< John 4 >

1 Àwọn Farisi sì gbọ́ pé, Jesu ni, ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀ ju Johanu lọ.
When therefore the Lord knew, that the Pharisees had heard—Jesus, more disciples, is making and immersing, than John, —
2 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Jesu tìkára rẹ̀ kò ṣe ìtẹ̀bọmi bí kò ṣe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀,
although indeed, Jesus himself, was not immersing, but his disciples,
3 Ó fi Judea sílẹ̀, ó sì tún lọ sí Galili.
he left Judaea, and departed again into Galilee.
4 Òun sì ní láti kọjá láàrín Samaria.
Now he must needs pass through Samaria.
5 Nígbà náà ni ó dé ìlú Samaria kan, tí a ń pè ní Sikari, tí ó súnmọ́ etí ilẹ̀ oko tí Jakọbu ti fi fún Josẹfu, ọmọ rẹ̀.
He cometh, therefore, unto a city of Samaria, called Sychar, near the parcel of ground which Jacob gave unto Joseph his son.
6 Kànga Jakọbu sì wà níbẹ̀. Nítorí pé ó rẹ Jesu nítorí ìrìn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó jókòó létí kànga, ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́.
Now Jacob’s fountain was there. Jesus, therefore, having become toil-worn with the journey, was sitting thus, upon the fountain. It was about the sixth hour.
7 Obìnrin kan, ará Samaria sì wá láti fà omi, Jesu wí fún un pé ṣe ìwọ yóò fún mi ni omi mu.
There cometh a woman of Samaria to draw water. Jesus saith unto her—Give me to drink!
8 Nítorí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ sí ìlú láti lọ ra oúnjẹ.
for, his disciples, had gone away into the city, that, food, they might buy.
9 Obìnrin ará Samaria náà sọ fún un pé, “Júù ni ìwọ, obìnrin ará Samaria ni èmi. Èétirí tí ìwọ ń béèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi?” (Nítorí tí àwọn Júù kì í bá àwọn ará Samaria ṣe pọ̀.)
The Samaritan woman, therefore, saith unto him—How dost, thou, being, a Jew, ask to drink, of me, who am, a Samaritan woman? [for, Jews, have no dealings with Samaritans.]
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ ẹ̀bùn Ọlọ́run, àti ẹni tí ó wí fún ọ pé, ‘Fún mi ni omi mu’, ìwọ ìbá sì ti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, òun ìbá ti fi omi ìyè fún ọ.”
Jesus answered, and said unto her—If thou hadst known the free gift of God, and who it is that is saying unto thee, Give me to drink, thou, wouldst have asked him, and he would have given thee living water.
11 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, ìwọ kò ní igbá-ìfami tí ìwọ ó fi fà omi, bẹ́ẹ̀ ni kànga náà jì, Níbo ni ìwọ ó ti rí omi ìyè náà?
She saith unto him—Sir! not even a bucket, hast thou, —and, the well, is, deep: —Whence, then, hast thou the living water?
12 Ìwọ pọ̀ ju Jakọbu baba wa lọ bí, ẹni tí ó fún wa ní kànga náà, tí òun tìkára rẹ̀ si mu nínú rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ̀?”
Art, thou, greater than, our father Jacob, who gave us the well, —and, himself, out of it drank, and his sons, and his flocks?
13 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi yìí, òǹgbẹ yóò sì tún gbẹ ẹ́.
Jesus answered, and said unto her—Whosoever drinketh of this water, will thirst, again;
14 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi tí èmi ó fi fún un, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé; ṣùgbọ́n omi tí èmi ó fi fún un yóò di kànga omi nínú rẹ̀, tí yóò máa sun si ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
But, whosoever shall drink of the water which, I, will give him, in nowise shall thirst, unto times age-abiding, —but, the water which I will give him, shall become, within him, a fountain of water, springing up unto life age-abiding. (aiōn g165, aiōnios g166)
15 Obìnrin náà sì wí fún u pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí, kí òǹgbẹ kí ó má ṣe gbẹ mí, kí èmi kí ó má sì wá fa omi níbí mọ́.”
The woman saith unto him—Sir! give me this water, that I thirst not, neither be coming hither to draw.
16 Jesu wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ, kí ó sì padà wá sí ìhín yìí.”
He saith unto her—Go, call thy husband, and come hither!
17 Obìnrin náà dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Èmi kò ní ọkọ.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn dáradára pé, èmi kò ní ọkọ:
The woman answered, and said [unto him]—I have no husband. Jesus saith unto her—Well, saidst thou, A husband, I have not;
18 Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí, ọkùnrin tí ìwọ sì ní báyìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”
for, five husbands, thou hast had, —and, now, he whom thou hast, is not thy, husband: This true thing, hast thou spoken.
