< Bisisu 16 >

1 Eso afaega, Sa: masane da Filisidini moilai bai bagade ea dio Ga: isa amoga asili, wadela: i hamosu uda gousa: i. E da amo uda gilisili golai.
Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
2 Ga: isa dunu fi da Sa: masane da esalebe nababeba: le, ilia da amo moilai bai bagade sisiga: le, moilai logo ga: su amoga e gagumusa: oulelu. Ilia da gasi ganodini ouiya: le lelu. Ilia agoane dawa: iou, “Ninia da oulelu, hahabedafa Sa: masane medole legemu.”
Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
3 Be Sa: masane da golale, gasimogoa wa: legadole, e da moilai logo ga: su bagade (ga: su huluane, ifa amola logo huluane) amo mugululi fasili, gisawane, agolo amoga dunu da Hibalone moilai bai bagade ba: su, amoga gaguli asi.
Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
4 Amalalu, Sa: masane da uda Solege fago amo ganodini esalu ea dio amo Dilaila, ema asigiba: le, lamusa: dawa: iou.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
5 Filisidini hina bagade biyale gala da Dilaila ema misini, amane sia: i, “Di Sa: masane hohonoma. Ninia da habodane e lale, la: gima: ne amola ea hou amoga hasalasima: ne, amo hogoi helema. Amalalu, ninia afae afae dima 1,100 silifa fage imunu.”
Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
6 Amaiba: le, Dilaila da Sa: masanema amane sia: i, “Na da dima edegesa. Dia gasa bagade hou da habidili mahabela: ? Dunu da di la: gili, dia gasa hedofamusa: da habodane hamoma: bela: ?”
Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
7 Sa: masane da bu adole i, “Ilia da gahe hame bioi gaheabolo dadi gosalo fesuale gala amoga na la: gisia, na da dunu eno defele gasa hame ba: mu.”
Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
8 Amaiba: le, Filisidini hina bagade da Dilaila ema gahe hame bioi gaheabolo dadi gosalo fesuale gaguli misi. Amoga, e da Sa: masane la: gi dagoi.
Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
9 Dilaila da sia: beba: le, dunu eno da diasu la: ididili sesei ganodini wamo ouesalebe ba: i. E gasa bagade wele sia: i, “Sa: masane! Filisidini dunu da manebe goea!” Be Sa: masane da amo dadi gosalo hedolo fi. Ilia da gobea ha: i laluga nei dibi agoane hedolowane fi. Amaiba: le, Filisidini dunu da ea gasa bagade wamolegei bai hame dawa: i.
Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
10 Dilaila da Sa: masane ema amane sia: i, “Di da nama ogogoiba: le, na da gagaoui dunu agoai ba: sa. Nama moloiwane adoma. Dia gasa hedofama: ne, dunu da habodane di la: gima: bela: ?”
Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
11 E bu adole i, “Ilia da efe gaheabolo (amoga liligi da musa: hame la: gi) amoga na la: gisia, na da eno dunu defele, gasa hame ba: mu.”
Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
12 Amaiba: le, Dilaila da efe gaheabolo lale, Sa: masane la: gi dagoi. Amalalu, e da gasa bagade wele sia: i, “Sa: masane! Filisidini dunu da manebe!” Dunu eno da diasu la: ididili wamo ouesalebe ba: i. Be Sa: masane da amo efe dasai gobea ha: i defele fi.
Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
13 Dilaila da Sa: masane ema amane sia: i, “Di da nama bu ogogoiba: le, na da gagaoui dunu agoane ba: sa. Dunu da habodane di lagima: bela: ?” Sa: masane da bu adole i, “Di da na dialumasa fesuale amo amunasuga amunasea amola mae fadegala masa: ne ifa amoga nodomenesisia, na da dunu eno defele gasa hame ba: mu.”
Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
14 Dilaila da Sa: masane amo ea masele da: iya, fene golama: ne susui. Amalalu, e da ea dialumasa fesuale amo amunasuga amuni. Mae fadegama: ne, e da ifaga nodomenesi. Amalalu, e da bagade wele sia: i, “Sa: masane! Filisidini dunu da manebe!” Be e da nedigili, ea dialuma hinabo amuni amo fadegai dagoi.
ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
15 Amalalu, Dilaila da ema amane sia: i, “Di da habodane nama asigisa amo sia: sala: ? Di da udiana agoane nama ogogoiba: le, na da gagaoui agoane ba: sa. Dia gasa bagade hou amo ea wamolegei bai, da nama hame olelei.”
Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
16 Eso huluane mae fisili, e da Sa: masanema adole ba: lalu. E da eso huluane sia: ga gegenabeba: le, Sa: masane da hele bagade nabi.
Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
17 Helebeba: le, e da moloiwane ea gasa bagade hou amo ea wamolegei bai ema olelei. E amane sia: i, “Na dialuma hinabo da hamedafa damusu. Na lalelegei eso amoga na da Na: salaide hou hamoma: ne, ilia da na Godema i. Na dialuma hinabo da damui dagoi ba: sea, na da dunu eno defele, gasa hame ba: mu.”
Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
18 Dilaila da Sa: masane da ema moloidafa olelei dagoi ba: i. Amaiba: le, e da Filisidini hina bagade ema sia: adole iasi, amane, “Afadafa fawane bu misa! E da nama moloiwane olelei!” Amalalu, ilia da misini, muni dabe ema ima: ne gaguli misi.
Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
19 Dilaila da Sa: masane ea masele da: iya fene golama: ne sususu. Amalalu, e da dunu eno misa: ne wele sia: i. Amo dunu da Sa: masane ea dialuma sa fesuale gala damuni fasi. Amalalu, Dilaila da Sa: masane ougima: ne, ema gadele sia: su. Bai Sa: masane ea gasa da fisi dagoi ba: i.
Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
20 Amalalu, Dilaila da amane wele sia: i, “Sa: masane! Filisidini dunu da manebe!” E da nedigili, amane dawa: i, “Na da musa: agoane hahawane masunu.” Be Hina Gode da e yolesi dagoi, amo e da hame dawa: iou.
Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
21 Amalalu, Filisidini dunu da Sa: masane afugili, ea si aduna duga: le fasi. Ilia da e Ga: isa moilaiga oule asili, balase sia: inega la: gili, ema se iasu diasu hawa: hamomusa: logei. E se iasu diasu ganodini gagoma amola widi goudalalu.
Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
22 Be ea dialuma hinabo da muni bu heda: lalebe ba: i.
Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
23 Filisidini hina bagade huluane da hahawane lolo manusa: amola ilia ogogosu ‘gode’ amo Da: igone ema gobele salasu bagade ima: ne gilisi dagoi. Ilia da amane gesami hea: i, “Ninia ‘gode’ da fidibiba: le, ninia da ninia ha lai dunu Sa: masane hasali.”
Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
25 Ilia da hahawane gilisili hedebeba: le, amane sia: i, “Sa: masane misa: ne wele sia: ma! E da nini hahawane ba: ma: ne hedemu da defea.” Ilia da Sa: masane se iasu diasuga gadili oule misini, ilia da hahawane ba: ma: ne hedema: ne sia: i. Ilia da e da igi dunibugi bagade aduna dogoa leloma: ne sia: i. Filisidini dunu da Sa: masane ba: loba, ilia da ilia ‘gode’ma bagadewane nodomusa: gesami hea: i, amane, “Amo dunu da ninia soge wadela: lesi amola ninia dunu bagohame medole legei. Be ninia ‘gode’ da hamobeba: le, ninia da e hasali dagoi.”
Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
26 Goi afae da Sa: masane lobolele, oule ahoasu. Sa: masane da ema amane sia: i, “Na da dunibugi amoga diasu da gagui amo digili ba: mu galebe. Na da ilima baligisiagamu hanai galebe.”
Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
27 Amo diasu ganodini da dunu amola uda bagohame gilisili esalebe ba: i. Filisidini hina bagade biyale gala huluane esalebe ba: i. Diasu ea figisu da: iya dunu amola uda 3,000 agoane esalebe ba: i. Ilia da Sa: masane ba: lalu amola ilia hahawane ba: ma: ne, e se nabawane hedemusa: bagadewane wele sia: su.
Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
28 Amalalu, Sa: masane da Godema sia: ne gadoi, amane, “Hina Gode Bagadedafa! Dia na bu dawa: loma! Na da ha: giwane Dima edegesa. Di nama na gasa bagade hou bu afaewane nama ima. Amasea, na da afadafa fabeba: le amo Filisidini dunu da na si duga: le fasi ilima dabemu.”
Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
29 Amaiba: le, Sa: masane dadunibugibagade aduna diasu dogoa dialu amo afae da lobodafa eno lobo fofadi amoga gaguli, gasawane fusu.
Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
30 E amane wele sia: i, “Na amola Filisidini dunu da gilisili bogomu da defea.” E da gasa bagade fubiba: le, diasu da mugululi, Filisidini hina bagade biyale gala amola dunu huluane amoga fana sa: i. Huluane da bogogia: i. Sa: masane da ea bogoi eso amoga da Filisidini dunu medole legei amo ilia idi da ea esalebe eso amoga medole legei amo ilia idi baligi dagoi.
Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
31 Ea yolali amola ea sosogo fi dunu eno da ea da: i hodo lala misi. Amo ilia gaguli, ea eda Manoua amo ea bogoi salasu Soula amola Esedoule dogoa sogebi dialu, amoga uli dogone sali. Sa: masane da ode 20amoga Isala: ili dunu ilia ouligisu esalu.
Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.

< Bisisu 16 >