< Aisaia 37 >
1 Hina bagade Hesigaia da ilia sia: ne iasu nababeba: le, da: i dioiba: le ea abula gadelale, wadela: i eboboi abula idiniginisili, Hina Gode Ea Debolo Diasuga asi.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 E da Ilaiagime (hina bagade ea diasu ouligisu dunu) amola Siebena (hina bagade ea sia: dedesu dunu) amola gobele salasu ouligisu dunu amo balofede dunu Aisaia (A: imose egefe) ema asunasi. Ilia amola da wadela: i eboboi abula amoga idiniginisili ahoanu.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Hesigaia da sia: beba: le, ilia da Aisaiama amane sia: i, “Wali eso da se nabasu eso. Ninia da se iasu ba: i dagoi amola gogosia: i bagade. Ninia da uda amo mano lalelegemu gala, be gasa hameba: le, lalelegemu hamedei, nini da agoaiwane gala.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Asilia hina bagade da ea bisilua ouligisu dunu amo Esalebe Gode Ema gademusa: asunasi dagoi. Dia Hina Gode da amo gadesu nabalu amola dunu da gadesu sia: i, ilima se imunu da defea. Amaiba: le, ninia fi dunu amo da mae bogole esalebe ba: sea, amo fidima: ne, di Godema sia: ne gadoma.”
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 Aisaia da hina bagade Hesigaia ea sia: ne iasu nababeba: le,
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 e da amo sia: bu adole iasi, “Asilia dunu da dili beda: ma: ne, Hina Gode da dilia gaga: mu hamedei sia: sa. Be Hina Gode da dili mae beda: ma: ne sia: sa.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Hina Gode da hamobeba: le, Asilia hina bagade da udigili sia: ne iasu nababeba: le, hi sogega buhagimu. Amasea, Hina Gode da hamobeba: le, amogawi eno dunu da Asilia hina bagade fane legemu.”
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Asilia bisilua ouligisu da hina bagade da La: igisi fisili, Libina moilaiga gegemusa: asi, amo nabi. Amaiba: le, e da amoga ea sia: nabimusa: asi.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 Asilia dunu da sia: nabi, amo Sudane hina bagade ea dio amo Dehaga da Idibidi dadi gagui gilisisu amo bisili, Asilia dunu doagala: musa: manebe nabi. Asilia hina bagade da amo sia: nababeba: le, Yuda hina bagade Hesigaiama meloa dedene iasili, amane sia: i,
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 “Gode amoma di da dafawaneyale dawa: be, amo da na loboga di hame gagulaligimu sia: i. Be amo ogogosu sia: mae nabima.
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Di da sia: ne iasu nabi dagoi. Asilia hina bagade da adi fifi asi gala wadela: musa: ilegesea, e da ea hanaiga agoane hamosa. Di da hobeale masunu logo ba: ma: ne dawa: bela: ? Hame mabu!
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Na musa: fi dunu da Gousa: ne, Ha: ila: ne amola Lisefe, amo moilai bai bagade wadela: lesi dagoi. Amola ilia da Bedidene dunu Dila: sa moilai bai bagade amo ganodini esalu, fane legei dagoi. Amola ilia ‘gode’ liligi ili gaga: mu hamedei ba: i.
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Ha: ima: de, A:ba: de, Sefafa: ime, Hina amola Aifa, ilia hina bagade dunu da habila: ?”
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 Hina bagade Hesigaia da meloa dedei amo sia: adole iasu dunuma lale, idi. Amalalu, e da Debolo diasuga asili, Hina Gode da meloa dedei ba: ma: ne, ligisi.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 Amola e da amane sia: ne gadoi,
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 “Isala: ili Hina Gode Bagadedafa! Di da Dia fisu amo ougia gala esalebe liligi gadodili diala amoga fili, Disu da Godedafa amola Disu da osobo bagade fifi asi gala huluane ilima Hina esala. Disu da osobo bagade amola mu hahamoi.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 Wali, Hina Gode! Ninia sia: nabima! Amola ninima doaga: i hou ba: ma! Gode Esalebe! Sena: gelibi ea Dima gadesu sia: nabima!
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Hina Gode! Asilia hina bagade ilia da fifi asi gala bagohame wadela: lesi dagoi, amola ilia soge wadela: lesilalu asi. Amo ninia dawa:
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 Amola ilia da amo dunu ilia ‘gode’ liligi laluga ulagisi. (Be amo ‘gode’ liligi da ‘gode’ hame. Ilia da udigili ‘gode’ liligi loboga hamoi. Ilia da amo liligi ifa amola igiga hamoi.)
