dedei, “Ea dio da Yone!” Ilia bagadewane fofogadigi.
Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.
64 Dedenanu, Segalaia da ea sia: hedolowane bu lale, Godema nodone sia: i.
Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.
65 Ilia na: iyado dunu huluane da bagadewane beda: i. Amo mabe hou huluane, Yudia goumi soge ganodini fi esalu dunu da bagadewane sia: dasu.
Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.
66 Amo hou nabi dunu huluane dawa: lalu, gilisili sia: dasu, “Amo mano da adi hou hamoma: bela: ?” Bai Hina Gode Ea gasa bagade hou da amo mano fidibiba: le, ilia noga: le ba: i dagoi.
Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.
67 Yone ea eda Segalaia da Gode Ea A: silibu Hadigidafa amoga nabaiba: le, Gode Ea sia: ne iasu amane ba: la: lusu sia: i,
Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:
68 “Ninia Hina Gode, Isala: ili fi ilia Godema nodone sia: ma! Bai E da Ea fi dunu fidimusa: , amola bu bidi lamusa: misi.
“Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,
69 E da gasa bagade Gaga: su dunu ninima i. Amo da Ea hawa: hamosu dunu Da: ibidi egaga fi.
Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;
70 E da hemonega, Ea balofede dunu ilia lafidili amane ilegele sia: i, (aiōn )
(bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́), (aiōn )
71 ‘Na da dilia ha lai dunu amo ilia dilima mae hasalima: ne, Na da dili gaga: mu.’
Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.
72 E da ninia aowalali dunu ilima gogolema: ne olofosu hou imunu sia: i. Amola E da Ea sema Gousa: su hamoi amo hame gogolemu sia: i.
Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,
73 Ninia siba eda A: ibalaha: me ema E da sia: dafawane ilegele sia: i,
ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,
74 amane, E da ninia ha lai dunu nini mae medoma: ne, E da nini gaga: mu, amola ninia da mae beda: iwane Ea hawa: hamonanuma: ne logo doasima: ne sia: i.
láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,
75 Amasea, ninia da Ea midadi hou ida: iwane amola hadigiwane hamosa, fifi ahoanumu.
ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
76 Di, na mano, di da Gode Gadodafa amo Ea balofede dunu amo ea dio lamu. Di da Hina Gode bisili, Ea logo fodomusa: masunu.
“Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;
77 Di da Ea dunu fi ilima ilia wadela: i hou gogolema: ne olofomusa: , Gaga: su dunu ilia ba: mu, di da olelemu.
láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
78 Ninia Gode da olofoiwane, asigiwane esalebeba: le, Ea Gaga: su hou da hehebolo mabe defele ninima doaga: mu.
nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà; nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,
79 Amo hadigi da Hebene amoga misini, dunu fi amo da gasi ganodini amola bogosu baba amo ganodini esalebe, ilima hadigimu. Amo hadigi da olofosu logo ninima noga: le olelemu.”
Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní òkùnkùn àti ní òjìji ikú, àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”
80 Yone da asigilalea, ea da: i amola ea a: silibu da gilisili asigilalu. E da dunu hame esalebe hafoga: i soge amo ganodini esalu, amoganini e da Isala: ili dunu ilima olelemusa: misi.
Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.