< Aisaia 1 >

1 Sia: da amo buga ganodini dedei da sia: amo Gode da Aisaia (A: imose egefe) amoma olelei. Amo sia: da Yuda fifi asi gala amola Yelusaleme fi, ilia hou olelesa. Amo esoga, hina bagade amo da Yuda fi ouligisu da Asaia, fa: no Youda: me, amola A: iha: se amola Hesigaia
Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
2 Hina Gode da amane sia: i, “Osobo bagade amola mu! Na sia: nabima! Na fofoi mano da nama higale odoga: i.
Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
3 Bulamagau da ilia ouligisu dunu dawa: Amola dougi da ilia ouligisu da ilima ha: i manu iabe sogebi dawa: Be amo hou da Na fi dunu Isala: ili fi, amo ilia hou baligisa. Ilia da amo hou hamedafa dawa:
Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
4 Dilia wadela: idafa dunu fi! Dilia da wadela: lesi dagoi ba: mu. Dilia da wadela: i hou hamonanebeba: le dafasa. Dilia da Hina Gode, Isala: ili dunu fi ilia Hadigi Gode amo higa: i dagoi. Dilia da Ema hihini baligi fa: i.
Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
5 Dilia da abuliba: le mae fisili odoga: sala: ? Dilia da Gode Ea se iasu eno lamu hanabela: ? Isala: ili fi! Dia dialuma da fa: ginisisu amoga dedeboi dagoi amola dia dogo amola asigi dawa: su da oloi gala.
Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
6 Dia dialuma da: iya asili dia emo gafe amoga doaga: le, dia da: i hodo amo ganodini oloi bagade fawane ba: sa. Dia da: i da fa: ginisisu amola fofonomasu amola aiya amoga dedeboi dagoi. Dia fa: ginisi da hame dodofei amola hame sosone dedeboi amola manoma hame legei.
Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
7 Dia soge da wadela: lesi dagoi, amola dia moilai bai bagade huluane da laluga nei dagoi. Ga fi dunu da dia soge huluane lale wadela: lesisa amola di da udigili lela ba: lala.
Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
8 Yelusaleme fawane da hame mugului, be ha lai dunu da ema gegenana. Yelusaleme da sosodo aligisu dunu ea diasu waini sagai ganodini gala o ifabi diasu dadami sagai ganodini amo defele hame gaga: iwane ba: sa.
Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
9 Hina Gode Bagadedafa da dunu mogili esaloma: ne hame gaga: i ganiaba, Yelusaleme da Sodame amola Goumola defele, wadela: lesi dagoi ba: la: loba.
Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
10 Yelusaleme! Dia ouligisu dunu ilia da Sodame amola Goumola elea ouligisu dunu defele ba: sa. Hina Gode da dilima sia: be noga: le nabima! Ninia Gode Ea olelesu noga: le dawa: digima.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
11 Hina Gode da amane sia: sa, “Dilia adi dawa: bela: ? Dilia da Nama gobele salasu dilia da eso huluane Nama iaha, amo Na da hanabela? Hame mabu! Dilia da Nama sibi bagohame amola ohe fi ilia sefe bagade Nama gobele sasalasu, be Na da amo lamu higa: i gala mabu. Na da bulamagau gawali amola sibi amola goudi ilia maga: me bagade ba: beba: le, helei bagade naba.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
12 Dilia da Nama nodone sia: ne gadomusa: masea amo liligi gaguli misa: ne nowa adobela: ? Nowa da dili, Na Debolo diasu ganodini laloma: ne adobela: ?
Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
13 Dilia gobele salasu liligi gaguli misunu da hamedei liligi. Dilia manoma gobele salasu gabusiga: Na da higale naba. Dilia Oubi Gaheabolo Lolo Nasu amola dilia Sa: bade eso amola dilia sia: ne gadosu gilisisu huluane Na higasa. Amo hou huluane da dilia wadela: i hou amoga wadela: lesi dagoi.
Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
14 Na da dilia Oubi Gaheabolo lolo Nasu amola “hadigi” gilisisu eso huluane bagade higasa. Ilia da Nama dioi bagade liligi amola Na da amo liligi bu dioiwane gaguli masunu higa: i.
Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
15 Dilia da sia: ne gadomusa: , dilia lobo ligia gadosea, Na da dili hame ba: mu. Dilia da baligiliwane sia: ne gadosea, be Na da hame nabimu. Bai dilia lobo da maga: mega dedeboi dagoi.
Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
16 Sinidigima! Dilia da: i dodofelalu, fofoloi agoane ba: mu da defea. Na da ba: loba, dilia wadela: i hou fawane hamosa. Amo yolesima!
“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
17 Hou ida: iwane hamoma: ne, logo hogoma! Moloidafa hou logo hogoma! Nowa da eno dunuma se laha, amo fidima! Guluba: mano fidima! Didalo amola gaga: ma!”
kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
18 Hina Gode da amane sia: sa, “Amo hou ninia da wahadafa hahamomu. Dilia da wadela: i hou hamobeba: le, maga: mega ledo hamoi dagoi ba: sa. Be Na da dili dodofesea, dilia da mu gohona: defele, ahea: iaidafa agoane ba: mu. Dilia ledo da ulasuiya: i agoane ba: sa, be dilia da sibi hinabo defele sua: iai agoane ba: mu.
“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
19 Dilia da Na sia: nabawane hamosea, dilia da soge ea ha: i manu gami noga: i agoai manu.
Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
20 Be dilia da Na sia: higasea, dilia da dafawane bogomu. Na, Hina Gode, da sia: i dagoi!”
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
21 Yelusaleme fi da musa: hou noga: i hamosu. Be wali ilia da da: i bidi lasu uda ea hou defele hamosa. Musa: amo moilai bai bagade da moloidafa dunu amoga nabai galu, be wali fane legesu dunu fawane esalebe ba: sa.
Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
22 Yelusaleme! Di da musa: silifa noga: iwane ba: su. Be wali di da hamedei moilai bai bagade agoane ba: sa. Di da musa: waini hano ida: iwane gala ba: su. Be wali di da hano gamogai agoane ba: sa.
Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
23 Dia ouligisu dunu ilia da odoga: su dunu, amola ilia da wamolasu dunu ilia dogolegei agoane esala. Ilia da eso huluane hano suligisu bidi hahawane laha. Ilia da fofada: su diasu ganodini guluba: mano hame gaga: sa, amola didalo ilila: hou gaga: ma: ne sia: sea, ilia sia: hame naba.
Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
24 Amaiba: le, Hina Gode Bagadedafa, Isala: ili dunu ilia gasa bagade Gode, amo Ea sia: nabima! Dilia da Nama ha lai hamobeba: le, Na da dilima dabe imunu. Amasea, dilia da Nama bu hame mosolamu.
Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
25 Na da dilima doagala: mu. Gouli amola silifa ilia gobele, ledo huluane fadegasa, amo defele Na da dilia ledo fadegale fasimu.
Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
26 Na da musa: Isala: ili fi ilia ouligisu dunu amola sia: ne iasu dunu, amo defele dilima bu imunu. Amasea, eno dunu ilia da Yelusaleme amoma “Moloidafa Moilai Bai Bagade” amola “Dafawaneyale Dawa: su Moilai Bai Bagade” dima asulimu.”
Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
27 Hina Gode Ea hou da moloidafa. Amaiba: le, E da Yelusaleme amo gaga: mu, amola nowa amo moilai bai bagade ganodini da wadela: i hou fisili, Godema sinidigisia, E da amo dunu gaga: mu.
A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
28 Be nowa da wadela: i hou hamosea amola Hina Godema odoga: sea, Gode da goudamu. Nowa da E higale yolesisa, E da amo dunu fane legemu.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
29 Dilia da udigili ifa amoma sia: ne gadobeba: le, amola sema ifabi bugiba: le, gogosiane asigi bagade ba: mu.
“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
30 Dilia da bioma: ne “ouge” ifa defele biomu. Amola sagai amoma ilia hano hame iasea biobe defele, dilia da biomu.
Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
31 Bioi gisi da lalu geso amoga lalu hamone, nei dagoi ba: sa. Amo defele, gasa fi dunu da ilisu wadela: i hamobeba: le, wadela: lesi dagoi ba: mu. Amola ilia mae wadela: lesima: ne, enoga gaga: mu da hamedei ba: mu.
Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

< Aisaia 1 >