< Isigiele 29 >

1 Eso fago amola oubi nabu amola ninia mugululi misi ode nabu, amoga Hina Gode da nama amane sia: i,
Ní ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹwàá, ọdún kẹwàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Dunu egefe! Idibidi hina bagade ema se ima: ne, mimogoa fofada: ma! E amola Idibidi fi huluane da se bidi iasu lama: ne sia: ma.
“Ọmọ ènìyàn, kọjú sí Farao ọba Ejibiti kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí i àti sí gbogbo Ejibiti.
3 Ema, Ouligisudafa Hina Gode da Idibidi hina bagade amane sia: sa, adosima, ‘Di, hanome bagadedafa, hanoa dialebe! Na da dia ha lai! Di da Naile Hano da dia: , amola dia amo hamoi sia: sa.
Sọ̀rọ̀, kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, Farao ọba Ejibiti ìwọ ẹ̀mí búburú ńlá inú òkun tí ó dùbúlẹ̀ sí àárín àwọn odò ṣíṣàn rẹ. Èyí tí ó sọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili; èmi ni ó sì ṣe é fún ara mi.”
4 Be Na da dia magado ma: goga hiougimu. Amola menabo dia hano ganodini fi, dima madelagima: mu. Amasea, Na da di Naile Hano ganodi dialu amola menabo huluane dima madelagi, amo bia hiougili gadomu.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìwọ̀ mú ẹnu rẹ èmi yóò sì mú ẹja inú odò rẹ gbogbo lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ. Èmi yóò fà ọ́ síta kúrò láàrín àwọn odò rẹ, àti gbogbo ẹja odò rẹ yóò lẹ̀ mọ́ ìpẹ́ ara rẹ.
5 Na da di amola menabo huluane, hafoga: i sogega galagamu. Dia da: i hodo osoboga galagale, hame uli dogoi ba: mu. Na da amo sio amola ohe fi iligili moma: ne imunu.
Èmi yóò sọ ọ́ nù sí aginjù ìwọ àti gbogbo ẹja inú odò rẹ: ìwọ yóò ṣubú sí gbangba oko a kì yóò sì ṣà ọ́ jọ tàbí gbé ọ sókè. Èmi ti fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹranko igbó àti fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run láti jẹ.
6 Amasea, Idibidi dunu huluane ilia da Na da Hina Gode dawa: mu. Isala: ili fi dunu da dilia Idibidi dunu amo ili fuligala: mu dawa: i galu. Be di da gasa hame ifa daba: agoai ba: i.
Nígbà náà gbogbo àwọn olùgbé ni Ejibiti yóò mọ pé, Èmi ni Olúwa. “‘Ìwọ ti jẹ́ ọ̀pá ìyè fún ilé Israẹli.
7 Ilia da dima baligisia ganoba, di da fili sa: ili, ilia ogoleba sone, ilia baligi fili gala: i.
Nígbà tí wọn fi ọwọ́ agbára wọn dì ọ́ mú. Ìwọ fọ́, ìwọ sì ya gbogbo èjìká wọn; nígbà tí wọn fi ara tì ọ́, ìwọ sẹ́, ìwọ sì mú gbogbo ẹ̀gbẹ́ wọn gbọ̀n.
8 Wali, Na, Ouligisudafa Hina Gode, da dima sia: sa. Na da dunu gegesu gobihei bagade gaguiwane dima doagala: musa: , dima asunasimu. Ilia da dia dunu amola ohe huluane medole legemu.
“‘Nítorí náà, èyí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi, Èmi yóò mú idà kan wá sórí rẹ tí yóò sì gé ènìyàn àti ẹran kúrò nínú rẹ.
9 Idibidi soge da dunu hulu hagia: le, wadela: lesi dagoi ba: mu. Amasea, di da Na da Hina Gode dawa: mu.
Ilẹ̀ Ejibiti yóò di aginjù àti ahoro, nígbà náà ní wọn yóò sì mọ̀ wí pé èmi ní Olúwa. “‘Nítorí tí ìwọ wí pé, “Tèmi ni odò Naili, Èmi ni mo ṣe é,”
10 Di da Naile Hano da dia: , amola di da amo hamoi sia: beba: le, Na da di amola dia Naile Hano amoma ha lai gala. Na da Idibidi soge huluane, Migidole moilai bai bagade ga (north) gala amoganini asili Asawane moilai bai bagade ga (south) gala, amonini asili Sudane fi alalo defei doaga: sa, amo dogoa huluane dunu hulu hagia: le, wadela: lesimu.
nítorí náà, mo lòdì sí ọ àti sí àwọn odò rẹ, èmi yóò sì mú kí ilẹ̀ Ejibiti di píparun àti ahoro, pátápátá, láti Migdoli lọ dé Siene, dé ààlà ilẹ̀ Kuṣi.
11 Dunu fi amola ohe fi ilia amodili mae asili galea, ode 40 da gidigili baligimu.
Kò sí ẹsẹ̀ ènìyàn tàbí tí ẹranko tí yóò gba ibẹ̀ kọjá; ẹni kankan kò ní gbé ibẹ̀ fún ogójì ọdún.