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 Defea! Ninia Hina Gode! Osobo bagade fifi asi gala huluane amo Disu fawane da Godedafa dawa: ma: ne, Dia nini, Asilia dunu nini mae wadela: lesima: ne, gaga: ma.
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Amalalu, Aisaia da hina bagade Hesigaiama sia: adole iasi. Hina Gode da Hesigaia ea sia: ne gadosu nababeba: le, E da bu Sena: gelibi ema sia: adole iasima: ne, sia: i,
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 “Sena: gelibi! Yelusaleme fi da di higasa amola dia houba: le oufesega: sa.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Di da nowama gadesu amola fofonobosu, di adi dawa: bela: ? Di da Na, Isala: ili Hadigi Gode amoma mae nodone, gadesa.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Di da Nama hidale sia: ma: ne, di sia: adole iasu dunu asunasi. Di da dia sa: liode amoga Lebanone baligili heda: i goumi hasanasi, hidale sia: i. Di da gadodafa heda: i dolo ifa amola noga: idafa “saibalase” ifa hedofale, amola iwila bagade ganodini golili sa: ili dogoadafa doaga: i, di da hidale agoane sia: i.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 Di da si dogone amola ga fi dunu ilia soge ganodini hano mai, amola dia dadi gagui dunu ilia da Naile Hano amoga ososa: giba: le, amo hano da hafoga: i dagoi, amo di da hidale sia: i.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 Be di da hame nabibala: ? Na da musa: hemonega, amo hou huluane ilegei dagoi. Amola wali Na da amo hou hamoi dagoi. Na da dima gagili sali moilai bai bagade amo isu legesu hamomusa: wadela: lesima: ne, amo Nisu da dima gasa i.
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 Dunu amo ganodini esalu, ilia gasa da hamedei galu. Ilia da bagadewane beda: iba: le, asigi dawa: su hobea: i dagoi. Ilia da ifabi gisi ganodini o gagalobo diasu da: iya gadodili bugi, amo da gia: i bagade gusudi mabe fo masea, biobe, amo defele ba: i.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Be dia hou huluane amola dia ahoabe Na dawa: Di da Nama gasa fili ougili sia: be Na dawa:
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Na da amo Nama gasa fili ougi sia: sia: ne iasu lai dagoi. Amola wali Na da dia mi amoga ma: go heda: mu, amola dia lafi ganodini ouli daba: misimu. Amola Na da logo di misi, amoga di bu hiouginana masunu.”
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 Amalalu, Aisaia da hina bagade Hesigaiama amane sia: i, “Fa: no misunu hou dawa: digisu hahamosu ba: ma! Wali ode amola aya ode dilia da ha: i manu udigili sogega heda: i fawane manu. Be gasida ode, di da gagoma sagai faimu, amola dilia da waini efe sagai fage manu.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Nowa dunu ilia da Yuda soge ganodini mae bogole esala, da sagai liligi amo ilia difi da osoba gududafa daha, amola fage noga: i legesa amo defele ba: mu.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Hina Gode Bagadedafa da amo hamoma: ne sia: i dagoiba: le, dunu mogili da Yelusalemega amola Saione Goumiga mae bogole esalebe ba: mu.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Hina Gode da Asilia hina bagade ea hou olelema: ne, amane sia: i, “E da amo moilai bai bagade golili hame sa: imu. E da dadi afae amoga hame gala: mu. Dadi gagui dunu gaga: su liligi gaguiwane da moilai bai bagade gadenene hamedafa misunu. Amola, moilai bai bagade gagoi wadela: lesima: ne, ilia da osobo bi hame gagagula heda: mu.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 E da moilai bai bagade mae golili sa: ili, ea misi logo amoga buhagimu. Bai Na, Hina Gode, da sia: i dagoi.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 Dunu huluane da Na hou da moloidafa dawa: ma: ne, amola Na da Na hawa: hamosu dunu Da: ibidi ema sia: i dagoiba: le, Na da Yelusaleme gaga: mu,” Hina Gode da amane sia: i.
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Hina Gode Ea a: igele dunu da gasia Asilia fisisu amoga asili, dadi gagui dunu 185,000 agoane fane legei dagoi. Hahabe, ilia huluane bogoi dialebe ba: i.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Amalalu, Asilia hina bagade Sena: gelibi da fisili, Ninefe moilai bai bagadega sinidigi.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 Eso afaega, e da ea ‘gode’ liligi amo Niseloge ea sia: ne gadosu diasu ganodini sia: ne gadolalebe, egefe aduna amo A: dala: melege amola Sialisa da elea gobiheiga e medole legele, hobeale, Elala: de sogega hobea: i. Egefe eno amo Isaha: done, da Sena: gelibi ea hina bagade sogebi lai dagoi.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.