< Mui 25 >

1 A: ibalaha: me da uda eno lai amo ea dio da Gedula.
Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
2 Gedula da A: ibalaha: mema mano eno lai. Ilia dio da Simala: ne, Yogasia: ne, Mida: ne, Midia: ne, Isaba: ge, amola Siua.
Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
3 Yogasia: ne ea mano da Siba amola Dida: ne. Didane ea mano fifi asi da Asiulaide fi, Ledusaide fi, amola Liumaide fi.
Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
4 Midia: ne ea mano fifi da Ifa, Ife, Ha: noge, Abaida, amola Eleda: ia. Amo huluane da Gedula ea mano fifi asi esalu.
Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
5 A: ibalaha: me da bogoloba, ea nana liligi huluane amo Aisagema i.
Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
6 Be e da esala, e da mano amo ea uda eno ema lai, ilima e da hahawane iasu liligi i. Amalalu, e da amo manolali, Aisage fisima: ne, gusu soge amoga asunasi.
Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
7 A: ibalaha: me da ode bagohame amo 175 esalu.
Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
8 Amalalu, e da mifo lalusu amo fisili, bogoi. E da ea aowalali dunu ilima buhagi.
Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
9 Ea mano aduna (Aisage amola Isiama: ile) da Ma: gafila gele gelabo (Ma: melei amoga gusudili gala) amo ganodini uli dogone Sali. Musa: Ifalone (Hidaide dunu Souha ea mano) da amo sogebi gagui galu.
Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
10 A: ibalaha: me da musa: amo sogebi, Hidaide dunuma bidi lai. Amoga A: ibalaha: me amola ea uda Sela gilisili uli dogoi ba: i.
inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
11 A: ibalaha: me da bogoi dagoi. Amo fa: no, Gode da A: ibalaha: me egefe amo Aisage hahawane dogolegele ilegele fidi. Aisage da amo esoga “Esalebe Gode da na Ba: lala Hano Uli Dou” amo gadenene esalu. Isiama: ile Egaga Fifi Misi
Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
12 A: ibalaha: me ea mano eno amo Isiama: ile, da Sela ea udigili hawa: hamosu Idibidi uda amo Ha: iga amoga lai. Ea hou da hagudu dedei diala.
Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
13 Isiama: ile egefelali ilia dio da dedei. Hidadea da magobo, amola fa: no magobo bagia, amola dogoa, amola ufi agoane dedei. Magobo mano da Niba: iode, amalu Gide amalu A: dabili, amalu Mibasa: me, amalu
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
14 Misima amalu Duma amalu Ma: sa amalu
Miṣima, Duma, Massa,
15 Ha: ida: de amalu Dima amalu Yide amalu Na: ifisi amalu Gedima.
Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
16 Amo da Isiama: ile egefelali. Ilia da fi gidayale gala ilia aowalali fi esalu. Ilia dio amo ilia da ilia moilai amola fisisu amoma asuli dagoi.
Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
17 Isiama: ile da ode 137 esalu. Amalalu, e da mifo labe fisili, bogoi dagoi.
Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
18 Isiama: ile ea lalelegei fi da soge amo da Idibidi amoma gusu galu amola logo Asilia moilaiga ahoasu gadenene dialu. Amo soge da Hafila soge amola Sioua hafoga: i soge amo dogoa dialebe ba: i. Amo dunu fi da A: ibalaha: me ea mano eno ilima hame gilisi.
Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
19 A: ibalaha: me egefe Aisage ea sia: dedei da agoane.
Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
20 Aisage da ode 40 esalu, e da Lebega (Bediuele, A:ila: mia dunu Badane Alame sogega esalu amo ea mano amola A: ila: mia dunu La: iba: ne amo ea dalusi) amo lai dagoi.
Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
21 Aisage ea uda da aligime esalu. Amaiba: le Aisage da Godema sia: ne gadoi. Gode da amo sia: ne gadosu nabi, amola Lebega da abula agui ba: i.
Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
22 Lebega da mano aduna lalelegemu galu. Be amo mano aduna da mae lalelegele, ea hagomo ganodini esala gegenanu. Lebega da fofogadigili Hina Godema amane adole ba: i, “Amo hou da abuli nama doaga: bela: ?”
Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
23 Hina Gode da ema bu adole i, “Fi aduna da dia hagomo ganodini esala. Dima da fi aduna lalelegemu. Afae da eno ea gasa baligimu. Magobo mano da eya ea hawa: hamosu dunu ba: mu.”
Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
24 Amalalu, Lebega da dunu mano aduna lalelegei.
Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
25 Bisili lai da haliga: me agoane ba: i. Ea gadofo da hinabo bagade galu. Amaiba: le ilia da ema Iso dio asuli.
Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
26 Fa: no mabe mano da Iso amo ea emo muguni amoga gagui dalebe ba: i. Amaiba: le, ilia da ema Ya: igobe dio asuli. Ela lalelegei eso amoga Aisage da ode 60 lai dagoi.
Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
27 Ela asigilaloba, Iso da benea ahoasu hou bagade dawa: i. E da gadili odagiabaga lalumu hanai galu. Be Ya: igobe e da asaboi dunu. E da diasuga esalumusa: hanai galu.
Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
28 Aisage da Iso ea dadi gala: i liligi manusa: hanaiba: le, Isoma bagade hahawane galu. Be Lebega ea dogolegei mano da Ya: igobe.
Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
29 Eso afaega Ya: igobe da da: iyene amola hano gilisili gobele, ha: i manu ida: iwane hamoi. Iso logo sedagaga benea ahoabeba: le, bagadewane ha: iba: le, sidimu agoaiwane, diasuga doaga: i.
Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
30 “Hedolo! Na bogosa: besa: le, amo yoi ha: i manu nama ima,” Iso da Ya: igobema amane sia: i. (Amaiba: le, ilia da ema Idome [Yoi] dio asuli.)
Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
31 Ya: igobe da ema amane sia: i, “Defea! Be hidadea dia magobo mano lamu nana liligi ilegei, amo nama lama: ne sia: ma.”
Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
32 Iso e bu adole i, “Defea! Amo lama! Na bogosea, amo liligi da hamedei liligi agoane ba: mu. Be ha: i manu ima!”
Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
33 Ya: igobe da bu adole i, “Hidadea di da magobo mano nana liligi ilegei amo nama imunu gasa bagade ilegele sia: ma!” Amaiba: le, Iso da amo magobo mano lamu nana liligi ilegei huluane Ya: igobema ima: ne, gasa bagade ilegele sia: i.
Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
34 Amalalu, Ya: igobe da agi amola da: iyene hano amo Isoma i. E da amo nanu, wa: legadole yolesili asi. Iso da ea magobo mano lamu nana hahawane liligi ilegei amo hamedei liligi agoane dawa: beba: le, udigili fisi.
Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.

< Mui 25 >