12 Na da Idibidi soge wadela: lesisia, amo soge ea wadela: su da soge huluane osobo bagadega gala, amo ilia wadela: su baligi dagoi ba: mu. Ode 40 amoga Idibidi soge moilai bai bagade huluane da wadela: lesi dagoi, eno moilai huluane ilia wadela: su bagade baligiwane dialumu. Na hamobeba: le, Idibidi dunu da gegesu amoga hobeale lasu dunu ba: mu. Ilia da fifi asi gala eno huluane amoga hobeale, amo fi ganodini esalumu.”
Èmi yóò sọ ilẹ̀ Ejibiti di ọ̀kan ní àárín àwọn ìlú tí ó di ahoro, fún ogójì ọdún, Èmi yóò sì fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sáàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sáàárín gbogbo ilẹ̀.
13 Ouligisudafa Hina Gode da amane sia: sa, “Ode 40 amo gidigili, Na da Idibidi fi dunu soge fifi asi enoga afagogolesi amo bu sinidigili oule misunu.
“‘Ṣùgbọ́n báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Ní òpin ogójì ọdún, èmi yóò ṣa àwọn ará Ejibiti jọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn níbi tí a fọ́n wọn ká sí.
14 Amola Na da ili ga (south), musa: ili fifi lalusu amogawi fifi lama: mu. Amo ganodini ilia da gasa hamedene fifi lalumu.
Èmi yóò sì tún mú ìgbèkùn Ejibiti padà bọ̀, èmi yóò sì dá wọn padà sí ilẹ̀ Paturosi, ilẹ̀ àwọn baba ńlá wọn. Wọn yóò wà níbẹ̀ bí ìjọba tí a rẹ̀ sílẹ̀.
15 Ilia da gasa hamedeiba: le, eno fifi asi gala da ilia gasa baligimu. Amola ilia da eno fifi asi gala ouligimu hamedei ba: mu. Na da ili gasa hamedene hamobeba: le, ilia da eno fifi asi gala sesemu da hamedei ba: mu.
Ibẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba tí ó rẹlẹ̀ jùlọ nínú àwọn ìjọba, kì yóò sì gbé ara rẹ̀ ga mọ́ sórí àwọn orílẹ̀-èdè: nítorí èmi ni ó dín wọn kù, tiwọn kì yóò fi ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù mọ́.
16 Isala: ili da ili fidima: ne, Idibidi dunu ilima bu hame adole ba: mu. Isala: ili da Idibidi amoga doaga: i hou ba: beba: le, ilia da ilima fidimusa: adole ba: beba: le da giadofai noga: le dawa: mu. Amasea, Isala: ili fi ilia da Na da Ouligisu Hina Gode dawa: mu.”
Ejibiti kí yóò sì jẹ orísun ìgbẹ́kẹ̀lé fún ilé Israẹli mọ́ ṣùgbọ́n, yóò jẹ́ ìrántí fún àìṣedéédéé wọn, nígbà tí yóò bá wò wọ́n fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’”
17 Eso age, amola oubi age, amola ode 27 ninia mugululi misi amoga, Hina Gode da nama amane sia: i,
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní, ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 “Dunu egefe! Ba: bilone hina bagade Nebiuga: denese da Daia amoma doagala: i. E da ea dadi gagui dunu ilima dioi gasa bagade liligi gisima: ne, ilima i. Amalalu ilia dialuma da gianai agoane ba: i, amola ilia gidagi da gadofo houga: lesi ba: i. Be Ba: bilone hina bagade amola dadi gagui dunu, ilia da amo hawa: hamobega dabe liligi afae hame lai.
“Ọmọ ènìyàn, Nebukadnessari ọba Babeli mú kí ogun rẹ sin ìrú ńlá fún Tire. Gbogbo orí pá, àti gbogbo èjìká bó, síbẹ̀, òun àti àwọn ogun rẹ̀, kò rí owó ọ̀yà gbà láti Tire fún wa, fún ìrú ti a ti sìn.
19 Amaiba: le, Na, Ouligisudafa Hina Gode, da amane sia: sa, ‘Na da Idibidi soge amo, hina bagade Nebiuga: denese ema iagamu. E da amoma doagala: le, Idibidi muni huluane gegenana lale, amo muni ea dadi gagui dunu ilima ilia bidi imunu.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, Èmi yóò fi Ejibiti fún Nebukadnessari ọba Babeli, òun yóò sì kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ. Òun yóò bo ilé, yóò sì ṣe ìkógun ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ tí a san fún ológun rẹ̀.
20 E da Na hawa: hamobeba: le, Na da Idibidi soge ea hawa: hamosu bidi agoane, ema imunu. Na, Ouligisu Hina Gode da sia: i dagoi.
Èmi ti fi Ejibiti fún un gẹ́gẹ́ bí èrè wàhálà rẹ̀ nítorí òun àti àwọn ológun rẹ ṣe é fún mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 Amo hou da doaga: sea, Na da Isala: ili dunu ilima gasa bu imunu. Amola, di Isigiele, di da dunu huluane nabima: ne sia: musa: , Isala: ili dunu da Na da Hina Gode dawa: ma: ne, Na da dia logo doasimu.”
“Ní ọjọ́ náà, èmi yóò mú kí ìwo Israẹli ru jáde, èmi yóò sì fún ọ ní ẹnu ọ̀rọ̀ ní àárín wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Isigiele 29 >