< Yelemaia 44 >
1 Hina Gode da nama na da Isala: ili dunu Idibidi soge ganodini esala (Migidole amola Daha: banisi amola Memefisi moilai bai bagade amola Idibidi gagoe (south) soge) ilima sia: ma: ne sia: i.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Hina Gode Bagadedafa, Isala: ili fi ilia Gode, da ilima amane sia: i, “Dilila: da gugunufinisi amo Na da Yelusaleme amola Yuda moilai huluane amoma iasu, dilia da ba: i dagoi. Ilia da wali mugului dagoi dialebe amola amo ganodini dunu esalebe hame ba: sa.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 Bai amo dunu fi da Na ougima: ne, wadela: le hamoi. Ilia da ogogosu ‘gode’ ilima gobele salasu amola eno ‘gode’ amo dilia amola dilia aowalalia da ilima hamedafa nodone sia: ne gadosu, amo ilia hawa: hamosu hamonanu.
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 Na da Na hawa: hamosu balofede dunu dilima asunasilalu. Amola ilia da dilima amo hou Na da higa: i, amo maedafa hamoma: ne sia: i.
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 Be dilia da ilia sia: hame nabi, amola hame dawa: digisu. Dilia wadela: i eno ‘gode’ ilima gobele salasu hou amo yolesimu hame dawa: i.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Amaiba: le, Na ougi bagade Na da Yelusaleme logo amola Yuda moilaiga sogadigi. Na da amo laluga ulagi. Ilia da mugului dagoi ba: i. Dunu da amo beda: iwane fofogadigili ba: i, amola ilia da wali amaiwane diala.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 Amaiba: le, Na, Hina Gode Bagadedafa, Isala: ili fi ilia Gode, da wali dilima adole ba: sa. Dilia da abuliba: le, dilila: wadela: lesima: ne, wadela: i hou hamosala: ? Dilia da dilia dunu amola uda amola mano da dilila: wadela: su lamu hanabela: ? Amasea, dilia dunu afae esalebe hame ba: mu.
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 Dilia da abuliba: le Na ougima: ne, loboga hamoi ‘gode’ ilima nodone sia: ne gadobela: ? Amola ogogosu ‘gode’ Idibidi soge amoga dilia da esaloma: ne misi amo ganodini gala, ilima gobele salasu hamosala: ? Dilia da dilila: wadela: ma: ne hamosala: ? Dilia da fifi asi gala huluanedafa da dili higamu amola dilia dio amoga gagabusu aligima: ne ilegemu, amo hanabela: ?
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Dilia, dilia uda, Yuda hina bagade, ilia uda amola dilia aowalalia huluane da Yuda moilai amola Yelusaleme logo amo ganodini, wadela: i hou bagade hamonanu. Amo dilia da gogoleila: ?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Be dilia eso huluane amola wali dilia hou gogosiane hame fofonobosu. Dilia da Nama hame nodosu amola sema amo Na da dilima amola dilia aowalalima i, amoma hame fa: no bobogesu.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 Amaiba: le, Na, Hina Gode Bagadedafa, Isala: ili fi ilia Gode, da dilima ha lale, Yuda fi huluane wadela: lesimu.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 Amola Yuda fi dunu hame bogoi esalebe, ilia da Idibidi sogega masunu hanai. Ilia huluane wadela: lesima: ne, Na da logo doasimu. Ilia huluane, fonobahadi amola bagade, da Idibidi soge ganodini gegesu o ha: i bagade amoga bogogia: mu. Dunu eno da amo hou beda: iwane fofogadigili ba: mu. Ilia da Yuda fi dunu higamu amola ilia dio amoga gagabusu aligima: ne ilegemu.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 Na da Yelusaleme fi ilima gegesu amola ha: i bagade amola olosu amoga se iasu. Amo defele, Na da Yuda fi Idibidi sogega esala, ilima se imunu.
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 Yuda fi dunu esalebe amo da Idibidi sogega esaloma: ne misi, huluanedafa da bogogia: mu. Ilia da Yuda sogega buhagima: ne hanai. Be dunu afae da hame buhagimu. Be mugululi asi dunu bagahamedafa da buhagimu.”
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 Amalalu, dunu huluane (ilia uda da eno ogogosu ‘gode’ ilima gobele salasu hamosu, amo ilia dawa: i) amola uda huluane amogawi lelu, amola Isala: ili fi dunu Idibidi gagoe (south) soge ganodini esalu, dunu gilisisu bagade, da nama amane sia: i,
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 “Ninia da dia sia: amo di da Hina Gode Ea Dioba: le ninima sia: i, amo hame nabimu.
