< Psalms 42 >
1 Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
To victorie, to the sones of Chore. As an hert desirith to the wellis of watris; so thou, God, my soule desirith to thee.
2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
Mi soule thirstide to God, `that is a `quik welle; whanne schal Y come, and appere bifor the face of God?
3 Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
Mi teeris weren looues to me bi dai and nyyt; while it is seid to me ech dai, Where is thi God?
4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
I bithouyte of these thingis, and Y schedde out in me my soule; for Y schal passe in to the place of the wondurful tabernacle, til to the hows of God. In the vois of ful out ioiyng and knoulechyng; is the sown of the etere.
5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Mi soule, whi art thou sory; and whi disturblist thou me? Hope thou in God, for yit Y schal knouleche to hym; he is the helthe of my cheer,
6 Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
and my God. My soule is disturblid at my silf; therfor, God, Y schal be myndeful of thee fro the lond of Jordan, and fro the litil hil Hermonyim.
7 Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
Depthe clepith depthe; in the vois of thi wyndows. Alle thin hiye thingis and thi wawis; passiden ouer me.
8 Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
The Lord sente his merci in the dai; and his song in the nyyt.
9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
At me is a preier to the God of my lijf; Y schal seie to God, Thou art my `takere vp. Whi foryetist thou me; and whi go Y sorewful, while the enemy turmentith me?
10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
While my boonys ben brokun togidere; myn enemyes, that troblen me, dispiseden me. While thei seien to me, bi alle daies; Where is thi God?
11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Mi soule, whi art thou sori; and whi disturblist thou me? Hope thou in God, for yit Y schal knouleche to hym; `he is the helthe of my cheer, and my God.