< 1 Sa:miuele 23 >

1 Filisidini dunu da Giaila moilai amo doagala: lalu, gagoma gaheabolo fai amo wamolalu. Da: ibidi da amo sia: nabi.
Wọ́n sì wí fún Dafidi pé, “Sá wò ó, àwọn ará Filistini ń bá ará Keila jagun, wọ́n sì ja àwọn ilẹ̀ ìpakà lólè.”
2 Amaiba: le, e da Hina Godema amane adole ba: i, “Na da asili Filisidini dunu doagala: ma: bela: ?” Hina Gode da bu adole i, “Ma! Ili doagala: ma amola Giaila gaga: ma!”
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Ṣé kí èmi ó lọ kọlu àwọn ará Filistini wọ̀nyí bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Lọ kí o sì kọlu àwọn ará Filistini kí o sì gba Keila sílẹ̀.”
3 Be Da: ibidi ea dunu da ema amane sia: i, “Guiwane Yuda sogega da nini beda: ma: ne ha lai liligi defele gala. Be ninia da Giaila amoga Filisidini dadi gagui doagala: musa: ahoasea, baligili se nabimu.”
Àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, àwa ń bẹ̀rù níhìn-ín yìí ní Juda; ǹjẹ́ yóò ti rí nígbà ti àwa bá dé Keila láti fi ojú ko ogun àwọn ara Filistini?”
4 Amaiba: le, Da: ibidi da bu Hina Godema adole ba: i. Amola Hina Gode da ema amane sia: i, “Masa! Giaila moilaiga doagala: musa: masa! Bai Na da di Filisidini dunu hasalasimusa: hamomu.”
Dafidi sì tún béèrè lọ́dọ̀ Olúwa. Olúwa sì dá a lóhùn, ó sì wí pé, “Dìde, kí o sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, nítorí pé èmi ó fi àwọn ará Filistini náà lé ọ lọ́wọ́.”
5 Amaiba: le, Da: ibidi amola ea dunu da Giaila moilaiga asili, Filisidini dunuma doagala: i. Ilia da Filisidini dunu bagohame fane lelegele, ilia laigebo huluane sasamogei. Amowane, Da: ibidi da Giaila moilai gaga: i.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Keila, wọ́n sì bá àwọn ará Filistini jà, wọ́n sì kó ohun ọ̀sìn wọn, wọ́n sì fi ìparun ńlá pa wọ́n. Dafidi sì gba àwọn ará Keila sílẹ̀.
6 Abaia: da (Ahimelege egefe) da hobeale, Da: ibidima Giaila moilaiga madelaloba, e da ‘Ifode’ gaguli asi.
Ó sì ṣe, nígbà tí Abiatari ọmọ Ahimeleki fi sá tọ Dafidi lọ ní Keila, ó sọ̀kalẹ̀ òun pẹ̀lú efodu kan lọ́wọ́ rẹ̀.
7 Solo da Da: ibidi da Giaila amoga asi nababeba: le, e amane sia: i, “Gode da Da: ibidi amo na gasaga fama: ne, nama i dagoi. Da: ibidi da gagili sali moilai amo ganodini asiba: le, hisu hi sanenesi dagoi.”
A sì sọ fún Saulu pé Dafidi wá sí Keila. Saulu sì wí pé, “Ọlọ́run ti fi í lé mi lọ́wọ́; nítorí tí ó ti sé ara rẹ̀ mọ́ ní ti wíwá tí ó wá sí ìlú tí ó ní ìlẹ̀kùn àti kẹrẹ.”
8 Amaiba: le, Solo da ea dadi gagui dunu gegemusa: misa: ne wele sia: i. Ilia da Giaila amoma doagala: le, Da: ibidi amola ea dunu amoga gagili salawane esalu, ilima gegemusa: dawa: i galu.
Saulu sì pe gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ sí ogun, láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, láti ká Dafidi mọ́ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀.
9 Da: ibidi da Solo ema doagala: musa: ilegelalu, amo nababeba: le, e da gobele salasu dunu Abaia: da ema amane sia: i, “Ifode amo goeguda: gaguli misa!”
Dafidi sì mọ̀ pé Saulu ti gbèrò búburú sí òun; ó sì wí fún Abiatari àlùfáà náà pé, “Mú efodu náà wá níhìn-ín yìí!”
10 Amalalu, Da: ibidi amane sia: i, “Isala: ili ilia Hina Gode! Na da nabi amo na hamobega, Solo da Giaila amoga misini, moilai wadela: lesimusa: ilegelala.
