< Yosiua 24 >

1 Yosiua da Isala: ili fi huluane Siegeme moilai bai bagadega gilisi. E da asigilai dunu, ouligisu dunu, fofada: su dunu amola Isala: ili ouligisu dunu misa: ne sia: i. Ilia da Hina Godema misi.
Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
2 Yosiua da dunu huluanema amane sia: i, “Hina Gode, Isala: ili fi ilia Gode da amane sia: sa, ‘Hemonega dilia aowalali da Iufala: idisi Hano na: iyadodili esalu, eno ogogosu ‘gode’ liligi ilima sia: ne gadosu. Dilia siba eda afae da Dila, A:ibalaha: me amola Na: iho ela eda.
Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
3 Amalalu, Na da dilia siba eda A: ibalaha: me amo soge Iufala: idisi Hano na: iyado amoga lale, amola Ga: ina: ne soge amoga oule asi. Na da ema egaga fi bagohame i. Na da Aisage ema i.
Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
4 Na da Aisagema, Ya: igobe amola Iso i. Na da Isoma amo Idome agolo soge i. Be dilia aowa Ya: igobe amola ea mano da Idibidi sogega sa: i.
àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
5 Fa: no Na da Mousese amola Elane asunasili, Idibidi dunuma se bagade iasu. Be Na da dili gadili oule asi.
“‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
6 Na da dilia aowalali Idibidi sogega fisili masa: ne, gadili oule misi. Idibidi dunu ilia dadi gagui amola sa: liode da: iya fila heda: i dunu da dilia aowalali fane legemusa: fa: no bobogei. Be dilia aowalali da Maga: me Hano Wayabo amoga doaga: loba,
Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
7 ilia da Na fidima: ne Nama wele sia: i. Na da ili amola Idibidi dunu afafamusa: , gasi bagade hamoi. Na da hamobeba: le, hano da Idibidi dunu dedebole, ilia da huluane gela sa: ili, bogogia: i. Na hou Idibidi dunuma hamoi, amo huluane dilia dawa: Dilia da hafoga: i wadela: i soge amo ganodini ode bagohame esalu.
Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
8 Amalalu, Na da dili A: moulaide dunu ilia soge Yodane Hano ea eso mabadi la: idi amoga oule misi. Ilia da dilima gegei, be Na da dili fidibiba: le, dilia amo dunu fane legei. Dilia da ilia soge lai amola dilia da gusuba: i ahoanoba, Na da amo dunu wadela: lesi.
“‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
9 Amalalu, Moua: be hina bagade dunu, Sibo ea mano Ba: ila: ge da dilima gegei. E da Ba: ila: me (Bio ea mano) ema e da dilima gagabusu aligima: ne sia: adole iasi.
Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
10 Be Na da Ba: ila: me ea sia: hame nabi. Amaiba: le, e da dilima Na da dili hahawane dogolegelewane fidima: ne sia: i. Na da agoane Ba: ila: ge dili hame wadela: ma: ne dili gaga: i.
Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
11 Dilia da Yodane Hano degele, Yeligou moilai bai bagadega doaga: i. Yeligou dunu da dilima gegei. A: moulaide dunu, Belisaide dunu, Ga: ina: naide dunu, Hidaide dunu, Gegasiaide dunu, Haifaide dunu amola Yebiusaide dunu huluane da dilima gegei. Be Na da fidibiba: le, dilia da amo huluane hasali dagoi.
“‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
12 Dilia da gusuba: i ahoanoba, Na da ili beda: ma: ne hamosu. Dilia da A: moulaide hina bagade aduna gadili sefasima: ne, Na da agoane hamoi. Dilia gegesu gobihei amola dadi da amo hasalasu hou hame hamosu.
Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
13 Na da soge amo dilia da hame dogosu amola moilai bai bagade dilia da hame gagui amo dilima i. Wali dilia da amo soge ganodini esala amola waini efe amo dilia hame sagai amoga dilia da waini fage naha amola olife ifa amo dilia hame bugi amoga olife fage naha.’”
Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
14 Yosiua da bu amane sia: i, “Amaiba: le, Godema nodoma amola mae fisili, hahawane Ea hawa: hamosu hamoma. Ogogosu ‘gode’ liligi amo dilia aowalali da Mesoubouda: imia amola Idibidi amo ganodini ilima hawa: hamosu, amo ha: digili, Hina Godema fawane hawa: hamoma.
“Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
15 Be dilia Ema hawa: hamomusa: hame hanai galea, defea, wali eso dilia da nowama hawa: hamomusa: dawa: sea, sia: ma! Dilia da ogogosu ‘gode’ liligi amo dilia aowalali da Mesoubouda: imia sogega sia: ne gadosu amo dilia da dafawaneyale dawa: le, lalegaguma: bela: ? O A: moulaide (ilia soge ganodini dilia da wali esala) amo dunu ilia ‘gode’ liligi lalegaguma: bela: ? Be na amola na sosogo fi da Hina Gode amo Ea hawa: hamosu fawane hamomu.”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
16 Dunu huluane da bu adole i, “Ninia da eno ‘gode’ liligi ilima hawa: hamoma: ne, Hina Godedafa hamedafa fisimu.
Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
17 Ninia Hina Gode da ninia aowalali amola nini amo Idibidi soge (amo ganodini ninia da udigili se nabawane hawa: hamosu) amoga fadegai dagoi. Ea musa: hame ba: su gasa bagade hou ninia ba: i dagoi. Ninia da dunu fi eno amoga baligili asili, E da eso huluane nini gaga: i.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
18 Ninia da amo soge ganodini golili sa: ili, Hina Gode da A: moulaide dunu amo ganodini esalu gadili sefasi. Amaiba: le, ninia da Hina Godema fa: no bobogemu hanai. E da ninia Gode.”
Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
19 Yosiua da dunu huluanema amane sia: i, “Be dilia Hina Gode Ea hawa: hamosu hamomu da hamedei. E da hadigi Gode amola E da dilia hame nabasu hou hame gogolema: ne olofomu. E da mudasu Gode, E da dili eno ‘gode’ liligi ilima fa: no bobogema: ne hamedafa ba: mu.
Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
20 Amola dilia da E fisili, ga fi ‘gode’ liligi ilima fa: no bobogesea, E da dilima sinidigili se bagade imunu. E da musa: dilima hahawane amola asigisu, be fa: no E da dili wadela: lesimu.”
Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
21 Dunu huluane da Yosiuama amane sia: i, “Hame mabu! Ninia da dafawane Hina Godema fa: no bobogemu.”
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
22 Yosiua da ilima bu adole i, “Dilisu da dilila: ba: su dunu esala. Dilia da Hina Godema fa: no bobogema: ne ilegei dagoi.” Ilia da amane sia: i, “Dafawane! Nini fawane da amo hou ba: su dunu.”
Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
23 Yosiua da amane sia: i, “Amaiba: le, amo ga fi ‘gode’ liligi dilia gagusa, amo fadegale fisima. Amola Isala: ili Hina Godema dafawane fa: no bobogema: ne ilegele sia: ma!”
Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
24 Amalalu, dunu huluane da Yosiuama amane sia: i, “Ninia da ninia Hina Godema fa: no bobogele, Ea hawa: hamomu. Ninia da Ea hamoma: ne sia: i nabawane hamomu.”
Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
25 Amaiba: le, Yosiua da amo esoha ilima gousa: su hamoi. Siegeme moilai bai bagadega e da sema amola hamoma: ne sia: i ilima i.
Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
26 Yosiua da amo hamoma: ne sia: i, amo Hina Gode Ea Sema Buga ganodini dedei. Amalalu, e da gele bagade lale, ouge ifa Hina Gode Ea hadigi sogebi ganodini dialu, amo hagudu ligisi.
Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
27 E da dunu huluanema amane sia: i, “Amo gele da ninia dawa: digima: ne ba: su olei agoane. Amo gele da sia: huluane Hina Gode da ninima sia: i, amo nabi dagoi. Amaiba: le, dilia da dilia Godema odoga: su hou hamosa: besa: le, amo gele da dilima ba: su olei agoane.”
“E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
28 Amalalu, Yosiua da dunu huluane gadili asunasi. Amola ilia huluane da ilia sogedafa amoga asi.
Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
29 Amalalu, Hina Gode Ea hawa: hamosu dunu, Nane egefe Yosiua, da bogoi dagoi. E da lalelegele, ode 110 gidigi.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
30 Ilia da ea soge ganodini ea da: i hodo uli dogone sali. Ea soge da Dimina: de Sila amo Ifala: ime agolo soge Ga: ia: se Goumi amo gano galu.
Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
31 Yosiua da esalea, Isala: ili dunu da Hina Godema noga: le fa: no bobogei. Yosiua da bogoloba, Isala: ili ouligisu dunu amo da Hina Gode Ea Isala: ili fidisu hou ba: i dagoi, amo dunu da esalea, Isala: ili dunu da Hina Godema noga: le fa: no bobogei.
Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
32 Yousefe ea da: i hodo amo Isala: ili dunu da Idibidi sogega gaguli misi, amo ilia da Siegeme moilai bai bagadega uli dogoi. Ilia da sogebi amo Ya: igobe da Ha: imo (Siegeme ea mano) amo ea manoma silifa fage 100 amoga lai, amo ganodini uli dogoi. Amo sogebi, Yousefe egaga fi da ilia edama nana lai.
Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
33 Elia: isa (Elane ea mano) amola da bogoi. Ilia da ea da: i hodo amo Gibia moilai (Ifala: ime agolo soge ganodini dialu. Amo moilai ilia da Elia: isa egefe Finia: se ema i dagoi) amoga uli dogone sali. Sia: Ama Dagoi Yosiua 24:15 “Wali eso, dilia da nowama fa: no bobogele, hawa: hamomusa: dawa: sea, sia: ma! Be na amola na sosogo fi da Hina Gode amo Ea hawa: hamosu fawane hamomu.”
Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.

< Yosiua 24 >