< Mui 23 >

1 Sela da ode 127 esalu.
Sara sì pé ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádóje.
2 Amalalu, e da Hibalone moilai bai bagade, Ga: ina: ne soge ganodini, amoga bogoi. A: ibalaha: me da amoga ea udama asigiba: le, dimusa: asi.
Ó sì kú ní Kiriati-Arba (ìyẹn ní Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani, Abrahamu lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti láti sọkún nítorí Sara.
3 Amalalu, A:ibalaha: me da ea uda bogoi da: i hodo amoga ouesalu, wa: legadole Hidaide dunuma asili, amane sia: i,
Abrahamu sì dìde lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkú aya rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ará Hiti wí pé,
4 “Na da dilia fi amo ganodini ga fi dunu esala. Na uda bogoi uli dogoma: ne, soge fonobahadi nama bidi lama.”
“Èmi jẹ́ àtìpó àti àlejò láàrín yín, ẹ ta ilẹ̀ ìsìnkú fún mi kí èmi le sin òkú tí ó kú fún mi sí.”
5 Hidaide dunu da A: ibalaha: mema bu adole i,
Àwọn ọmọ Hiti dá Abrahamu lóhùn pé,
6 “Ada! Ninia sia: nabima! Di da ninima gasa bagade ouligisu dunu agoane. Ninia bogoi uli dogoi sogebiga, uli dogoi noga: idafa lama. Ninia huluane da baligili noga: idafa uli dogoi dima imunu hame higamu.”
“Olúwa mi, gbọ́ tiwa, ó jẹ́ alágbára ọmọ-aládé láàrín wa, sin òkú rẹ sí ibojì tí ó dára jù nínú àwọn ibojì wa, kò sí ẹni tí yóò fi ibojì rẹ dù ọ́ láti sin òkú rẹ sí.”
7 Amalalu, A:ibalaha: me da wa: legadole, amo soge esalebe dunu amo Hidaide, ilima begudui.
Nígbà náà ni Abrahamu dìde, ó sì tẹríba níwájú àwọn ará ilẹ̀ náà, àwọn ará Hiti.
8 E da ilima amane sia: i, “Dilia da na bogoi uli dogomusa: hahawane ba: i galea, defea, dilia Ifalone (Souha ea mano) amoma na fidima: ne adole ba: ma.
Ó sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá ṣe pé, lóòótọ́ ni ẹ fẹ́ kí n sin òkú mi kúrò nílẹ̀, ẹ gbọ́ tèmi, ẹ bá mi bẹ Efroni ọmọ Sohari,
9 Ea soge la: idi ganodini da Ma: gafila gele gelabo. Amo e da gaguiba: le, e da amo ea muni defei na da dilia fi amo ganodini na bogoi uli dogomusa: bidi lama: ne, dilia ema adole ba: ma.”
kí ó ta ihò àpáta Makpela tí ó jẹ́ tirẹ̀ fún mi, èyí tí ó wà ni orí oko rẹ̀, kí ó tà á fún mi ni iye owó tí à ń ta irú rẹ̀ fún ilẹ̀ ìsìnkú láàrín yín.”
10 Ifalone e da amo Hidaide fi dunu ea fi ganodini esalebe ba: i. Ilia huluane da moilai logo holeiga gilisi. E da Hidaide dunu huluane nabima: ne, A:ibalaha: mema amane adole i,
Efroni ará Hiti sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú, ó sì dá Abrahamu lóhùn lójú gbogbo àwọn ará ìlú tí ó wà níbẹ̀, lẹ́nu ibodè ìlú,
11 “Hame mabu ada! Na sia: nabima! Amo soge amola gele gelabo amo ganodini diala, na da udigili dima imunu. Na dunu huluane ba: ma: ne, na da dima iaha. Dia bogoi amoga uli dogoma!”
pé, “Rárá, olúwa mi. Gbọ́ tèmi; mo fún ọ ní ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà níbẹ̀. Mo fún ọ níwájú gbogbo àwọn ènìyàn mi. Sin òkú rẹ síbẹ̀.”
12 A: ibalaha: me da amo soge fi dunu ilima bu begudui,
Abrahamu sì tún tẹríba níwájú àwọn ènìyàn ìlú náà,
13 Ilia huluane nabima: ne, e da Ifalonema amane sia: i, “Na da dilima na sia: nabima: ne edegesa. Na da amo soge huluane ea ilegei amo defele bidi lamu. Amo muni lama. Na da na bogoi amoga uli dogomu galebe.”
ó sì wí fún Efroni lójú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, gbọ́ tèmi, èmi yóò san owó ilẹ̀ náà, gbà á lọ́wọ́ mi kí n lè sin òkú mi síbẹ̀.”
14 Ifalone da A: ibalaha: mema bu adole i,
Efroni sì dá Abrahamu lóhùn pé,
15 “Ada! Nabima! Amo soge bidi lamu defei da silifa fage 400 fawane. Amo muni da anima hamedei liligi. Dia bogoi uli dogoma!”
“Gbọ́ tèmi Olúwa mi, irinwó òsùwọ̀n owó fàdákà ni ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n kín ni ìyẹn já mọ láàrín àwa méjèèjì? Sá à sin òkú rẹ.”
16 A: ibalaha: me da Ifalone ea sia: i hahawane ba: i. E da Hidaide dunu huluane ba: ma: ne, muni ea sia: i defele Ifalonema i. Defei da silifa fage 400 amo ea dioi ilegei defele da bidiga lasu dunu ilia hou defele i.
Abrahamu sì gbọ́ tí Efroni wí, Abrahamu sì wọn iye fàdákà náà fún Efroni, tí ó sọ ní etí àwọn ọmọ Hiti, irinwó òsùwọ̀n ṣékélì fàdákà, tí ó kọjá lọ́dọ̀ àwọn oníṣòwò.
17 Amaiba: le, Ifalone ea sogebi amo da Ma: gafila soge ganodini Ma: melei soge gadenene, - sogebi, gele gelabo amo ganodini dialu amola ifa huluane amo sogebi ganodini, huluane A: ibalaha: me da lai dagoi.
Báyìí ni ilẹ̀ Efroni tí ó wà ni Makpela nítòsí Mamre, ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ àti gbogbo igi tí ó wà nínú ilẹ̀ náà ni a ṣe ètò rẹ̀ dájú,
18 Hidaide dunu huluane logo holeiga gilisi da amo hou ba: beba: le, amo soge da wali A: ibalaha: me ea soge ilegei.
bí ohun ìní fún Abrahamu níwájú gbogbo ará Hiti tí ó wá sí ẹnu ibodè ìlú náà.
19 Amalalu, A:ibalaha: me da ea uda Sela amo gele gelabo Ma: gafila sogebi ganodini (Ga: ina: ne soge ganodini) uli dogone sali.
Lẹ́yìn náà ni Abrahamu sin aya rẹ̀ Sara sínú ihò àpáta ní ilẹ̀ Makpela nítòsí Mamre (tí í ṣe Hebroni) ní ilẹ̀ Kenaani.
20 Amola Ma: gafila sogebi amola gele gelabo amo ganodini gala musa: da Hidaide dunu da gagui, amo A: ibalaha: me ea fi bogoi uli dogomusa: bidi lai dagoi.
Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni àwọn ará Hiti fi fún Abrahamu gẹ́gẹ́ bí ohun ìní títí láé, bí ilẹ̀ ìsìnkú fún àwọn òkú tí ó bá kú fun un.

< Mui 23 >