19 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.
The woman saith unto him—Sir! I perceive that, a prophet, art, thou: —
20 Àwọn baba wa sìn lórí òkè yìí; ẹ̀yin sì wí pé, Jerusalẹmu ni ibi tí ó yẹ tí à bá ti máa sìn.”
Our fathers, in this mountain, worshipped; and, ye, say, that, in Jerusalem, is the place, where, to worship, it behoveth.
21 Jesu wí fún un pé, “Gbà mí gbọ́ obìnrin yìí, àkókò náà ń bọ̀, nígbà tí kì yóò ṣe lórí òkè yìí tàbí ní Jerusalẹmu ni ẹ̀yin ó máa sin Baba.
Jesus saith unto her—Believe me, woman! There cometh an hour, when, neither in this mountain, nor yet in Jerusalem, shall ye worship the Father.
22 Ẹ̀yin ń sin ohun tí ẹ̀yin kò mọ̀, àwa ń sin ohun tí àwa mọ̀, nítorí ìgbàlà ti ọ̀dọ̀ àwọn Júù wá.
Ye, worship, that which ye know not; We, worship, that which we know; because, salvation, is, of the Jews.
23 Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́, nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.
But there cometh an hour, and, now, is, —when, the real worshippers, shall worship the Father in spirit and truth; for, even the Father, is seeking, such as these, as his worshippers.
24 Ẹ̀mí ni Ọlọ́run: àwọn ẹni tí ń sìn ín kò lè ṣe aláìsìn ín ní Ẹ̀mí àti ní òtítọ́.”
God is, spirit; and, they that worship him, in spirit and truth, must needs worship.
25 Obìnrin náà wí fún un pé, mo mọ̀ pé, “Messia ń bọ̀ wá, tí a ń pè ní Kristi, nígbà tí Òun bá dé, yóò sọ ohun gbogbo fún wa.”
The woman saith unto him—I know that, Messiah, cometh, who is called Christ, —Whensoever, he, shall come, he will tell us, everything.
26 Jesu sọ ọ́ di mí mọ̀ fún un pé, “Èmi ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí ni Òun.”
Jesus saith unto her—I, that speak unto thee, am he.
27 Lákokò yí ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ dé, ẹnu sì yà wọ́n pé ó ń bá obìnrin sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó wí pé, “Kí ni ìwọ ń wá?” tàbí “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá a sọ̀rọ̀?”
And, hereupon, came his disciples, and they began to marvel, that, with a woman, he was talking. No one, however, said—What seekest thou? or—Why talkest thou with her?
28 Nígbà náà ni obìnrin náà fi ládugbó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n lọ sí ìlú, ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé,
The woman, therefore, left her water-vessel, and went away into the city, and saith unto the men—
29 “Ẹ wá wò ọkùnrin kan, ẹni tí ó sọ ohun gbogbo tí mo ti ṣe rí fún mi, èyí ha lè jẹ́ Kristi náà?”
Come! see a man, that told me all things that ever I did: Can, this, be, the Christ?
30 Nígbà náà ni wọ́n ti ìlú jáde, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
They came forth out of the city, and were coming unto him.
31 Láàrín èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń rọ̀ ọ́ wí pé, “Rabbi, jẹun.”
In the meantime, the disciples were requesting him, saying—Rabbi! eat.
32 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ní oúnjẹ láti jẹ, tí ẹ̀yin kò mọ̀.”
But, he, said unto them—I, have, food, to eat, of which, ye, know not.
33 Nítorí náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bi ara wọn lérè wí pé, “Ẹnìkan mú oúnjẹ fún un wá láti jẹ bí?”
The disciples, therefore, began to say, one to another—Hath anyone brought him, to eat?
34 Jesu wí fún wọn pé, “Oúnjẹ mi ni láti ṣe ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, àti láti parí iṣẹ́ rẹ̀.
Jesus saith unto them—My food, is, that I should do the will of him that sent me, and complete, his work.
35 Ẹ̀yin kò ha wí pé, ‘Ó ku oṣù mẹ́rin, ìkórè yóò sì dé?’ wò ó, mo wí fún un yín, Ẹ ṣí ojú yín sókè, kí ẹ sì wo oko; nítorí tí wọn ti pọ́n fún ìkórè.
