< Yosiua 10 >

1 Yelusaleme hina bagade amo Adounaisidege da Yosiua da Yeligou mugululi ea hina bagade fane legei amo defele A: iai mugululi, ea hina bagade medole legei, amo nabi dagoi. E da Gibione dunu da Isala: ili dunuma gousa: su hamone, ilia fi amo ganodini esala amola nabi.
Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
2 Yelusaleme dunu fi da bagadewane beda: i. Bai Gibione da moilai bai bagade. Gibione da moilai huluane hina bagade gala amo defele galu. Ilia dadi gagui dunu da gasa bagade amola Gibione moilai ea defei da A: iai moilai defei baligiligai.
Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
3 Amaiba: le, Adounaisidege da Hibalone hina bagade Houha: me, Yamade hina bagade Ba: ila: me, La: igisi hina bagade Yafaia amola Egelone hina bagade Dibe ilima sia: adole iasi, amane,
Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
4 “Nama fidila misa. Gibione moilai bai bagade dunu da Yosiua amola Isala: ili dunu ilima gousa: su hamoiba: le, na da Gibione doagala: musa: masunu.”
“Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
5 Amo A: moulaide hina bagade biyale gala amo Yelusaleme hina bagade, Yamade hina bagade, La: igisi hina bagade amola Egelone hina bagade, ilia da gilisili Gibione moilai bai bagade sisiga: le, doagala: i.
Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
6 Gibione dunu da Yosiua (Giliga: le abula moilaiga esalu) ema sia: adole iasi, “Nini mae fisima! Wahadafa nini gaga: la misa! Agolo sogega esala A: moulaide hina bagade huluane da gilisili ninima doagala: i dagoi.”
Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
7 Amaiba: le, Yosiua amola ea dadi gagui dunu huluane (noga: idafa dadi gagui amola da asi) da Giliga: le yolesi.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
8 Hina Gode da Yosiuama amane sia: i, “Ilima mae beda: ma. Na da dima hasalasu hou i dagoi. Dunu afae da dima bu gasawane gegemu hamedei ba: mu.”
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
9 Daeya wa: le ahoanoba hadigi, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da Giliga: le fisili, Gibione moilai bai bagadega asi. Ilia da A: moulaide dunu ilima hedolowane doagala: loba, A:moulaide dunu da fofogadigi.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
10 Hina Gode da hamoiba: le, A:moulaide dunu da Isala: ili dadi gagui dunu ba: loba, bagade beda: iba: le hobea: i. Isala: ili dadi gagui da ili bagohame Gibione moilai bai bagadega medole legele, sefasi. Sefasili, ilia da goumi adobo logo amo Bede Houlone amoga sefasili, Asiga moilai amola Ma: gida moilaiga doaga: i.
Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
11 A: moulaide dunu da goumi logoga Isala: ili dadi gagui ilima hobeale ahoananoba, Hina Gode da hamoiba: le, gibu mugene da ilima sa: ili mae fisili Asiga ahoasu amoga sa: i. Amola mugene igi amoga medole legei idi da Isala: ili dunuga medole legei idi amo baligi dagoi.
Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
12 Amo esoha Hina Gode da hamoiba: le, Isala: ili dunu da A: moulaide dunuma hasali. Amola amo esoha, Isala: ili dunu huluane ba: ma: ne, Yosiua da Hina Gode hamoma: ne amane sia: i, “Eso! Di Gibione moilaiga gadodili leloma. Oubi! Di A: iyalone Fago amoga gadodili leloma.”
Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
13 Amalalu, eso da mae asili, oulelu amola oubi da mae asili, oulelu. Isala: ili dunu da ilima ha lai hasali dagoiba: le fawane bu asi. Amo hou da Ya: isa buga ganodini dedei diala. Eso da mu dogoa amo ganodini lelu, eso afaega hame sa: i.
Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
14 Amo hou amo Hina Gode da osobo bagade dunu ea sia: ne ba: su, musa: da hame ba: su amola fa: no amo hame ba: su. Hina Gode da Isala: ili fi fidima: ne gegei.
Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
15 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da Giliga: le abula diasu gilisisuga buhagi.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
16 Be A: moulaide hina bagade biyale gala da hobeale, Ma: gida sogebi gele gelabo amo ganodini wamoaligi.
Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
17 Dunu eno da amo ba: i dagoi. Ilia wamoaligisu ilia da Yosiuama olelei.
nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
18 E amane sia: i, “Gele gelabo amo ea logo holei igi bagadega ga: sima. Ouligisu dunu amo logo ouligima: ne sia: ma.
ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
19 Be dilia amogawi mae esaloma. Ninima ha lai amo sefasili ilia baligiga fane legema. Ilia moilai bai bagadega buhagimu logo hedofama. Dilia Hina Gode da fidibiba: le, dilia da amo dunu hasali dagoi.”
Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
20 Yosiua amola Isala: ili dunu da amo dunu fane legei dagoi. Be mogili da ilia moilai bai bagade gagoi amo ganodini hobeale, ilia hame fane legei.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
21 Amalalu, Yosiua ea dunu huluane da hahawane Ma: gida abula diasu gilisisuga bu misi. Amalalu, amo soge dunu huluane da beda: iba: le, Isala: ili dunuma lasogole sia: mu bagadewane beda: i galu.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
22 Amalalu, Yosiua da amane sia: i, “Gele gelabo logo doasili, amo hina bagade biyale gala nama oule misa.”
Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
23 Amaiba: le, ilia da gele gelabo doasili, Yelusaleme, Hibalone, Yamade, La: igisi amola Egelone amoea hina bagade dunu gadili hiouginana asili,
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
24 Yosiuama oule misi. Amalalu, Yosiua da Isala: ili dunu huluane amola dadi gagui ouligisu dunu huluane da e sigi asi, amo ilia emo amo hina bagade dunu ilia gonomagi da: iya osa: la heda: ma: ne sia: i. Ilia amo hamoi dagoi.
Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
25 Amalalu, Yosiua da ea dadi gagui hina dunuma amane sia: i, “Dilia mae beda: ma mae da: i dioma. Gasa bagadewane amola hahawane hamoma. Bai Hina Gode da dilima ha lai dunu huluane ninia wali hamoi defele hamomu.”
Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
26 Amalalu, Yosiua da amo hina bagade biyale gala medole legele, ilia da: i hodo ifa biyale gala amoga hegoa: nesi. Ilia da amogawi hegoa: nesili dialu, eso dabe galu bu lai.
Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
27 Eso dabe amoga Yosiua da sia: beba: le, ilia da hina bagade dunu amo ilia da: i hodo ifaga fadegale, gele gelabo amo ganodini musa: hina bagade da wamoaligi amoga ha: digi. Ilia da gele bagade bagohame amoga gele gelabo ea logo holeiga dedeboi. Amo gele da wali eso amaiwane diala.
Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
28 Yosiua da amo esoga, Ma: gida moilai bai bagade amola ea hina bagade doagala: le, fedele lai. Dunu huluane amo ganodini esalu e da medole legei. Dunu afae esalebe hame ba: i. E da Yeligou hina bagade ema hamoi defele, Ma: gida hina bagadema hamoi.
Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
29 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da Ma: gida fisili, Libina moilai bai bagadega doagala: i.
Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
30 Hina Gode da fidibiba: le, Isala: ili dunu da amo moilai amola ea hina bagade hasali. Ilia dunu afae amoma hame asigiwane, huludafa fane legei. Ilia da Yeligou hina bagade ema hamoi amo defele Libina hina bagadema hamoi dagoi.
Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
31 Amalalu, Yosiua da Libina fisili, La: igisi moilai bai bagade amo sisiga: le, doagala: i.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
32 Eso ageyaduga, Hina Gode da fidibiba: le, Isala: ili dunu da La: igisi hasali. Ilia da Libina amoga hamoi defele dunu afae moilai ganodini amoma hame asigiwane, huludafa fane legei.
Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
33 Houla: me (Gise moilai bai bagade hina bagade) da La: igisi dunu fidimusa: misi, be Yosiua da e amola ea dadi gagui dunu hasali. Dunu afae esalebe hame ba: i.
Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
34 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da La: igisi fisili, Egelone moilaiga asili, amo moilai sisiga: le, doagala: i.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
35 Amo eso afaega ilia da moilai lai. Ilia da La: igisi fi ilima hamoi defele, dunu huluanedafa medole legei.
Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
36 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da Egelone moilai fisili, agolo sogega asili, Hibalone moilai bai bagadega doagala: i.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
37 Ilia da Hibalone lale, amo hina bagade dunu, amogai esalebe dunu huluane amola dunu huluane moilai sisiga: le ganodini esalu, medole legei. Yosiua ea sia: beba: le, ilia da Egelone moilai amoma hamoi defele, amo moilai gugunufinisi. Dunu afae amo ganodini esalebe hame ba: i.
Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
38 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui da sinidigili, Dibe moilaiga doagala: i.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
39 E da amo moilai, ea hina bagade amola dunu huluane moilale sisiga: le dialu amo ganodini esalu lai dagoi. Yosiua da Hibalone, Libina amola ela hina bagade dunu ilima hamoi defele, e da Dibe amola ea hina bagade amoma hamoi. E da ilia dunu huluane medole legei dagoi.
Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
40 Yosiua da soge huluane hasali. E da hina bagade huluane, amo agolo soge hina bagade, eso mabadi soge hina bagade, eso dabe agolo fonobahadi hina bagade amola hafoga: i soge ga (south) dialebe hina bagade huluane fane legei. E da dunu huludafa medole legei dagoi. Bai Isala: ili Hina Gode da amo hamoma: ne sia: beba: le.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
41 Yosiua da soge huluane lai. Amo da ga (south) Ga: idese Bania asili Ga: isa (amo da wayabo bagade bega: ), Gousiene soge huluane ga (north) asili, Gibione moilai bai bagadega doaga: i.
Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
42 Isala: ili Hina Gode da ili fidimusa: gegeiba: le, Yosiua da amo hina bagade amola ilia soge huluane hasali dagoi.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
43 Amalalu, Yosiua amola ea dadi gagui dunu da Giliga: le abula diasu gilisisuga buhagi.
Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.

< Yosiua 10 >