< Mui 33 >

1 Ya: igobe da Iso amola dunu 400 agoane logoga ahoanebe ba: i. Amaiba: le, e da ea mano huluane afafane, Lia, La: isele amola ea gidisedagi uda aduna, amo ouligima: ne ilima i.
Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
2 E da gidisedagi uda amola ela mano bisimusa: asunasili, Lia amola ea mano fa: no, amola fa: nodafa La: isele amola Yousefe amola asunasi.
Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
3 Ya: igobe da bisili, ea ola gadenene doaga: loba, fesuale agoane osoboga begudui.
Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
4 Be Iso da hehenane, Ya: igobe ouga: ne nonogoi. Ela da bagadewane dinanu.
Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
5 Iso da ba: le ga: le, uda amola mano ba: beba: le, amane sia: i, “Amo dima sigi maha da nowala: ?” Ya: igobe da bu adole i “Ada! Amo da mano, Gode da nama hahawaneba: le nama i.”
Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
6 Amalalu, gidisedagi uda aduna amola ela mano da misini begudui.
Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
7 Amalalu Lia amola ea mano misini amola fa: no Yousefe amola La: isele da misini, huluane da begudui.
Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
8 Iso da amane adole ba: i, “Be amo gilisisu eno da nama misi. Amo da adila: ?” Ya: igobe da bu adole i, “Amo da di hahawane ba: ma: ne, na da asunasi.”
Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
9 Be Iso da amane sia: i, “Be na da defele gagui gala. Dia liligi di fawane gaguma!”
Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
10 Be Ya: igobe da amane sia: i, “Di da na hou hahawane ba: sea, na udigili hahawane iasu lalegaguma. Amo na da dima ha: giwane edegesa. Bai di da na hahawane ba: beba: le, dia odagi da nama Gode Ea odagi agoane ba: sa.
Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
11 Gode da nama asigiba: le, nama bagade i dagoi. Na da sadiba: le, amo hahawane udigili iasu di lalegaguma.” Ya: igobe da ha: giwane sia: beba: le, Iso da ea iasu lai.
Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
12 Amalalu, Iso da amane sia: i, “Defea! Hadiga! Ani liligi momagele, ahoa: di! Na da dili bisili masunu.”
Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
13 Be Ya: igobe da bu adole i, “Di dawa: ! Mano ilia da gasa hame galebe amola sibi, eno lai gebo fi amola ilia mano na da dawa: lala. Eso afaiwane ninia amo gasawane sefasisia, ilia huluane bogogia: mu.
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
14 Di bisili masa. Na da gebewane fa: no bobogemu. Na da ilia gasa defele, lai gebo fi amola mano oule asili, Idome diasuga dima bu gilisimu.”
Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
15 Iso da bu sia: i, “Amasea na da na dunu mogili di ouligima: ne yolesimu.” Be Ya: igobe da bu adole i, “Mae dawa: ma! Na hanai da di da nama asigisa amo fawane hanai!”
Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
16 Amalalu, amo esoga, Iso da Idome sogega doaga: musa: asi.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
17 Be Ya: igobe da Sagode sogega asili, diasu gagui. Amola ea lai gebo golama: ne, diasu eno gaguli gagai. Amaiba: le, ilia amo diasuga Sagode dio asuli.
Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
18 Ya: igobe da Mesoubouda: imia sogega buhagiloba, e da hahawane Siegeme moilai bai bagade (Ga: ina: ne soge amo ganodini) amoga doaga: loba, e da sogebi Siegeme moilai bai bagade gadenene amoga ea abula diasu gilisisu gagui galu.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
19 E da amo ifabi sogebi bidi lama: ne, Ha: imo (Siegeme eda) amo egaga fi ilima silifa muni fage 100 amoga bidi lai.
Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
20 Amoga e da oloda hamoi. Amo oloda e da dio asuli amo Ele Elouhe (Isala: ili fi ilia Gode Ea Dio).
Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.

< Mui 33 >