< Aisaia 66 >

1 Hina Gode da amane sia: sa, “Hebene da Na Fisu gala. Amola osobo bagade da Na emo osa: sisu. Amaiba: le, dilia da habodili diasu amo ganodini Na esaloma: ne gaguma: bela: ?
Báyìí ni Olúwa wí: “Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà? Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
2 Na Nisu da osobo bagade amola mu huluane hahamoi dagoi. Nowa dunu da ilia hou fonobosa amola Nama sinidigili, Nama beda: i gala amola Na sia: naba, amo dunuma Na da hahawane gala.
Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?” ni Olúwa wí. “Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí: ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀, tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
3 Be dunu fi ilia nodone sia: ne gadosu hou da wadela: idafa. Ilia da bulamagau medole legele gobele sala amo defele dunu medole legele gobele sala. Ilia da sibi mano gobele salasu defele, wa: me ea galogoaga fisa. Ilia gagoma iasu defele gebo ea maga: me iaha. Ilia da ogogosu loboga hamoi ‘gode’ liligi ilima sia: ne gadosa amola gabusiga: manoma gobesisa. Ilia da hahawane wadela: idafa nodone sia: ne gadosu hou hamosa.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ, dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá, ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí, dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà. Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n, ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn,
4 Amaiba: le, Na da ili gugunufinisimu. Liligi amoga ilia beda: i amoga ili gugunufinisimu. Bai Na da ilima misa: ne wele sia: beba: le, ilia da hame misi, amola Na da ilima sia: beba: le, ilia da Na sia: nabimu higa: i galu. Ilia da Na sia: i mae nabima: ne, amola wadela: i hou hamoma: ne, ilegei dagoi.”
fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn. Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn, nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀. Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”
5 Dilia dunu amo da Godema beda: i amola Ea sia: naba, dilia! Hina Gode Ea sia: nabima, “Dilia fidafa dunu mogili da dili higasa amola dilima gilisimu higasa. Bai dilia Nama molole fa: no bobogesa. Ilia da dilima oufesega: le, amane sia: sa, ‘Hina Gode da Ea gasa bagade hou olelemu amola dili gaga: mu da defea. Amasea, dilia hahawane hou ninia ba: mu.’ Be ilisu da gogosiasu ba: mu.”
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀: “Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín, tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé, ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo, kí a le rí ayọ̀ yín!’ Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
6 Nabima! Ga: bagade moilai amola Debolo diasu ganodini nabima! Amo da Hina Gode da Ea ha lai dunu ilima se iaha.
Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá, gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá! Ariwo tí Olúwa ní í ṣe tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí wọn.
7 Hina Gode da amane sia: sa, “Na hadigi moilai bai bagade da uda amo da hedolodafa mano lalelegesa be sega gawialasu hame hamosa, agoaiwane gala.
“Kí ó tó lọ sí ìrọbí, ó ti bímọ; kí ó tó di pé ìrora dé bá a, ó ti bí ọmọkùnrin.
8 Dunu afae da musa: amo hou ba: bela: ? o nabibala: ? Fifi asi gala afae da eso afadafa amoga lalelegebela: ? Be Saione da fonobahadi fawane se nabalu, Isala: ili fifi asi da lalelegei dagoi ba: mu.
Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan? Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
9 Dilia adi dawa: bela: ? Na da Na fi fidisia, ilia lalelegemu gadenesea, ilia lalelegemu logo Na da ga: ma: bela: ? Hame mabu! Ilia da lalelegemu,” Hina Gode da amane sia: i.
Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí kí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ nígbà tí mo ń mú ìbí wá?” Ni Ọlọ́run yín wí.
10 Nowa da Yelusaleme amoma asigi galea, wali e amola gilisili hahawane hamoma. Dilia da ea dafai eso amoga, ema asigiba: le, dinanu. Be wali, e da wa: legadomuba: le, hahawane ba: mu.
