< 1 Hou Olelesu 21 >

1 Sa: ida: ne da Isala: ili fi ilima bidi hamosu ima: ne dawa: i galu. E da Da: ibidi ea asigi dawa: su ganodini hamobeba: le, Da: ibidi da Isala: ili fi dunu huluane idili dedemusa: dawa: i galu.
Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
2 Amaiba: le, Da: ibidi da dadi gagui wa: i ouligisudafa amo Youa: be, amola ea afoha ouligisu dunu huluane ilima amane sia: i, “Isala: ili fi huluane fadomane fasisa asili muni na: iyado soge bega: asili na: iyado bega: doaga: le amola dunu huluane idima. Na da ili idi dawa: mu hanai gala.”
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
3 Be Youa: be da amane adole i, “Hina noga: idafa! Dia Hina Gode da Isala: ili dunu ilia idi amo bagalesili, bu afae da 100 ba: ma: ne hamomu da defea. Amola amo dafawane ba: ma: ne, di da esalumu da defea. Be di, hina noga: idafa, ninia fi huluane da wadela: le hamosa: besa: le, abuliba: le amo hamomusa: hanabela: ?”
Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
4 Be Da: ibidi da Youa: be ea sia: i nabawane hamoma: ne logei. Youa: be da e fisili, Isala: ili dunu idimusa: asi. E da Isala: ili soge huluanedafa amo ganodini ahoanu, Yelusalemega buhagi.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
5 E da hina bagadema amo dunu huluane amo da gegemusa: defele esalu, amo ilia idi ema sia: ne iasu. Ilia idi da Isala: ili dunu 1,100,000 agoane amola Yuda dunu 470,000 agoane.
Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
6 Youa: be da hina bagade Da: ibidi ea hamoma: ne sia: i higa: iba: le, e da Lifai amola Bediamini fi dunu hame idili dedei.
Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
7 Gode da amo hou hamoi hihini ba: i. Amaiba: le, e da Isala: ili fi ilima se iasu i.
Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
8 Da: ibidi da Godema amane sia: i, “Na da amo hamobeba: le, wadela: le bagadedafa hamoi. Dafawane! Na da gagaoui agoane hamoi dagoi. Na gogolema: ne olofoma.”
Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
9 Hina Gode da Ga: de (Da: ibidi ea balofede dunu) ema amane sia: i,
Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
10 “Di Da: ibidima asili, amola ema Na da ilegesu udiana ema olelemu. Amo ilegesu hi da ilegesea, amo Na da ema hamomu.”
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
11 Ga: de da ema asili, Hina Gode Ea sia: i ema alofele i. E da Da: ibidima amane adole ba: i, “Di da adi ilegesala: ?
Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
12 Dia soge amo ganodini ha: i ode udiana ilegema: bela: ? O oubi udiana amoga dia ha lai da di hasalabeba: le, di sefasimu, amo ilegema: bela: ? O eso udiana Hina Gode da Ea gegesu gobiheiga dima doagala: mu amola olo bagade dia sogega madelama: ne, Ea a: igele dunu asunasimu, amo ilegema: bela: ? Di dawa: lalu, nama adole ima. Amasea, na da Hina Godema alofele adole imunu.”
Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
13 Da: ibidi da bu adole i, “Na da bidi hamosu bagadedafa amoga sisiga: i. Be na da osobo bagade dunuga se nabimu higa: i. Hina Gode Hisu da ninima se imunu da defea. Bai e da asigisa, amola gogolema: ne olofosu dawa:”
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
14 Amaiba: le, Hina Gode da olo bagade Isala: ili dunuma iasi. Olo da amogala hahabe muni, Gode ea ilegei eso idi ganodini ba: i. Olo da Isala: ili soge bega: asili, la: idi bega: doaga: le, amola Isala: ili dunu 70,000 agoane da bogogia: i ba: i.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
15 Hina Gode da Ea a: igele dunu Yelusaleme wadela: lesimusa: asunasi. Be Hina Gode ea asigi dawa: su afadenene, da: i dione, a:igele dunuma sia: i, “Aligima! Bu mae wadela: lesima.” Amogalu, a:igele dunu da Yebiusaide dunu ea dio amo Alona ea widi dabasu sogebi amoga lelebe ba: i.
Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
16 Da: ibidi da a: igele ea gegesu gobihei gaguiwane, Yelusaleme gugunufinisimusa: , osobo gadodili hamefufua esalebe ba: i. Amalalu, Da: ibidi amola Isala: ili ouligisu dunu - huluane da eboboi abulaga ga: i- ilia da beguduli osoboga mi bugila sa: i.
Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
17 Da: ibidi da Hina Godema amane sia: i, “Gode! Na fawane da wadela: le hamoi. Na fawane da idili dedesu hamoma: ne sia: i. Amo hahani dunu da adi hamobela: ? Na Hina Gode! Di da na amola na sosogo ninima se imunu da defea galu. Be Dia fi dunu yolesima!”
Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
18 Hina Gode Ea a: igele dunu da ema sia: beba: le, Ga: de da Da: ibidima asili, amane sia: i, “Dia Alona ea widi dabasu amoga asili, Hina Godema gobele salimusa: , oloda gaguma.”
Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
19 Da: ibidi da Hina Gode Ea sia: Ga: demadi misi, amo nababeba: le, asi.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
20 Widi dabasu sogega, Alona amola egefe biyaduyale da widi dabalelebe ba: i. Ilia da a: igele ba: beba: le, Alona egefelali da wamoaligimusa: hobea: i.
Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
21 Alona da hina bagade manebe ba: beba: le, e da dabasu soge fisili, beguduli osoboga mi bugila sa: i.
Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
22 Da: ibidi da ema amane sia: i, “Dia widi dabasu sogebi nama bidi lama! Bai amogawi amo olo hedofama: ne, na da Hina Godema oloda hamomusa: misi. Na da amo sogebi ea bidi defele dima imunu.”
Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
23 Alona da amane sia: i, “Defea, hina noga: idafa! Lama! Amola dia hanaiga Hina Godema gobele salima. Amola na bulamagau di oloda da: iya gobele salimusa: lama. Ilia ‘youge’ amola dabasu ifa amo lalu didima: ne lama. Na da amo huluane udigili dima iaha.”
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
24 Be hina bagade da bu adole i, “Hame mabu! Na da amo liligi ea bidi defele dima imunu. Liligi amo na da bidi mae iawane udigili lai, amo na da na Hina Godema hame gobele salimu.”
Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
25 Amola, e da widi dabasu sogebi, amo gouli fage 600 agoanega bidi lai.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
26 Amalalu, Da: ibidi da Hina Godema oloda gaguli, amola amo da: iya Wadela: i Hou Dabe Ima: ne Iasu amola Hahawane Gilisili Olofele Iasu hamosu. Da: ibidi da Hina Godema sia: ne gadoi amola Hina Gode da Da: ibidi ea sia: ne gadosu nababeba: le, dabe adole i. E da muagadodili, lalu amo gobele salasu liligi gobele salimusa: iasi.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
27 Hina Gode da Ea a: igele dunuma, ea gegesu gobihei bu salima: ne sia: i.
Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
28 Amo hou ba: beba: le, Hina Gode da ea sia: ne gadosu amoma dabe adole i, Da: ibidi da ba: i dagoi. Amaiba: le, e da Alona widi dadabisu sogebiga oloda da: iya, gobele salasu.
Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
29 Amo esoga, Hina Gode Ea Abula Diasu (Mousese da amo hafoga: i sogega hamoi) amola oloda amoga ilia da gobele salasu, amo da Gibione sia: ne gadosu sogebiga dialebe ba: i.
Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
30 Be Da: ibidi da Godema nodone sia: ne gadomusa: , Gibione soge amoga masunu hamedei ba: i. Bai e da Hina Gode Ea a: igele dunu ea gegesu gobiheiba: le beda: i galu.
Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.

< 1 Hou Olelesu 21 >