< Aisaia 49 >

1 Fifi asi gala fi sedagawane esala! Na sia: nabima! Musa: hemonega na da hame lalelegeiya, Hina Gode da na Ea hawa: hamomusa: gini ilegei dagoi.
Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
2 E da na sia: , amo gegesu gobihei mei bagade defele hamoi dagoi. E da Ea loboga na gaga: i, amola na hou e da dadi agoane, agesoi amola hawa: hamomusa: momagei dagoi, agoane hamoi.
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
3 E da nama amane sia: i, “Isala: ili! Di da Na hawa: hamosu dunu. Dia hawa: hamobeba: le, dunu huluane da Nama nodomu.”
Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
4 Na da amane sia: i, “Na da hawa: hamoi, be hamedei agoane ba: i. Na gasa da ebelei dagoi, be na da udigili hawa: hamoi dagoi. Be Hina Gode da na hou amola na asigi dawa: su huluane dawa: beba: le, na hawa: hamoi defele Nama bidi imunu.
Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
5 Na da hame lalelegeiya, Hina Gode da na ilegei. E da Ea fi dunu amo Isala: ili dunu afafai dagoi, amo bu oule misa: ne, E da na hawa: hamomusa: ilegei dagoi. Hina Gode da nama nodosa, amola E da nama gasa i dagoi.
Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
6 Hina Gode da nama amane sia: i, “Dafawane! Di da Isala: ili dunu amo da hame bogoi esala, ilima ilia musa: gasa bagade hou ilima bu imunu. Be amo baligili, osobo bagade fifi asi gala huluane da gaga: sudafa ba: ma: ne, Na da di Dienadaile dunu ilima gamali agoane asunasimu.
Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
7 Isala: ili fi ilia Hadigi Gode amola Gaga: su dunu, da dunu ilima eno dunu amola fifi asi gala ilia bagade higasa, amola dunu amo da ouligisu dunu ilia udigili hawa: hamosu dunu esala, E da ilima amane sia: sa, “Hina bagade dunu ilia da di ba: sea, ilia da dima nodomusa: wa: legadomu. Hina bagade ilia mano amola ilia di ba: sea, dima nodomusa: , gududafa begudumu. Bai Hina Gode da Ea hawa: hamosu dunu ilegei dagoi. Amola Isala: ili fi ilia Hadigi Gode, da Ea ilegele sia: i amo fisimusa: hame dawa:
Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
8 Hina Gode da Ea fi dunu ilima amane sia: sa, “Dilia gaga: su eso ilegei doaga: sea, Na da hahawane hou dilima olelemu. Dilia da Nama fidima: ne disia, Na da di fidimusa: adole imunu. Na da dili gaga: mu amola dilia dioba: le, fifi asi gala fi huluane ilima gousa: su hamomu. Wali dilia soge da wadela: lesi dagoi diala. Be Na hamobeba: le, dilia da amo soge ganodini bu esala sodomu.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
9 Na da se dabe iasu diasu ganodini sali dunu ilima, “Hahawane gadili masa! Amola dunu gasi ganodini esala, ilima ‘Hadigi amoga misa’, amane sia: mu. Ilia da sibi amo da agologa gisi naha, amo defele ba: mu.
láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
10 Ilia da hame ha: mu amola hano hame hanamu. Eso da gia: sea amola hafoga: i sogega gia: sea ilia da se hame nabimu. Bai ilima asigi Dunu da ili oule masunu. E da ili hano si galoba amoga oule masunu.
Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
11 Na fi dunu hahawane masa: ne, Na da logo bagade amo goumiga masa: ne hahamomu.
Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
12 Na fi dunu da soge sedaga amoga bu misunu. Ilia da soge ga (north) amola gusudili, amola Asawane ga (south) soge amoga misunu.
Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
13 Fedege sia: Muagado dialebe liligi! Dilia gesami hea: ma! Osobo bagade! Hahawaneba: le, wele sia: ma! Goumi amola da fudagala: lewane gesami hea: mu da defea. Hina Gode da Ea fi ilia dogo denesimu. Ilia da se bagade naba, be E da ilima asigimu.
Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
14 Be Yelusaleme dunu da amane sia: sa, “Hina Gode da nini yolesi dagoi. E da nini gogolei dagoi.”
Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
15 Amaiba: le, Hina Gode da bu adole iaha, “Uda da ea dudubu mano gogolema: bela: ? E da ea mano lalelegei amoma hame asigima: bela: ? Hame mabu! Be osobo bagade ame da ea mano gogolei ganiaba, Na da dili hamedafa gogolemu.
“Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
16 Yelusaleme! Na da di gogolemu da hamedei. Na da dia dio amo Na lobo gafe da: iya dedei dagoi.
Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
17 Yelusaleme! Di da mugului dagoi. Be dunu ilia da di bu gagumusa: misunu da gadenesa. Dunu ilia da di wadela: lesi amo da fisili masunu.
Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
18 Ba: le gagale, hou hamobe ba: ma! Isala: ili fi da gilisilala. Ilia da di Yelusaleme amoga buhagimu. Na da Godedafa esala, amo dafawaneyale dawa: ma. Amo defele, di da dia bu misunu mano amo hahawane ba: mu. A: fini da ea uda gaguli lasu eso amoga ea nina: hamoi liligi hahawane ba: sa, amo defele di da ili hahawane ba: mu.
Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
19 Dia soge da wadela: lesi dagoi, amola dunu hame esalebe ba: i. Be wali dunu bagohame da buhagili manebe ba: beba: le, dia soge da fonobahadidafa agoane ba: mu. Amola dunu ilia da di wadela: lesili, fisili asi, amo da dima sedagadafa esalebe ba: mu.
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
20 Amola dia fi dunu ilia da mugululi asi soge amo ganodini lalelegei, eso enoga da dima amane sia: mu, “Amo soge da fonobahadidafa. Ninia eno soge amo ganodini esaloma: ne hanai.”
Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
21 Amasea, di da dima amane gobele sia: mu, “Amo mano huluane wali esalebe, nowa da nama ima: ne lalelegebela: ? Na da na mano huluane fisi dagoi amola eno lalelegemu hamedei ba: i. Na da enoga sefasili, mugululi asi. Nowa da amo mano asigilama: ne, fofobela: ? Na da nisu esalebe ba: i! Amo mano huluane da habidili misibela: ?”
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
22 Hina Gode Ouligisudafa da Ea fi dunu ilima amane sia: sa, “Na da fifi asi gala ilima dawa: digisu olelemu. Amasea, ilia da dia mano dima bu oule misunu.
Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
23 Hina bagade ilia da dima ada agoane ba: mu amola hina bagade uda da dima ame agoane ba: mu. Ilia dima beguduli, dima nodomu. Ilia da ilia hou fofonobone, dima nodomu. Amasea, Na da Hina Godedafa amo di da dawa: mu. Nowa da Na fidisu lama: ne ouesalea, e da da: i diosu hame ba: mu.”
Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
24 Di da dadi gagui dunu ea wamolai liligi bu samogemu dawa: bela: ? Di da nimi bagade ouligisu dunu amo ea se dabe iasu diasu hamosu dunu gagulaligi, amo gaga: mu dawa: bela: ? Hame mabu!
Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
25 Be Hina Gode da amane bu adole iaha, “Na da amo defele hamomu. Na da dadi gagui ea se iasu diasu hamosu dunu gagulaligi, amo bu samogemu. Amola nimi bagade ouligisu dunu ea liligi lai amo bu samogemu. Nowa da dima gegesea, Na da ilima gegemu. Amola Na da dia manolali gaga: mu.
Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 Na da hamobeba: le, dima se iasu dunu da sinidigili, sama da ea sama medole legemu. Ilia da medole legesu hou, amola ougi bagade hou hamonanebeba: le, adini bagade ba: i dunu agoane ba: mu. Amasea, Na da Hina Gode, dilia gaga: su dunu, amola dilia se iasu diasu logo doasisu dunu, amo osobo bagade dunu huluanedafa da dawa: mu. Na da Isala: ili dunu ilia gasa bagade Gode, amo ilia da dawa: mu.
Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

< Aisaia 49 >