< Lamentations 2 >

1 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Како обастре Господ облаком у гневу свом кћер сионску! Сврже с неба на земљу славу Израиљеву, и не опомену се подножја ногу својих у дан гнева свог!
2 Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
Господ потре немилице све станове Јаковљеве, развали у гневу свом градове кћери Јудине, и на земљу обори, оскврни царство и кнезове његове.
3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
Одби у жестоком гневу сав рог Израиљу, обрати натраг десницу своју од непријатеља, и распали се на Јакова као огањ пламени, који прождире све око себе.
4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
Натеже лук свој као непријатељ, подиже десницу своју као противник, и поби све што беше драго очима; на шатор кћери сионске просу као огањ гнев свој.
5 Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
Господ поста као непријатељ; потре Израиља, потре све дворе његове, раскопа све градове његове, и умножи кћери Јудиној жалост и јад.
6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
Развали му ограду као врту; потре место састанцима његовим; Господ врже у заборав на Сиону празнике и суботу, и у жестини гнева свог одбаци цара и свештеника.
7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
Одбаци Господ олтар свој, омрзе на светињу своју, предаде у руке непријатељима зидове двора сионских; стаде их вика у дому Господњем као на празник.
8 Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
Господ науми да раскопа зид кћери сионске, растеже уже, и не одврати руке своје да не затре, и ојади опкоп и зид, изнемогоше скупа.
9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
Утонуше у земљу врата њена, поломи и потре преворнице њене; цар њен и кнезови њени међу народима су; закона нема, и пророци њени не добијају утваре од Господа.
10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
Старешине кћери сионске седе на земљи и ћуте, посуле су прахом главу и припасале кострет; обориле су к земљи главе своје девојке јерусалимске.
11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
Ишчилеше ми очи од суза, утроба се моја усколебала, просипа се на земљу јетра моја од погибли кћери народа мог, јер деца и која сисају обамиру на улицама градским.
12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
Говоре матерама својим: Где је жито и вино? Обамиру као рањеници на улицама градским, и испуштају душу своју у наручју матера својих.
13 Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
Кога ћу ти узети за сведока? С чим ћу те изједначити, кћери јерусалимска? Какву ћу ти прилику наћи, да те утешим, девојко, кћери сионска? Јер је несрећа твоја велика као море, ко ће те исцелити?
14 Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
Пророци твоји пророковаше ти лаж и безумље, и не откриваше безакоња твог да би одвратили ропство твоје; него ти казиваше утваре лажне и које ће те прогнати.
15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
Пљескају рукама над тобом сви који пролазе, звижде и машу главом за кћерју јерусалимском: То ли је град, за који говораху да је права лепота, радост свој земљи?
16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
Разваљују уста на те сви непријатељи твоји, звижде и шкргућу зубима говорећи: Прождресмо; ово је доиста дан који чекасмо; дочекасмо, видесмо.
17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
Учини Господ шта науми, испуни реч своју, коју каза одавна; разори немилице и развесели тобом непријатеља, подиже рог противницима твојим.
18 Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
Виче срце њихово ка Господу: Зиде кћери сионске, проливај потоком сузе дан и ноћ, не дај себи мира, и зеница ока твог да не стаје.
19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
Устани, вичи обноћ, у почетку страже, проливај срце своје као воду пред Господом, подижи к Њему руке своје за душу деце своје која обамиру од глади на угловима својих улица.
20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
Погледај, Господе, и види, коме си овако учинио. Еда ли жене једу пород свој, децу коју носе у наручју? Еда ли се убија у светињи Господњој свештеник и пророк?
21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
Леже на земљи по улицама деца и старци, девојке моје и младићи моји падоше од мача, побио си их у дан гнева свог и поклао не жалећи.
22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”
Сазвао си као на празник страхоте моје од свуда, и у дан гнева Господњег нико не утече нити оста. Које на руку носих и отхраних, њих ми непријатељ мој поби.

< Lamentations 2 >