< Aisaia 42 >

1 Hina Gode da amane sia: sa, “Na Hawa: Hamosu Dunu amoma Na da gasa iabe da goea. Na da E ilegei dagoi. Na da Ema hahawane gala. Na da Na A: silibu Ema imunu, amola E da fifi asi gala huluane ilima moloidafa hou gaguli misunu.
“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró, àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀; Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀ òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.
2 E da hame wele sia: mu amola gasawane hame sia: mu. E da moilai logoga gasa fili bagade sia: su hame sia: mu.
Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè, tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.
3 E da saga: selefai amo hame fimu. E da gamali ea sawa: ugugulala amo hame ha: ba: domu. E da moloidafa hou eso huluane dialoma: ne, dunu huluane fidima: ne, oule misunu.
Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́, àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa. Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;
4 E da hobea misunu hahawane hou dafawaneyale dawa: su hou hame fisimu amola E da hame beda: mu. E da osobo bagadega moloidafa hou dialoma: ne, ilegemu. Soge sedaga fi dunu da hanaiwane Ea olelesu nabimusa: ouesala.
òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé. Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”
5 Gode da mu hahamone, fadegale gai. E da osobo bagade amola fi huluane amo ganodini esalebe amo hahamoi. E da osobo bagade fifi asi gala dunu huluane ilima esalusu amola mifo i dagoi. Amola wali Hina Godedafa da Ea Hawa: Hamosu Dunu Ema amane sia: sa,
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde, tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn, Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:
6 “Na, Hina Gode, da Dima misa: ne wele sia: nanu, Dima moloidafa hou da osobo bagadega dialoma: ne, Dia amo hou hamoma: ne, gasa i dagoi. Dia hamobeba: le, Na da fifi asi gala dunu huluane ilima gousa: su hamomu. Dia hamobeba: le, Na da fifi asi gala huluane ilima hadigi imunu.
“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo, Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú. Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà
7 Di da si dofoi dunu amo ilia si fadegamu. Amola dunu ilia gasi se iasu diasu ganodini amo ilia halegale masa: ne, ilia se dabe iasu logo doasimu.
láti la àwọn ojú tí ó fọ́, láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.
8 Na, Nisu fawane da Hina Gode, Dia Gode. Eno ‘gode’ liligi da Na Hadigi gilisili hame lamu. Hamedei ‘gode’ loboga hamoi liligi da Nama nodosu gilisili lama: ne, Na da logo hame doasimu.
“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí! Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.
9 Na da hobea misunu hou musa: olelei dagoi. Amola amo hou defele da doaga: i dagoi. Wali Na da gaheabolo hou hobea misunu, amo dilima olelemu.”
Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé, àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé; kí wọn tó hù jáde mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”
10 Hina Godema gesami gaheabolo hea: ma! Osobo bagade fifi asi gala huluane! Ema nodone gesami hea: ma! Dilia dunu amo dusagai ganodini hano wayabo bagadega ahoa! Ema nodoma! Amola liligi huluane hano wayabo bagade amo ganodini esala! Ema nodoma! Soge sedaga amola amo ganodini esalebe dunu huluane! Ema gesami hea: ma!
Kọ orin tuntun sí Olúwa ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá, ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Hafoga: i soge amola moilai amo ganodini diala da Godema nodomu da defea. Gida fi dunu da Ema nodomu da defea. Nowa dunu da Sila amo ganodini esala da goumi da: iya hahawaneba: le wele sia: mu da defea.
Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè; jẹ́ kí ibùdó ti àwọn ìlú Kedari ń gbé máa yọ̀. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀; jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.
12 Dunu da soge sedagaga esala, ilia da hadigi amola nodosu Hina Godema imunu da defea.
Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.
13 Hina Gode da gegesu dunu defele gegemusa: ahoa. E da gegesu hamoma: ne, momagei amola hanaiwane esala. E da gegemusa: halasa. E da Ea ha lai hasanasimusa: , Ea gasa hou olelesa.
Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára, yóò ru owú sókè bí ológun; yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun, òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.
14 Gode da amane sia: sa, “Na da eso bagohame ouiya: le, Na fi dunuma hame adole i. Be wali Na hamomu eso da doaga: i dagoi. Na da uda da mano lalelegemu gadenesea wele sia: sa, amo defele Na da wele sia: sa.
“Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró. Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí, mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.
15 Na da agolo amola goumi wadela: lesimu. Na da gisi amola ifa bioma: ne hafoga: mu. Na da hano fago amo afadenene bu hafoga: i soge hamomu. Amola hano wayabo hafoga: mu.
Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù, Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù n ó sì gbẹ àwọn adágún.
16 Na da Na dunu si dofoi amo logo ilia da musa: hame ahoasu, amoga oule masunu. Na da ilia gasi afadenene, bu hadigi hamomu amola soge fofagoi amo bu umi hamomu. Na da amo sia: i dagoi amola amo sia: i liligi Na da mae fisili, didili hamomu.
Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀, ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ; Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná. Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí; Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
17 Be dunu huluane da ‘gode’ loboga hamoi liligi dafawaneyale dawa: sa, amola ilia loboga hamoi liligi da ‘gode’ ilia da sia: sa, amo huluane Na da fonobomu amola ilia da gogosiasu bagade ba: mu.
Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà, tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’ ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.
18 Hina Gode da amane sia: sa, “Dilia ge hamedei dunu! Nabima! Dilia si dofoi dunu! Noga: le ba: ma!
“Gbọ́, ìwọ adití, wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!
19 Na hawa: hamosu dunu (Isala: ili fi) da si dofoidafa. Amola Na sia: ne iasu dunu Na asunasisu da ge hamedei.
Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi, àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán? Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí, ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?
20 Isala: ili! Dilia da bagadewane ba: i dagoi. Be ba: i liligi hame lalegagui. Dilia da nabima: ne ge gala. Be hamedafa nabi.”
Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí; etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”
21 Hina Gode da gaga: musa: hanai gala. Amaiba: le, E da Ea sema amola Ea olelesu gaguia gadoi. Amola E da Ea fi amo Ea olelesu fa: no bobogema: ne, E da hanai galu.
Ó dùn mọ́ Olúwa nítorí òdodo rẹ̀ láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.
22 Be wali Ea fi dunu da wamolai dagoi ba: sa. Ilia da se dabe iasu diasu amo ganodini ga: si amola wamolegei dagoi ba: sa. Dunu eno da ilia liligi huluane lai dagole, dunu afae ilia gaga: musa: manebe hame ba: i.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun tí a sì kó lẹ́rú, gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun, tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n. Wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀; wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”
23 Dunu afae da amo sia: nabima: bela: ? Dilia da wali amola fa: no amola noga: le nabimu da defea.
Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
24 Nowa da eno dunu ilia Isala: ili fi wadela: lesima: ne amola ilia liligi lama: ne logo doasibala: ? Hina Gode Hisu da amo logo doasi. Bai ninia da Ema wadela: le hamoi. E da ninia Ea hanai defele amola Ea olelesu nabawane esaloma: ne dawa: i galu. Be ninia da higa: i.
Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun, àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí? Kì í ha ṣe Olúwa ni, ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí? Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀; wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
25 Amaiba: le, E da Ea ougi ninima olelei amola ninia gegesu amo ganodini Ea se iasu nabima: ne, logo doasi dagoi. Ea ougi gia: i bagade lalu agoane Isala: ili soge huluane ganodini nenanu ba: i dagoi. Be amo hou ninima doaga: i, ninia da hame dawa: i. Ninia da amoga dawa: hamedafa lasu.
Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí, rògbòdìyàn ogun. Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀ èdè kò yé wọn; ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.

< Aisaia 42 >