< Joshua 21 >
1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Então os Cabeças dos pais dos levitas se achegaram a Eleazar o sacerdote, e a Josué, filho de Nun, e aos Cabeças dos pais das tribos dos filhos de Israel;
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
E falaram-lhes em Silo na terra de Canaan, dizendo: O Senhor ordenou, pelo ministério de Moisés, que se nos dessem cidades para habitar, e os seus arrabaldes para os nossos animais.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Pelo que os filhos de Israel deram aos levitas da sua herança, conforme ao dito do Senhor, estas cidades e os seus arrabaldes.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
E saiu a sorte pelas famílias dos kohathitas: e aos filhos de Aarão, o sacerdote, dentre os levitas, cairam por sorte da tribo de Judá, e da tribo de Simeão, e da tribo de Benjamin, treze cidades;
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
E aos outros filhos de Kohath cairam por sorte das famílias da tribo de Ephraim, e da tribo de Dan, e da meia tribo de Manasseh, dez cidades;
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
E aos filhos de Gerson cairam por sorte das famílias da tribo de issacar, e da tribo de Aser, e da tribo de Naphtali, e da meia tribo de Manasseh em Basan, treze cidades;
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Aos filhos de Merari, segundo as suas famílias, da tribo de Ruben, e da tribo de Gad, e da tribo de Zebulon, doze cidades.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
E deram os filhos de Israel aos levitas estas cidades e os seus arrabaldes por sorte, como o Senhor ordenara pelo ministério de Moisés.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
Deram mais da tribo dos filhos de Judá e da tribo dos filhos de Simeão estas cidades, que por nome foram nomeadas:
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Para que fossem dos filhos de Aarão, das famílias dos kohathitas, dos filhos de Levi: porquanto a primeira sorte foi sua.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
Assim lhes deram a cidade de Arba, do pai de Anok (esta é Hebron), no monte de Judá, e os seus arrabaldes em redor dela.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Porém o campo da cidade, e as suas aldeias, deram a Caleb, filho de Jefoné, por sua possessão.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Assim aos filhos de Aarão, o sacerdote, deram a cidade do refúgio do homicida, Hebron, e os seus arrabaldes, e Libna, e os seus arrabaldes;
E Jatthir, e os seus arrabaldes, e Estmoa, e os seus arrabaldes;
E Cholon, e os seus arrabaldes, e Debir, e os seus arrabaldes,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
E Ain, e os seus arrabaldes, e Jutta, e os seus arrabaldes, e Bethsemes, e os seus arrabaldes: nove cidades destas duas tribos.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
E da tribo de Benjamin, Gibeon, e os seus arrabaldes, Geba, e os seus arrabaldes;
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Anathoth, e os seus arrabaldes, e Almon, e os seus arrabaldes; quatro cidades.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Todas as cidades dos sacerdotes, filhos de Aarão, foram treze cidades e os seus arrabaldes.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
E as famílias dos filhos de Kohath, levitas, que ficaram dos filhos de Kohath, tiveram as cidades da sua sorte da tribo de Ephraim.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
E deram-lhes Sichem, cidade do refúgio do homicida, e os seus arrabaldes, no monte de Ephraim, e Gezer, e os seus arrabaldes;
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
E Kibsaim, e os seus arrabaldes, e Beth-horon, e os seus arrabaldes: quatro cidades.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
E da tribo de Dan, Elteke, e os seus arrabaldes, Gibbethon, e os seus arrabaldes;
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ajalon, e os seus arrabaldes, Gath-rimmon, e os seus arrabaldes: quatro cidades.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
E da meia tribo de Manasseh, Taanach, e os seus arrabaldes, e Gath-rimmon, e os seus arrabaldes: duas cidades.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
Todas as cidades para as famílias dos filhos de Kohath que ficavam, foram dez, e os seus arrabaldes.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
E aos filhos de Gerson, das famílias dos levitas, Golan da meia tribo de Manasseh, cidade do refúgio do homicida, em Basan, e os seus arrabaldes, e Be-estra, e os seus arrabaldes: duas cidades.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
E da tribo de Issacar, Kisjon, e os seus arrabaldes: Daberath, e os seus arrabaldes;
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jarmuth, e os seus arrabaldes, En-Gannim, e os seus arrabaldes: quatro cidades.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
E da tribo de Aser, Misal, e os seus arrabaldes, Abdon, e os seus arrabaldes;
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkath, e os seus arrabaldes, e Rohob, e os seus arrabaldes: quatro cidades.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
E da tribo de Naphtali, Kedes, cidade do refúgio do homicida, em Galiléia, e os seus arrabaldes, e hamoth-dor, e os seus arrabaldes; e Cartan, e os seus arrabaldes: três cidades.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Todas as cidades dos gersonitas, segundo as suas famílias, foram treze cidades e os seus arrabaldes.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
E às famílias dos filhos de Merari, dos levitas que ficavam, foram dadas da tribo de Zebulon, Jokneam e os seus arrabaldes, Carta e os seus arrabaldes,
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimna e os seus arrabaldes, Nahalal e os seus arrabaldes: quatro cidades.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
E da tribo de Ruben, Beser, e os seus arrabaldes, e Jahaz, e os seus arrabaldes;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kedemoth, e os seus arrabaldes, e Mephaath, e os seus arrabaldes: quatro cidades.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
E da tribo de Gad, Ramoth, cidade do refúgio do homicida, em Gilead, e os seus arrabaldes, e Mahanaim, e os seus arrabaldes;
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Hesbon, e os seus arrabaldes, Jaezer e os seus arrabaldes: por todas, quatro cidades.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Todas estas cidades foram dos filhos de Merari, segundo as suas famílias, que ainda restavam das famílias dos levitas; e foi a sua sorte doze cidades.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
Todas as cidades dos levitas, no meio da herança dos filhos de Israel, foram quarenta e oito cidades e os seus arrabaldes.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
Estavam estas cidades cada qual com os seus arrabaldes em redor delas: assim estavam todas estas cidades.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Desta sorte deu o Senhor a Israel toda a terra que jurara dar a seus pais: e a possuiram e habitaram nela.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
E o Senhor lhes deu repouso em redor, conforme a tudo quanto jurara a seus pais; e nenhum de todos os seus inimigos ficou em pé diante deles; todos os seus inimigos o Senhor deu na sua mão.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Palavra alguma falhou de todas as boas palavras que o Senhor falara à casa de Israel: tudo se cumpriu.