Dafidi sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, lóòótọ́ ni ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ pé Saulu ń wá ọ̀nà láti wá sí Keila, láti wá fọ́ ìlú náà nítorí mi.
11 Amo hamosea, Giaila fi dunu da na Soloma ima: bela: ? Na nabi defele, Solo da misa: bela: ? Isala: ili Hina Gode! Na da Dima edegesa! Nama adole ima!” Hina Gode da amane adole i, “Solo da misunu!”
Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi mí lé e lọ́wọ́ bí? Saulu yóò ha sọ̀kalẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ bí?” Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èmi bẹ̀ ọ́, wí fún ìránṣẹ́ rẹ. Olúwa sì wí pé, “Yóò sọ̀kalẹ̀ wá.”
12 Da: ibidi da bu adole ba: i, “Giaila fi dunu da Solo samogema: ne, na ema ima: bela: ?” Hina Gode da adole i, “Ilia da di ema imunu!”
Dafidi sì wí pé, “Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi èmi àti àwọn ọmọkùnrin mi lé Saulu lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí pé, “Wọn ó fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́.”
13 Amaiba: le, Da: ibidi amola ea dunu (huluane da 600 agoane) da hedolowane Giaila yolesili, gadili ahoanu. Solo da Da: ibidi da Giaila amoga hobea: i, amo sia: nababeba: le, e da ea musa: ilegei yolesiagai.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n tó ẹgbẹ̀ta ènìyàn sì dìde, wọ́n lọ kúrò ní Keila, wọ́n sì lọ sí ibikíbi tí wọ́n lè rìn lọ. A sì wí fún Saulu pé, “Dafidi ti sá kúrò ní Keila; kò sì lọ sí Keila mọ́.”
14 Da: ibidi da agolo soge (wadela: i hafoga: i soge Sife moilai bai bagade gadenene gala) amo ganodini wamoaligi lalu. Solo da mae yolesili, Da: ibidi hogolalu. Be Hina Gode da Da: ibidi gaga: su.
Dafidi sì ń gbé ní aginjù, níbi tí ó ti sá pamọ́ sí, ó sì ń gbé níbi òkè ńlá kan ní aginjù Sifi. Saulu sì ń wá a lójoojúmọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò fi lé e lọ́wọ́.
15 Da: ibidi e da Solo ea e medole legemu galebeya dawa: lebe, amo hi dawa: i galu. E da Houlese sogebi wadela: i hafoga: i soge Sife moilai bai bagade gadenene esalu.
Nígbà tí Dafidi wà ní Horeṣi ní aginjù Sifi, Dafidi sì rí i pé, Saulu ti jáde láti wá ẹ̀mí òun kiri.
16 Yonada: ne da Da: ibidi ea dogo denesima: ne, amola Gode da e gaga: ma: ne esala amo olelema: ne, amoga asi.
Jonatani ọmọ Saulu sì dìde, ó sì tọ Dafidi lọ nínú igbó Horeṣi, ó sì gbà á ní ìyànjú nípa ti Ọlọ́run.
17 E da Da: ibidima amane sia: i, “Mae beda: ma! Na ada Solo da di wadela: lesimu hamedei ba: mu. E da noga: le dawa: , amo di da fa: no ea hina bagade sogebi lamu, amola na da dia baligia hina ba: mu.”
Òun sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí tí ọwọ́ Saulu baba mi kì yóò tẹ̀ ọ́. Ìwọ ni yóò jẹ ọba lórí Israẹli, èmi ni yóò sì ṣe ibìkejì rẹ. Saulu baba mi mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
18 Ela da eso huluane dogolegele esaloma: ne sema ilegei. Da: ibidi da Houlese amoga esalu, amola Yonada: ne da hi diasuga asi.
Àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn níwájú Olúwa; Dafidi sì jókòó nínú igbó Horeṣi. Jonatani sì lọ sí ilé rẹ̀.
19 Sife fi dunu mogili da Gibia moilaiga Soloma asili ema amane sia: i, “Da: ibidi da ninia soge Houlese amo ganodini wamoaligisa. E da Ha: sila Goumi amo Yuda soge ga (south) la: idili esala.
Àwọn ará Sifi sì gòkè tọ Saulu wá sí Gibeah, wọ́n sì wí pé, “Ṣé Dafidi ti fi ara rẹ̀ pamọ́ sọ́dọ̀ wa ní ibi gíga ìsápamọ́sí ní Horeṣi, ní òkè Hakila, tí ó wà níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
20 Hina bagade noga: idafa! Di da e gagulaligimu bagade hanai, amo ninia dawa: Amaiba: le, ninia sogega misa. Amasea, ninia da di amo dunu gagulaligima: ne, logo doasimu.”
