< Psalms 95 >

1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
بیایید خداوند را ستایش کنیم و در وصف صخرهٔ نجات خود، با شادی سرود بخوانیم!
2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
با شکرگزاری به حضور او بیاییم و با سرودهای شاد او را بپرستیم!
3 Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
زیرا خداوند، خدای عظیمی است؛ او پادشاهی است که بر همهٔ خدایان فرمان می‌راند.
4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
اعماق زمین در دست خداوند است و بلندی و عظمت کوهها از آن او می‌باشد.
5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
آبها و خشکی‌ها را خدا به وجود آورده و آنها به او تعلق دارند.
6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú Olúwa ẹni tí ó dá wa,
بیایید در برابر خدا، سر فرود آوریم و او را عبادت کنیم. بیایید در حضور آفرینندهٔ خود زانو بزنیم.
7 nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
ما قوم او هستیم و او خدای ما، ما گلهٔ او هستیم و او شبان ما. امروز، اگر صدای او را می‌شنوید که می‌فرماید:
8 “Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba, àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
«دل خود را سخت نکنید، همان کاری که نیاکان شما در صحرای مریبا و مَسّا کردند.
9 nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò tí wọn wádìí mi, tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
زیرا در آنجا، نیاکان شما، صبر مرا آزمایش و امتحان کردند، با اینکه کارهای مرا دیده بودند.
10 Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà; mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
مدت چهل سال، از آنها بیزار بودم، و گفتم:”اینها قومی هستند که دلشان از من برگشته. آنها دیگر مرا اطاعت نمی‌کنند.
11 Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’”
پس در خشم خود سوگند خوردم که به آسایش من هرگز راه نخواهند یافت.“»

< Psalms 95 >