< Mui 35 >

1 Gode da Ya: igobema amane sia: i, “Di da Bedele sogega hedolo asili, esaloma. Amoga Nama oloda hamoma. Na da Gode amo di da Isoba: le hobealoba, Na da dima misi.”
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
2 Amaiba: le, Ya: igobe da ea sosogo fi amola dunu huluane ema gilisi, ilima amane sia: i, “Ga loboga hamoi ‘gode’ liligi dilia gagui amo huluane fadegale fasima. Dilia nigima: dodofelalu, abula gaheabolo salima.
Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
3 Ninia da amo soge yolesili, Bedele moilaiga masunu. Amoga na da Gode amo da na se nabasu ganodini fidi, amola na lalebe soge huluane E da gilisili lala, amoga na da oloda hamomu.
Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
4 Amaiba: le, ilia da loboga hamoi ‘gode’ liligi amola gegagulu ilia ge ganodini sali, amo huluane duga: le, Ya: igobema i. Ya: igobe da amo liligi huluane ‘ouge’ ifa Siegeme soge ganodini amo haguduga uli dogone sali.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
5 Amalalu, ilia da logoga asili, moilai dunu huluane gadenene esalu da beda: i bagade ba: i. Ilia da beda: iba: le, Ya: igobe ea fi hame se bobogei.
Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
6 Ya: igobe amola ea fi huluane da Luse (wali ea dio da Bedele), Ga: ina: ne soge ganodini amoga doaga: i.
Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
7 Amoga e da oloda hamone amola amo soge dio eno asuli amo Ele Bedele. Bai amoga e da ea olaba: le hobeale ahoanoba, Gode da ema misi.
Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
8 Lebega ea hawa: hamosu uda amo Debola da amoga bogoi. Ea da: i hodo ilia da ‘ouge’ ifa Bedele sogebi amoga ga (south) dialu, amo hagudu uli dogone sali. Amaiba: le, amo ifaga ilia da ‘Disu Ouge Ifa’ dio asuli.
Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
9 Ya: igobe da Mesoubouda: imia yolesili, bu Ga: ina: ne sogega bu misini, Gode da ema bu misini, ema hahawane dogolegele fidima: ne sia: i.
Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
10 Gode da ema amane sia: i, “Dia dio da Ya: igobe, be amo fa: no dia dio da Isala: ili.” Amaiba: le, Gode da ema Isala: ili dio asuli.
Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
11 Amola Gode da ema amane sia: i, “Na da Gode Bagadedafa! Di mano bagohame lalelegema! Digaga fi da fifi asi gala bagohame ba: mu, amola di da hina bagade dunu ilima aowa ba: mu.
Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
12 Soge Na da A: ibalaha: me amola Aisage elama i dagoi, amo na da dima imunu. Amola fa: no digaga fibi ilima imunu.”
Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
13 Amalalu, Gode da yolesili asi.
Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
14 Amogawi, Gode da amo sogebiga ema sia: musa: misiba: le, Ya: igobe da wanonesisu gele bugili, amo Godema modale ligiagama: ne, amo da: iya waini amola olife susuligi sogadigi.
Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
15 E da amo sogebiga dio asuli, amo Bedele.
Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
16 Ya: igobe amola ea sosogo fi da Bedele yolesili, logoga ahoanoba, Efala: de amoga mae doaga: le, La: isele da mano lamusa: se nabi. E da mano lalelegemu logebeba: le, gasa bagade ba: i.
Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
17 Mano lamusa: se bagade nabaloba, mano lasu fidisu uda da ema amane sia: i, “La: isele! Mae beda: ma! Dunu mano da lalelegei dagoi.
Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
18 Be La: isele da bogolalu, amola mifo laha da gadenene dagoloba, ea manoma dio asuli amo Benoni. Be Ya: igobe da ema Bediamini dio asuli.
Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
19 La: isele da bogoi. Ilia da ea da: i hodo Efala: de moilai logo ahoasu dafulili uli dogoi. Amo moilai ea dio wali da Bedeleheme.
Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
20 Ya: igobe da dawa: ma: ne gele wanonesisu amoga bugi, amola wali amo da La: isele ea uli dogoi amoga dawa: ma: ne diala.
Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
21 Ya: igobe da asili, diasu gagagula heda: i, ea dio Ede amo baligili, ea abula diasu gagui.
Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
22 Ya: igobe da amo soge ganodini esaloba, ea mano Liubene da misini, Ya: igobe ea gidesedagi uda amo Biliha ema gilisili golai. Ya: igobe da amo hou nababeba: le, mi hanai galu. Ya: igobe ea dunu mano da fagoyale galu.
Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
23 Lia ea dunu manolali da Liubene (Ya: igobe ea magobo mano) Simione, Lifai, Yuda, Isiga amola Sebiulane.
Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
24 La: isele ea dunu manola da Yousefe amola Bediamini.
Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
25 La: isele ea hawa: hamosu uda Biliha amo ea dunu manola da Da: ne amola Na: badalai.
Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
26 Lia ea hawa: hamosu uda Siliba amo ea dunu manola da Ga: de amola A: sie. Amo dunu mano ilia da Mesoubouda: imia sogega lalelegei.
Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
27 Aisage da Ma: melei amo Hibalone moilaiga gadenene esalu. Amoga Ya: igobe da asi.
Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
28 Aisage da lalelegele, ode 180 esalu.
Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
29 E da amo ode bagohame lai dagoloba, bogoi. Ea mano Iso amola Ya: igobe da ea da: i hodo uli dogone sali.
Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.

< Mui 35 >