< Psalms 77 >
1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
Глас мој иде к Богу, и ја призивам Њега; глас мој иде к Богу, и Он ће ме услишити.
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
У дан туге своје тражих Господа; ноћу је рука моја подигнута, и не спушта се; душа моја неће да се утеши.
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
Помињем Бога, и уздишем; размишљам, и трне дух мој.
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
Држим очи своје да су будне; клонуо сам, и не могу говорити.
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
Пребрајам старе дане и године од векова.
6 mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
Опомињем се песама својих ноћу; разговарам се са срцем својим, и испитујем дух свој:
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
"Зар ће се довека гневити на нас Господ, и неће више љубити?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
Зар је засвагда престала милост Његова, и реч се прекинула од колена на колено?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
Зар је заборавио милостив бити и у гневу затворио милосрђе своје?"
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
И рекох: Жалосна је за мене ова промена деснице Вишњега.
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
Памтим дела Господња; памтим пређашње чудо Твоје.
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
Мислио сам о свим делима Твојим, размишљао о радњи Твојој;
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
Боже! Пут је Твој свет; који је Бог тако велик као Бог наш?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
Ти си Бог, који си чинио чудеса, показивао силу своју међу народима;
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
Мишицом си одбранио народ свој, синове Јаковљеве и Јосифове.
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
Видеше Те воде, Боже, видеше Те воде, и устрепташе, и бездане се задрмаше.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
Из облака лијаше вода, облаци даваху глас, и стреле Твоје лећаху.
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
Грмљаху громови Твоји по небу; муње Твоје севаху по васиљеној, земља се тресаше и њихаше.
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
По мору беше пут Твој, и стазе Твоје по великој води, и траг Твој не познаваше се.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Водио си народ свој као овце руком Мојсијевом и Ароновом.