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 Ninia da ninia musa: sia: i defele hamomu. Ninia da ninia uda ‘gode’ (hebene hina bagade Uda) ema gobele salasu hamomu. Ninia aowalalia, ninia hina bagade amola ninia ouligisu dunu da Yuda moilai amola Yelusaleme logo amo ganodini, ema nodoma: ne, waini hano iasu sogadigisu. Amo defele ninia da hamomu. Amo esoga ninia da bagade gaguiwane, hame ha: i amola bidi hamosu hame ba: i.
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 Be ninia da Hebene hina bagade Uda ema gobele salasu amola waini hano sogadigisu hou amo yolesiba: le, ninia wali hame gaguiwane ba: sa, amola ninia fi dunu da gegesu amola ha: i bagade amoga bogogia: lala.”
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 Amola uda ilia amane sia: i, “Ninia da agi ga: gi (Hebene hina bagade Uda ea ba: su agoane) gobele, amola ema gobele salasu amola waini hano iasu sogadigisu amo hamobeba: le, ninia lagoalali da ninia hamobe hahawane ba: su.”
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 Amalalu, na da dunu amola uda huluane amo da nama agoane bu adole i, ilima amane sia: i,
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 “Dilia adi dawa: bela: ? Gobele salasu hou amo dilia amola dilia aowalalia, amola dilia hina bagade dunu amola dilia ouligisu dunu amola soge dunu huluane da Yuda moilai amola Yelusaleme logo amo ganodini iasu, amo Hina Gode da hame ba: bela: ? E da amo gogoleila: ? Hame mabu!
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 Wali eso dilia soge da wadela: lesi dagoi diala. Dunu eno da amo beda: iwane fofogadigili ba: sa, amola soge ea dio amoga ilia da gagabusu aligima: ne ilegesa. Bai Hina Gode da dilia wadela: i hou hamobe amo bu ba: mu higasu.
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Dilia da ba: sa! Wali se nabasu amola gugunufinisisu da dilima doaga: i dagoi. Bai dilia da eno ogogosu ‘gode’ ilima gobele salasu hou hamosu amola Hina Godema wadela: le hamoi. Dilia da Ea hamoma: ne sia: i huluane amoma hame fa: no bobogesu.”
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Na da dunu huluane olelei (amola uda ilima baligili olelei), amo Hina Gode Bagadedafa, Isala: ili fi ilia Gode, da Yuda fi Idibidi soge ganodini esala ilima amane sia: sa, “Dilia amola dilia uda da ‘hebene hina bagade Uda’ ema sia: dafawane ilegei. Dilia da ema gobele salimu amola waini hano iasu sogadigima: ne dafawane ilegesu, amola amo ilegesu dilia da dafawane hamoi. Defea! Dilia ilegesu mae yolesima! Hamoma!
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 Be wali, Na, Hina Gode, da Na Dio Bagadedafa amoga dilia Isala: ili dunu Idibidi soge ganodini esala dilima dafawane sia: ilegei dagoi. Amo nabima! Na da dilia logo ga: i dagoi. Dilia da bu ‘na da Ouligisudafa Hina Gode Esala amo Ea Dioba: le sia: ilegesa’ amo bu hamedafa sia: mu.
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Dilia huluane hame gaguiwane, wadela: lesima: ne, Na da logo doasimu. Dilia huluane da gegesu o olosu amoga bogogia: mu. Dunu afae esalebe hame ba: mu.
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 Be afae afae da mae bogole, Idibidi fisili, Yuda sogega buhagimu. Amasea, dunu hame bogoi esalebe, ilia da Na sia: da dafawane amola ilia sia: da ogogosu, amo dawa: digimu.
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 Na, Hina Gode, da Na sia: i liligi (amo soge ganodini Na da dilima se imunu amola wadela: su iasimu) dilia dafawane dawa: ma: ne, Na da dawa: digima: ne olelesu dilima imunu.
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Amo da Na Yuda hina bagade Sedegaia amo ea ha lai, Ba: bilone hina bagade Nebiuga: denese (e da Sedegaia medole legemu hanai) ema i - amo defele Na da Idibidi hina bagade Hofala ea ha lai dunu (ilia e medole legemu hanai) ilima imunu.”
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”