“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀; ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
11 E da bu bagade gagui ba: muba: le, dilia da mano ea: mea dodo nabeba: le, hahawane gala, amo defele hahawane ba: mu.
Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára, ẹ̀yin yóò mu àmuyó ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”
12 Hina Gode da amane sia: sa, “Na da dilima bagade gagui hou imunu, amola amo hou da dialumu. Fifi asi gala ilia liligi da hano amo hafoga: su hame dawa: defele, dilima manebe ba: mu. Dilia da mano amo ea: me da ema dodo maga: me iaha amola ouga: ne, ema asigi bagade hamosa, dilia da amo mano agoaiwane ba: mu.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi; ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀ a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
13 Eme da ea mano dogo denesima: ne hamosa, amo defele Na da Yelusaleme ganodini, dilia dogo denesimu.
Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”
14 Dilia amo hou ba: sea, hahawane ba: mu. Amola Na da dilima amo hou hamomuba: le, dilia da gasa bagade amola oloi hame gala ba: mu. Amasea, dilia da dawa: mu, amo Na, Hina Gode, da nowa dunu da Na sia: nabawane hamosa amo fidisa, amola nowa da Nama ha lai amoma Na da ougi hou olelesa.”
Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko; ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
15 Hina Gode da lalu gaguli manebe ba: mu. E da fedege agoane, isu ea ougia fila heda: le, Ea ha lai ilima se imunusa: manebe ba: mu.
Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle; òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú, àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
16 E da nowa osobo bagade dunu da wadela: i hou hamonanebe ba: sea, ilima laluga amola gegesu gobihei amoga, se iasu ilima imunu. E da dunu bagohame medole lelegemu.
Nítorí pẹ̀lú iná àti idà ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.
17 Hina Gode da amane sia: sa, “Na ha lai da ogogosu ‘gode’ ilima nodone sia: ne gadomusa: , ilia ledo doga: sea, ilia da sema ifabi amoga mogodigili ahoa, amola ilia da gebo hu amola dauwa amola eno sema ha: i manu naha. Ilia wadela: mu eso da gadenesa.
“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.
18 Ilia asigi dawa: su amola wadela: i hou amo Na dawa: Na da fifi asi gala fi dunu huluane amo gilisima: ne misunu. Ilia da gilisisia, Na gasa bagade hou ea hamobe ba: mu.
“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.
19 Amola Na da se bidi iasu dunu, amo ilia da dawa: mu. Be mogili ilima Na da se hame imunu. Be Na da ili soge sedaga amo da Na dio hame nabi amola Na gasa bagade hou hame ba: i, amoga asunasimu. Na da Siba: ini amola Libia amola Lidia (amoga dadi gagui dunu da gegesu bagade dawa: ) amola Duba: le amola Galisi amo sogega asunasimu. Amo sogega ilia Na gasa bagade hou amo dunu fi ilima sisia: mu.
“Èmi yóò sì gbé àmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
20 Ilia da dilia fi Isala: ili dunu amo soge ganodini esala, amo guiguda: bu oule misini, Nama hahawane iasu defele, Nama oule misunu. Ilia da amo Na sema agolo Yelusaleme ganodini amoga oule misunu. Ilia da hosi amola dougi amola ga: mele amo da: iya fila heda: le, amola sa: liode amola gaguli fula ahoasu amo ganodini oule misunu. Isala: ili dunu da widi amola gagoma ledo hamedei, ofodo ganodini Debolo diasuga gaguli maha, amo defele ilia da Yelusalemega oule misunu.
Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ̀-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́.
21 Amo dunu mogili, Na da gobele salasu amola Lifai dunu ilegemu.
Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.
22 Osobo bagade gaheabolo amola mu gaheabolo da Na gasaga dialumu. Amo defele, diligaga fi, amola dilia dio, da Na gasaga dialumu.
“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé.
23 Oubi Gaheabolo Lolo Nabe amola Sa: bade Eso huluane, fifi asi gala huluane dunu ilia da Nama nodone sia: ne gadomusa: , Yelusaleme guiguda: misunu.
Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí.
24 Ilia da Yelusaleme fisili, ahoasea, dunu amo da Nama odoga: i, amo ilia bogoi da: i hodo ba: mu. Ifidi amo da ilia da: i hodo nanebe da bogosu hame ba: mu. Amola lalu ili nenana da ha: ba: dosu hame dawa: Amola amo liligi ba: sea, fifi lasu dunu huluanedafa da higale ba: mu.” Sia: ama dagoi
“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

< Aisaia 66 >