< Yone 3 >

1 Amo esoha, Yu ouligisu dunu afae (Fa: lisi dunu) ea dio amo Nigoudimase, esalebe ba: i.
Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
2 E da gasia, wamowane Yesuma misini, amane sia: i, “La: bai (Olelesu)! Gode da hame fidi ganiaba, Dia da musa: hame ba: su dawa: digima: ne olelesu hamonanebe amo hamomu da hamedela: loba. Amo ninia ba: beba: le, di da Godema asunasi olelesu dunu ninia dawa:”
Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
3 Be Yesu da ema bu adole i, “Na dima dafawane sia: sa! Nowa dunu da bu hame lalelegesea, e da Gode Ea Hinadafa Hou hamedafa ba: mu.”
Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
4 Nigoudimase fofogadigili bu adole ba: i, “Abolebela: ? Asigilai dunu da habodane bu lalelegema: bela: ? E da ame ea hagomo ganodini bu galuli amo bu lalelegema: bela: ?”
Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
5 Yesu E bu adole i, “Na da dima dafawane sia: sa. Dunu e da hanoga amola A: silibuga bu hame lalelegesea, e da Gode Ea Hinadafa Hou amoga heda: mu hamedei.
Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
6 Dunu da eda amola eme, amoga ela hamoiba: le lalelegesea, e da da: i hodo fawane hamosa. Be A: silibu Hadigidafa amoga lalelegesea, e da a: silibuwane ahoanumu.
Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
7 Dilia huluane da bu lalelegemu da defea, amo Na da sia: beba: le, mae fofogadigima.
Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
8 Fo da hi hanaiba: le hi logoga ahoa. Fo da habodili misi, amola habodili masunu, di hame dawa: Fo ea sia: fawane naba. Dunu ilia da Gode Ea A: silibu Hadigidafa Gala amoga lalelegebeba: le, ilia hou da amo agoane ba: sa.”
Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
9 Nigoudimase da bu fofogadigili amane adole ba: i, “Amo hou da habodane mahabela: ?”
Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
10 Yesu da bu adole i, “Defea! Di da mimogo olelesu dunu Isala: ili soge ganodini. Amaiba: le, di abuliba: le amo hou hame dawa: sala: ?”
Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
11 Na da dafawane sia: dilima olelesa. Na dawa: su liligi, na siga ba: su liligi, amo fawane na dilima sia: ne iaha. Be dilia huluane amo sia: ne iasu nabimu higasa.
Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
12 Na da osobo bagade hou dilima olelebeba: le, dilia da dafawaneyale hame dawa: be. Amaiba: le, Na da Hebene hou dilima olelesea, dilia da habodane dafawaneyale dawa: ma: bela: ?
Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
13 Osobo bagade dunu da Hebene sogega hamedafa heda: su. Be Dunu Egefe, E da osobo bagadega gudu sa: i, Hi fawane da Hebene sogega esalebe dunu.
Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
14 Mousese da hemonega dunu hame esalebe hafoga: i wadela: i soge ganodini, sania balasiga hamoi amola ifaga gosagisili, gaguia gadole, bugili, amo hou defele ilia da Dunu Egefe gaguia gadomu.
Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
15 Dunu huluane amo da Dunu Egefe Ea hou dafawaneyale dawa: sea, eso huluane Fifi Ahoanusu lama: ne, amo hou da doaga: mu. (aiōnios g166)
Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios g166)
16 Bai Gode da osobo bagade fifi asi gala hodole, ilima asigili, Egefe ilima i. Ea sia: dafawaneyale dawa: sea, lalegagusia, eso huluane mae bogole Fifi Ahoanumu. (aiōnios g166)
“Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
17 Gode da osobo bagade dunu huluane ilima se imunusa: fofada: musa: , Egefe hame asunasi. Be dunu huluane gaga: musa: , E da Egefe asunasi dagoi.
Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
18 Nowa dunu da Gode Egefe dafawaneyale dawa: sea, e da se imunusa: fofada: su hame ba: mu. Be nowa da dafawaneyale hame dawa: sea, e da Yesu Ea Dio dafawaneyale hame dawa: beba: le, se imunusa: fofada: su ba: mu.
Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
19 Gode Ea fofada: su da agoane ba: sa. Hadigidafa da osobo bagadega doaga: i dagoi. Be dunu ilia hou da wadela: iba: le, ilia hadigi higale, gasi hanai galebe.
Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
20 Nowa dunu da wadela: i hou hamosea, e da hadigi higabeba: le, hadigi amoga hame maha. Eno dunu da ea wadela: i hou ba: sa: besa: le, e da hadigiga hame maha.
Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
21 Be ida: iwane, moloiwane hamosu dunu, ea hadigi da Godema hamoi amo olelemusa: , e da hadigi amoga maha.”
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
22 Amalalu, Yesu amola Ea ado ba: su dunu, ilia da Yudia sogega asili, ouesalu, hanoga fane salasu hou hamonanu.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
23 Inone sogebi (amo da Sa: ilaime moilai gadenei) amoga Yone da ba: bodaise hou hamonanu. Bai amo sogebiga, hano bagohame dialebe ba: i. Dunu bagohame da ema doaga: beba: le, e da ili hanoga fane salasu.
Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
24 (Amo esoha, Yone da se iasu diasu ganodini hame sali.)
(Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
25 Yone ea ado ba: su dunu da Yu dunuma sia: ga gegei. Ilia hanoga ulasu sema amoma dawa: beba: le, sia: ga gegei.
Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
26 Amalalu, ilia Yonema misini, amane sia: i, “Olelesu! Dunu amo da ali Yodane gusu bega: amoga esalu. Di da Ea hou ninima olelei. Amo da wali ba: bodaise hou hamonanebeba: le, dunu huluane da Ema ahoa!”
Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
27 Yone da bu adole i “Gode da osobo bagade dunuma hou hame olelei ganiaba, e da gasa bagade hou hame dawa: la: loba.
Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
28 Na sia: dilia huluane nabi dagoi. Na amane sia: i, ‘Na da Mesaia hame be E bisili masa: ne, Gode da na asunasi.
Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
29 Uda da uda lamu dunu amo ea uda. Be uda lamu dunu ea na: iyado, e da uda lamu dunu ea sia: nababeba: le, hahawane ba: sa. Amaiba: le, na hahawane hou da nabaiwane diala.
Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
30 Ea mimogo hou da heda: le, amola na hou da gudu sa: imu da defea.”
Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
31 Gadodafa amoga misi dunu da osobo bagade dunu huluane baligisa. Osobo bagade dunu da osobo bagadega esalebeba: le, osobo bagade hou fawane sia: daha. Be Hebene sogega misi dunu da liligi huluane baligisa.
“Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
32 E da Ea ba: su amola Ea nabasu liligi olelesa. Be dunu huluane da Ea sia: hame lalegagusa.
Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
33 Be nowa dunu Ea sia: dafawane lalegagusia, amo dunu e da Gode Ea hou da dafawanedafa eno dunuma olelesa.
Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
34 Gode Ea asunasi dunu da Gode Ea sia: fawane olelesa. Bai Gode da Ea A: silibu nabaiwane Ema iaha.
Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
35 Adadafa da Egefema asigiba: le, Ea gasa bagade hou huludafa Ema ia dagoi.
Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
36 Nowa da Gode Egefe dafawaneyale dawa: sea, e da eso huluane Fifi Ahoanusu lai dagoi. Be nowa da Gode Egefe Ea sia: hame nabawane hame hamosea, e da eso huluane Fifi Ahoanusu mae lale, Gode Ea ougi se iasu ba: mu agoai galebe!” (aiōnios g166)
Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios g166)

< Yone 3 >