< Matthew 4 >
1 Nígbà náà ni Ẹ̀mí Mímọ́ darí Jesu sí ijù láti dán an wò láti ọwọ́ èṣù.
A LAILA, alakaiia'ku la o Iesu e ka Uhane i ka waonahele, e hoowalewaleia'ku ai e ka diabolo.
2 Lẹ́yìn tí Òun ti gbààwẹ̀ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ebi sì ń pa á.
Hookeai iho la ia i hookahi kanaha la, a me na po he kanaha, a mahope iho, pololi iho la ia.
3 Nígbà náà ni olùdánwò tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ kí òkúta wọ̀nyí di àkàrà.”
A hiki aku ka mea hoowalewale io na la, i aku la ia, Ina o ke Keiki oe a ke Akua, e i mai oe i keia mau pohaku i lilo i berena.
4 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn pé, “A ti kọ ìwé rẹ̀ pé: ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan, bí kò ṣe nípa gbogbo ọ̀rọ̀ ti ó ti ẹnu Ọlọ́run jáde wá.’”
Aka, olelo mai la o Iesu, i mai la, Ua palapalaia, Aole e ola ke kanaka i ka berena wale no, aka, ma na mea a pau mai ka waha mai o ke Akua.
5 Lẹ́yìn èyí ni èṣù gbé e lọ sí ìlú mímọ́ náà; ó gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili.
Alaila, lawe aku la ka diabolo ia ia i ke kulanakauhale hoano; a hookau aku la ia ia maluna iho o kahi oioi o ka luakini;
6 Ó wí pé, “Bí ìwọ̀ bá jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ. A sá à ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí tìrẹ wọn yóò sì gbé ọ sókè ni ọwọ́ wọn kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
I aku la ia ia, Ina o oe ke Keiki a ke Akua, e lele iho oe ilalo; no ka mea, ua palapalaia, E kauoha mai no ia i kona poe anela nou, e kaikai lakou ia oe ma ko lakou mau lima, o kuia kou wawae i ka pohaku.
7 Jesu sì dalóhùn, “A sá à ti kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
I mai la o Iesu, Ua palapalaia no hoi, Mai hoao aku oe i ka Haku i kou Akua.
8 Lẹ́ẹ̀kan sí i, èṣù gbé e lọ sórí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé àti gbogbo ògo wọn hàn án.
Lawe hou aku la ka diabolo ia ia i kahi mauna kiekie loa, a hoike aku la ia ia i na aupuni a pau o ka honua, a me ko lakou nani;
9 Ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi yóò fi fún ọ, bí ìwọ bá foríbalẹ̀ tí o sì sìn mi.”
I aku la hoi ia ia, O keia mau mea a pau ka'u e haawi aka ai ia oe, ke kukuli iho oe, a hoomana mai ia'u.
10 Jesu wí fún un pé, “Padà kúrò lẹ́yìn mi, Satani! Nítorí a ti kọ ọ́ pé, ‘Olúwa Ọlọ́run rẹ ni kí ìwọ kí ó fi orí balẹ̀ fún, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ máa sìn.’”
Alaila, olelo mai la Iesu ia ia, E hele pela oe, e Satana; no ka mea, ua palapalaia, E hoomana aku oe i ka Haku i kou Akua, a e malama aku oe ia ia wale no.
11 Nígbà náà ni èṣù fi í sílẹ̀ lọ, àwọn angẹli sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Alaila, haalele aku la ka diabolo ia ia; aia hoi, hele mai la na anela, a lawelawe nana.
12 Nígbà tí Jesu gbọ́ wí pé a ti fi Johanu sínú túbú ó padà sí Galili.
Lohe ae la o Iesu, ua hooleiia o Ioane iloko o ka halepaahao, hele aku la ia i Galilaia.
13 Ó kúrò ní Nasareti, ó sì lọ í gbé Kapernaumu, èyí tí ó wà létí Òkun Sebuluni àti Naftali.
Haalele ae la oia ia Nazareta, hele aku la a noho ma Kaperenauma ma ke kahaloko, ma ka mokuna o Zabulona o me Napetali.
14 Kí èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Isaiah lè ṣẹ pé,
Pela i ko ai ka mea i oleloia e ke kaula e Isaia, i ka i ana mai,
15 “Ìwọ Sebuluni àti ilẹ̀ Naftali ọ̀nà tó lọ sí Òkun, ní ọ̀nà Jordani, Galili ti àwọn kèfèrí.