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ọba, sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìfẹ́ tí ó wà ní ọkàn rẹ láti sọ̀kalẹ̀: ipa tí àwa ní láti fi lé ọba lọ́wọ́.”
21 Solo da ilima amane nodoi, “Dilia da nama asigiwane hamobeba: le, Hina Gode da dilima hahawane dogolegele hamomu da defea.
Saulu sì wí pé, “Alábùkún fún ni ẹ̀yin nípa Olúwa; nítorí pé ẹ̀yin ti káàánú fún mi.
22 Dilia ea wamoaligisu bu noga: le ba: ma: ne masa. Nowa da e ba: i galea, amo hogoma. Bai ea ogogole dawa: digisu hou, amo na da nabi.
Lọ, èmi bẹ̀ yín, ẹ tún múra, kí ẹ sì mọ̀ ki ẹ si rí ibi tí ẹsẹ̀ rẹ̀ gbé wà, àti ẹni tí ó rí níbẹ̀: nítorí tí a ti sọ fún mi pé, ọgbọ́n ni ó ń lò jọjọ.
23 Ea wamoaligisu sogebi huluane noga: le hogolalu, nama sia: legema. Amasea, na da nini masunu. E da dilia sogea amogaiwane esalea, na da ema fa: no bobogele gagulaligimu. Hedolo hame ba: sea, na da Yuda soge huluanedafa hogomu.”
Ẹ sì wò, kí ẹ sì mọ ibi ìsápamọ́ tí ó máa ń sá pamọ́ sí, kí ẹ sì tún padà tọ̀ mí wá, kí èmi lè mọ̀ dájú; èmi ó sì bá yín lọ: yóò sì ṣe bí ó bá wà ní ilẹ̀ Israẹli, èmi ó sì wá a ní àwárí nínú gbogbo ẹgbẹ̀rún Juda!”
24 Amalalu, Sife fi dunu da yolesili, ilia da Solo bisili Sife sogega buhagi. Da: ibidi amola ea dunu da Ma: ione hafoga: i soge, wadela: i fago Yuda soge ga (south) la: ididili amoga esalebe ba: i.
Wọ́n sì dìde, wọ́n sì ṣáájú Saulu lọ sí Sifi, ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wà ní aginjù Maoni, ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
25 Solo amola ea dunu da Da: ibidi hogola asi. Be Da: ibidi amo nababeba: le, gele agolo Ma: ione wadela: i hafoga: i soge amo ganodini diala, amoga asili esalu. Solo da Da: ibidi amo sogebia esalebe nabaloba, ema fa: no bobogemusa: asi.
Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ ń wá a. Wọ́n sì sọ fún Dafidi: ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí ibi òkúta kan, ó sì jókòó ní aginjù ti Maoni. Saulu sì gbọ́, ó sì lépa Dafidi ní aginjù Maoni.
26 Solo amola ea dunu da agolo la: idi esalu, amola Da: ibidi da agolo amogawane la: ididili esalebe ba: i. Da: ibidi amola ea dunu da hehenaia hobealebe ba: i. Bai Solo da ili gagulaligimu gadenene ba: i.
Saulu sì ń rin apá kan òkè kan, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní apá kejì òkè náà. Dafidi sì yára láti sá kúrò níwájú Saulu; nítorí pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ti rọ̀gbà yí Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ká láti mú wọn.
27 Be amoha, sia: ne iasu dunu da Soloma doaga: le, ema amane sia: i, “Wahadafa buhagima! Filisidini dunu da ninia sogega doagala: le, golili daha.”
Ṣùgbọ́n oníṣẹ́ kan sì tọ Saulu wá ó sì wí pé, “Ìwọ yára kí o sì wá, nítorí tí àwọn Filistini ti gbé ogun ti ilẹ̀ wa.”
28 Amaiba: le, Solo da Da: ibidi sefasilalu yolesili, buhagili, Filisidini dunuma gegemusa: asi. Amaiba: le, ilia da amo agolo dio “Afafasu Agolo” asuli.
Saulu sì padà kúrò ní lílépa Dafidi, ó sì lọ pàdé àwọn Filistini nítorí náà ni wọ́n sì ṣe ń pe ibẹ̀ náà ní Selahamalekoti (èyí tí ó túmọ̀ sí “Òkúta Ìpinyà”).
29 Da: ibidi da amo soge yolesili, Enegedi sogega wamoaligimusa: asili, esalu.
Dafidi sì gòkè láti ibẹ̀ lọ, ó sì jókòó níbi tí ó sá pamọ́ sí ní En-Gedi.

< 1 Sa:miuele 23 >