< Isigiele 36 >

1 Hina Gode da amane sia: i, “Dunu egefe! Isala: ili goumi amoma sia: ma.
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
2 Ilia da Na, Ouligisudafa Hina Gode, Na sia: nabima: ne sia: ma! ‘Isala: ili ha lai da Isala: ili dafai dawa: beba: le, hidale amane sia: i, ‘Amo hemonega hamoi goumi wali da ninia: ,’ amane nodone sia: i.
Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
3 Defea! Ilima fofada: ma! Na, Ouligisudafa Hina Gode, Na sia: ilima adosima. Isala: ili fi ilia na: iyado fi da Isala: ili goumi amo gegenana samogele laloba, amola soge wadela: lesilaloba, ilia huluane Isala: ili amoma gadesu.
Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
4 Amaiba: le, Na, Ouligisudafa Hina Gode da dili goumi, agolo, hano, fago amola sogebi amo da wadela: lesili yolesi amola moilai hagia: i amo fifi asi gala Isala: ili sisiga: su da wadela: lesi amola dilima lasogole oufesega: su, dilia huluane Na sia: nabima.
nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
5 Na, Ouligisudafa Hina Gode, Na da gia: iwane ougili, Isala: ili sisiga: sa fi, ilima sia: i. Na da Idome ilima baligili ougili sia: i. Bai ilia da hahawane amola higale mae asigiliwane, Na soge gegenana lai, amola amo ea gisi nasu soge huluane fima: ne lai.
èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
6 Amaiba: le, Isala: ili soge amoma ba: la: lusu amo sia: ma. Goumi amola fago amola hano amoma Na, Ouligisudafa Hina Gode, da ougili mudale agoane sia: daha, amo ilima adoma. Bai fifi asi gala da Isala: ili fi ilima gadele sia: ne, ili banenesi.
Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
7 Na, Ouligisudafa Hina Gode, da dafawanedafa ilegele sia: sa. Isala: ili fi sisiga: le fifi lai huluane da fonobone banenesi dagoi ba: mu.
Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
8 Be dilia, Na fi Isala: ili! Isala: ili goumia, dili fidima: ne, ifa da bu lubi lale, fage legemu. Dilia da gadenenewane dilia sogedafa amoga buhagimu galebe.
“‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
9 Na da dilimagai, amola dilia soge bu dogone, ha: i manu bugima: ne, Na da hamomu.
Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
10 Na da dilia dunu fi bagama: mu. Dilia da moilai mugului amo bu gaguli, amo ganodini esalumu.
èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
11 Na dunu amola ohe fi ilia idi bu gado heda: ma: mu. Dilia idi da musa: idi baligimu, amola dilia mano bagohame lalelegemu. Dilia da dilia musa: esalu defele bu esaloma: ne, amola dilia gagui hou da musa: gagui baligima: ne, Na da hamomu. Amasea, dilia da Na da Hina Gode dawa: mu.
Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
12 Na da dilia, Na fi Isala: ili, amo dilia sogedafa bu esaloma: ne, bu oule misunu. Amo da dilia sogedafa ba: mu, amola amo ganodini dilia mano da bu hame ha: gia: mu.
Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
13 Na, Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: sa, ‘Dafawane! Dunu da fedege agoane, Isala: ili soge da dunu fane nasu soge, amane sia: daha. Amola amo soge da esalebe fi ea mano amo gegenana samogene laha, amane sia: daha.
“‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
14 Be waha winini amaiwane hame ba: mu. Isala: ili soge da bu dunu fane nasu soge hame ba: mu amola dilia mano enoga hame gegenana sasamogemu. Bai Na, Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: i dagoi.
nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Waha winini, Isala: ili da eno fifi asi gala ilima lasogole oufesega: su amola ba: sola: su amo bu hame nabimu. Amola, soge da Isala: ili mano bu hame gegenana samogene lamu. Na, Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: i dagoi.”
Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
16 Hina Gode da nama amane sia: i,
Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
17 “Dunu egefe! Isala: ili dunu ilia da Isala: ili soge ganodini esaloba, ilia da wadela: le hamoiba: le, soge gugunufi agoane hamosu. Musa: sema defele, Na da ilia hou, uda da oubiga sioi fisa defele, ledo hamoi ba: su.
“Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
18 Ilia da ilia soge ganodini fane legesu hou hamobeba: le, amola ogogosu ‘gode’ ilima nodone sia: ne gadole, soge gugunufiba: le, ilia da Na ougi hou nabima: ne, Na da ilima gasa bagade ougili hamoi.
Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
19 Na da ilia hamobeba: le, ilima fofada: nanu, se bidi i. Na da ili ga fi amo ganodini esaloma: ne, afagogolesi.
Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
20 Ilia habodili ahoanoba, ilia da Na dio wadela: lesi. Bai dunu fi eno da agoane sia: dasu, ‘Amo da Hina Gode Ea fi dunu. Be ilia da wadela: i hou hamobeba: le, Gode da Hina: sogega ili gadili sefasi.’
Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
21 Amaiba: le, Na da Na Hadigi Dio bu gaguia gadoma: ne dawa: i. Bai Isala: ili dunu da habodili ahoanoba, Na Dio da gudu sa: i agoane ba: i.
Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
22 Wali, di Isala: ili dunuma, amo Na, Ouligisudafa Hina Gode, Na sia: ilima alofele adosima, ‘Na wali hamomu da dili Isala: ili dunu gaguia gadoma: ne hame hamomu. Be Na Hadigi Dio (amo dilia da habodili ahoanoba, gudu sa: ima: ne hamosu) amo gaguia gadoma: ne Na da hamomu.
“Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
23 Na da fifi asi gala ilima Na Dio ea Hadigi (amo Dio dilia da fifi asi gala amo ganodini gudu sa: ima: ne hamosu) amo ilia dawa: digima: ne olelesea, ilia da Na, Ouligisudafa Hina Gode, da sia: i dagoi, amo dawa: mu. Na da fifi asi gala amo Na da Hadigi ilima olelemusa: , Na da dili, Isala: ili fi dunu, dilima hamomu.
Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
24 Na da dili fifi asi gala huluane amola soge huluane amoga fadegale, Isala: ili sogega bu oule misunu.
“‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
25 Na da dilima hano fogaga: gala: mu. Amo da dilia gugunufi hamosu (loboga hamoi ogogosu ‘gode’ ilima nodone sia: ne gadosu amola eno wadela: i hou huluane) amo dodofele, dilia da foloai ba: mu.
Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
26 Na da dogo gaheabolo amola asigi dawa: su gaheabolo dilima imunu. Na da dia ga: nasi igi hamoi dogo, amo fadegale fasili, nabasu dogo dilima imunu.
Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
27 Na da Na A: silibu Hadigidafa Gala dilia dogo ganodini sanasimu. Amola dilia da Na malei amola Na sia: nabawane hamoma: ne, Na da dilia hou afadenemu.
Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
28 Amasea, dilia da soge amo Na da dilia aowalalia ilima i, amo ganodini esalumu. Dilia da Na dunu fi esalumu, amola Na da dilia Gode esalumu.
Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
29 Hou huluane da dili gugunufisa, amoga Na da dili gaga: mu. Na da gagoma bagadewane heda: ma: mu. Amasea, dilia ha: bu hame ba: mu.
Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
30 Na da dilia fage legesu ifa amo fage baligili legema: mu, amola dilia ifabi amo ha: i manu bagade heda: ma: mu. Amasea, dilia da ha: eno bu hame ba: muba: le, fifi asi gala eno ba: ma: ne, dilia da bu hame gogosiamu.
Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
31 Dilia da dilia musa: wadela: i hou hamoi bu dawa: beba: le, dili gobele da bagadewane gogosiamu.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
32 Isala: ili fi! Dilia noga: le dawa: mu, Na da hanai gala! Na da dili gaguia gadoma: ne amo hame hamosa. Dilia da dilia wadela: i hou hamoi amo dawa: beba: le gogosiamu, amo Na da hanai. Na, Ouligisudafa Hina Gode, da sia: i dagoi.”
Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
33 Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: sa, “Na da dilia wadela: i amola gugunufisu hou huluane dodofesea, Na da dilia moilai ganodini esaluma: mu amola mugului diasu bu gaguma: mu.
“‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
34 Dunu huluane da dilia ifabidili baligili ahoanoba da ilia gagalabo hamoi dagoi ba: i. Be amo Na da dilia bu ouligima: mu.
Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
35 Dunu huluane da agoane sia: mu, ‘Amo soge da musa: iwila agoane galu. Be wali afadenene, Idini Soge defele ba: sa. Moilai bai bagade huluane da mugului dagole, liligi huluane gegenana lai agoane ba: i. Be wali amogawi dunu fi da fifi lala amola moilai bai bagade da gagili sali dagoi.
Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
36 Amasea, na: iyado fifi asi gala amo da mae bogole esala, ilia da Na, Hina Gode, da mugului moilai amo bu gagumusa: dawa: , amola gagalobo misi ifabi amo bu sagamusa: dawa: , amo ilia da dawa: mu. Na, Hina Gode da amo hamomusa: ilegei, amola Na da dafawane hamomu.
Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
37 Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: sa, “Na da Isala: ili dunu Nama fidima: ne adole ba: ma: ne, logo bu doasimu. Na da sibi wa: i ilia idi da heda: sa, amo defele Na da Isala: ili fi ilia idi heda: ma: mu.
“Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
38 Musa: Yelusaleme da ilia lolo nabe amoga gobele salasu hamoma: ne, sibi amoga nabaiwane ba: i. Amo defele, Isala: ili moilai bai bagade wali mugului diala, da fa: no dunu fi amoga nabaiwane ba: mu. Amasea, ilia da Na da Hina Gode dawa: mu.”
kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”

< Isigiele 36 >