O ka aina o Zabulona, a o ka aina o Napetali ma ke ala o ka loko ma kela aoao o Ioredane, o Galilaia no na kanaka e;
16 Àwọn ènìyàn tí ń gbé ni òkùnkùn tí ri ìmọ́lẹ̀ ńlá, àti àwọn tó ń gbé nínú ilẹ̀ òjijì ikú ni ìmọ́lẹ̀ tan fún.”
O ka poe kanaka e noho ana ma ka pouli, ike ae la lakou i ka malamalama nui; amaluna o ka poe e noho ana ma ka malu o ka make, ua puka mai ka malamalama.
17 Láti ìgbà náà lọ ni Jesu ti bẹ̀rẹ̀ sí wàásù: “Ẹ ronúpìwàdà, nítorí tí ìjọba ọ̀run kù sí dẹ̀dẹ̀.”
Mai ia manawa mai, hoomaka o Iesu e hai mai a e olelo mai, E mihi oukou, no ka mea, ua kokoke mai nei ke aupuni o ka lani.
18 Bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, ó rí àwọn arákùnrin méjì, Simoni, ti à ń pè ní Peteru, àti Anderu arákùnrin rẹ̀. Wọ́n ń sọ àwọ̀n wọn sínú Òkun nítorí apẹja ni wọ́n.
Hele aku la o Iesu ma ke kae o ka loko o Galilaia, ike mai la ia i na hoabanau elua, o Simona i kapaia o Petero, a me kona kaikaina o Anederea, e kuu ana i ka upena i ka loko, no ka mea, he mau lawaia laua.
19 Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ wá, ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
I mai la oia ia laua, E hahai mai olua ia'u, a e hoolilo au ia olua i mau lawaia kanaka.
20 Lójúkan náà, wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Haalele koke iho la laua i na upena, a hahai aku la ia ia.
21 Bí ó sì ti kúrò ní ibẹ̀, ò rí àwọn arákùnrin méjì mìíràn, Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu, arákùnrin rẹ̀. Wọ́n wà nínú ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú Sebede baba wọn, wọ́n ń di àwọ̀n wọn, Jesu sì pè àwọn náà pẹ̀lú.
A hele aku la ia malaila aku, ike mai la ia i na hoahanau e ae elua, o Iakobo ke keiki a Zebedaio, a me kona kaikaina o Ioane, maluna no o ka moku me ko laua makuakane o Zebedaio, e hono ana i ka lakou mau upena, a kahea mai la oia ia laua.
22 Lójúkan náà, wọ́n fi ọkọ̀ ojú omi àti baba wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Haalele koke aku la laua i ka moku, a me ka laua makuakane, a hahai aku la ia ia.
23 Jesu sì rin káàkiri gbogbo Galili, ó ń kọ́ni ní Sinagọgu, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba ọ̀run, ó sì ń ṣe ìwòsàn ààrùn gbogbo àti àìsàn láàrín gbogbo ènìyàn.
Kaahele ae la o Iesu ma Galilaia a puni, e ao mai ana iloko o ko lakou mau halehalawai, a e hai mai ana i ka euanelio no ke aupuni, a e hoola ana hoi i ka mai a me ka nawaliwali a pau o na kanaka.
24 Òkìkí rẹ̀ sì kàn yí gbogbo Siria ká; wọ́n sì gbé àwọn aláìsàn tí ó ní onírúurú ààrùn, àwọn tí ó ní ìnira ẹ̀mí èṣù, àti àwọn ti o ní wárápá àti àwọn tí ó ní ẹ̀gbà; ó sì wò wọ́n sàn.
Kui aku la kona kaulana i Suria a puni, halihali mai la lakou io na la i ko lakou poe mai a pau, i loohia e kela mai keia mai, a me na eha, o ka poe i ulubia e na daimonio, a me ka poe hebena, a me ka poe lolo; a hoola mai la oia ia lakou.
25 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili, Dekapoli, Jerusalẹmu, Judea, àti láti òkè odò Jordani sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
He nui loa ka poe kanaka i hahai mai ia ia no Galilaia mai, no Dekapoli mai, a no Ierusalema mai, no Iudea mai, a no kela kapa mai o Ioredane.