< Esela 9 >

1 Amalalu, Isala: ili fi ouligisu dunu mogili da nama sia: na misini, gobele salasu dunu amola Lifai dunu da dunu fi ilima na: iyado soge amo A: mone, Moua: be, Idibidi, Ga: ina: ne dunu, Hidaide dunu, Belisaide dunu, Yebiusaide dunu amola A: moulaide dunu ilima hame afafasu ilia sia: i. Ilia da amo dunu ilia wadela: idafa hou hamosu amoma fa: no bobogei dagoi.
Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
2 Yu dunu da ga fi uda labeba: le, Gode Ea hadigi fi dunu da wadela: lesi dagoi ba: i. Be Yu ouligisu dunu amola ouligisu hina dunu, ilia amola da ga fi uda laiba: le, ilia da amo wadela: i hou amo ganodini baligili wadela: i hamosu dunu agoai ba: i.
Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
3 Na da amo sia: nababeba: le, se bagade nabi. Na abula gadelale, na dialuma hinabo amola mayabo mogili golole fasili, da: i dioi bagadewane esalu.
Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
4 Na da amanewane da: i dione esaloba, daeya galu Godema gobele salasu da doaga: i. Amalalu, dunu da na esaloba, na guba: le sisiga: le aligi. Ilia da Isala: ili Godema bagade beda: i. Bai Gode da mugululi asi buhagi dunu ilia wadela: i hou ba: i dagoi, amola Ea sia: ilia da nabi.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
5 Daeya gobele salasu hou da doaga: loba, na da ni musa: udigili esalua amoga da: i dione esalu, amoga wa: legadole, amola na abula gadelai ga: i amola na da muguni bugili, na Hina Godema lobo ligia gadole, Ema sia: ne gadoi.
Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6 Na da amane sia: i, “Na Gode! Na da bagadewane gogosia: iba: le, Dia hadigi amoma na dialuma molole gadomu hamedei agoane ba: sa. Ninia wadela: i hou da bagadedafa, fedege agoane bi hamone ninia dialuma baligili muagado heda: sa.
Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
7 Musa: aowalali ilia fifi mana, wali wadela: i hou bu baligili bagadedafa ninia hamonana. Ninia wadela: i houba: le, ninia hina bagade dunu amola ninia gobele salasu dunu da ga fi hina bagade ilia baiga dafai dagoi. Ga fi dunu da ninia fi dunu medole legele, ilia liligi wamolai amola mogili udigili hawa: hamomusa: mugululi oule asi. Ninia wadela: i hou hamoiba: le, bagadewane gogosiasu, amola waha da amomane diala. Ninia Hina Gode!
Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
8 Waha, eso fonobahadi amoga, Di da ninima asigiba: le, ninia se iasu diasuga fisili masa: ne gadili asunasi, wali ninia da Dia hadigidafa soge amoga gaga: iwane esala. Di da wali ninima hadigi ganodini udigili lalusu amola gaheabolo esalusu ninima i dagoi.
“Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
9 Nini da udigili se iasu diasua esalebe hawa: hamosu dunu agoai galu, be di da nini se iasu diasua esalebe hawa: hamoma: ne hame yolesi. Di da Besia hina bagade dunu ilia asigi dawa: su olelebeba: le, ilia da ninima asigisu. Ilia da nini hame fane legei. Be ninia da Dia Debolo musa: wadela: lesi dagoi, amo bu gagumusa: amola ninia Yuda soge amola Yelusaleme amo ganodini gaga: iwane esaloma: ne, ilia da logo doasi dagoi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
10 Be wali, Na Gode! Amo hou da doaga: beba: le, ninia da adi sia: ma: bela: ? Ninia da Dia sema amola hamoma: ne sia: i bu hame nabasu.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
11 Di da ilima olelebeba: le, Dia hawa: hamosu dunu amo balofede dunu, da amo sema amola hamoma: ne sia: i ninima olelei. Ilia da ninima adoi amane, soge amo ninia da gesowale fimu da ledo bagade soge. Ga: ina: ne dunu fi amo ganodini da wadela: i hou bagade hamobeba: le, soge huluanedafa da ledo bagade ba: i.
èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
12 Ilia da ninima amane sia: i, ‘Dilia da amo soge ganodini hahawane esalumusa: dawa: sea, amola amo ganodini diligaga fi da eso huluane hahawane esaloma: ne ilima imunusa: dawa: sea, dilia amo soge fi ilia uda maedafa lama, amola ilia muni labe hou amola hou huluanedafa mae fidima,’ balofede dunu da amane sia: i.
Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
13 Ninia da wadela: i hou bagade hamobeba: le, se dabe iasu bagade lai. Be ninia Gode, ninia dawa: Di da nini hame fane legei, amola ninia wadela: i hou se dabe iasu defele ninima hame i.
“Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
14 Amaiba: le, ninia da abuliba: le da Dia hamoma: ne sia: i bu mae nabawane, amo wadela: i fi ilia uda lama: bela: ? Agoane hamosea, Dia ougi da heda: sea, nini huluane wadela: lesi dagoi ba: mu. Dunu afadafa esalebe hamedafa ba: mu.
Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
15 Isala: ili Hina Gode! Di da moloidafa fofada: su dunu! Di da nini bogoma: ne hame fane legei! Ninia wadela: i hou Dima fofada: ne iaha! Ninia da Dia hadigi amoga misunu da ninima hamedei liligi agoai,” Esela da amane sia: ne gadoi.
Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.

< Esela 9 >