Are, ye, not saying—Yet, a fourmonth, it is, and, the harvest, cometh? Lo! I say unto you—Lift up your eyes, and gaze at the fields, —that, white, are they unto, harvest. Already,
36 Kódà báyìí, ẹni tí ó ń kórè ń gba owó ọ̀yà rẹ̀, ó si ń kó èso jọ sí ìyè àìnípẹ̀kun, kí ẹni tí ó ń fúnrúgbìn àti ẹni tí ń kórè lè jọ máa yọ̀ pọ̀. (aiōnios g166)
he that reapeth, receiveth, a reward, and gathereth fruit unto life age-abiding; that, he that soweth, together may rejoice, with him that reapeth. (aiōnios g166)
37 Nítorí nínú èyí ni ọ̀rọ̀ náà fi jẹ́ òtítọ́, ‘Ẹnìkan ni ó fúnrúgbìn, ẹlòmíràn ni ó sì ń kórè jọ.’
For, herein, doth the saying, hold good, —One, is the sower, and, another, is the reaper.
38 Mo rán yín lọ kórè ohun tí ẹ kò ṣiṣẹ́ fún. Àwọn ẹlòmíràn ti ṣiṣẹ́, ẹ̀yin sì kórè èrè làálàá wọn.”
I, sent you forth, to be reaping that whereon, ye, have not toiled: Others, have toiled, and, ye, into their toil, have entered.
39 Ọ̀pọ̀ àwọn ará Samaria láti ìlú náà wá sì gbà á gbọ́ nítorí ìjẹ́rìí obìnrin náà pé, “Ó sọ gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún mi.”
And, out of that city, many, believed on him—of the Samaritans, —by reason of the word of the woman in bearing witness—He told me all things that ever I did.
40 Nítorí náà, nígbà tí àwọn ará Samaria wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n rọ̀ ọ́ pé, kí ó wà pẹ̀lú wọn, ó sì dúró fún ọjọ́ méjì.
When, therefore, the Samaritans came unto him, they went on to request him to abide with them; and he abode there two days.
41 Àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì gbàgbọ́ sí i nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
And, many more, believed by reason of his discourse;
42 Wọ́n sì wí fún obìnrin náà pé, “Kì í ṣe nítorí ọ̀rọ̀ rẹ nìkan ni àwa ṣe gbàgbọ́, nítorí tí àwa tìkára wa ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àwa sì mọ̀ pé, nítòótọ́ èyí ni Kristi náà, Olùgbàlà aráyé.”
and, unto the woman, began to say—No longer, by reason of thy talk, do we believe; for, we ourselves, have heard, and know that, This One, is, in truth, the Saviour of the world.
43 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì ó sì ti ibẹ̀ kúrò, ó lọ sí Galili.
But, after the two days, he went forth from thence, into Galilee.
44 Nítorí Jesu tìkára rẹ̀ ti jẹ́rìí wí pé, Wòlíì kì í ní ọlá ní ilẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
For, Jesus himself, bare witness, that, a prophet, in his own fatherland, hath not, honour.
45 Nítorí náà nígbà tí ó dé Galili, àwọn ará Galili gbà á, nítorí ti wọ́n ti rí ohun gbogbo tí ó ṣe ní Jerusalẹmu nígbà àjọ ìrékọjá; nítorí àwọn tìkára wọn lọ sí àjọ pẹ̀lú.
So, when he came into Galilee, the Galilaeans welcomed him, having seen, all things, whatsoever he had done in Jerusalem during the feast; for, they also, went unto the feast.
46 Bẹ́ẹ̀ ni Jesu tún wá sí Kana ti Galili, níbi tí ó gbé sọ omi di wáìnì. Ọkùnrin ọlọ́lá kan sì wá, ẹni tí ara ọmọ rẹ̀ kò dá ní Kapernaumu.
So he came again into Cana of Galilee, where he had made the water, wine. And there was a certain courtier, whose son was sick, in Capernaum.
47 Nígbà tí ó gbọ́ pé Jesu ti Judea wá sí Galili, ó tọ̀ ọ́ wá, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, kí ó lè sọ̀kalẹ̀ wá kí ó mú ọmọ òun láradá: nítorí tí ó wà ní ojú ikú.
The same, hearing that Jesus had come out of Judaea into Galilee, came away unto him, and began requesting him, that he would come down and heal his son; for he was on the point of dying.
48 Nígbà náà ni Jesu wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá rí àmì àti iṣẹ́ ìyanu, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́ láé.”
Jesus therefore said unto him—Except, signs and wonders, ye see, in nowise will ye believe.
49 Ọkùnrin ọlọ́lá náà wí fún un pé, “Olúwa, sọ̀kalẹ̀ wá kí ọmọ mi tó kú.”
The courtier saith unto him—Sir! come down, ere my child die!
50 Jesu wí fún un pé, “Máa bá ọ̀nà rẹ lọ; ọmọ rẹ yóò yè.” Ọkùnrin náà sì gba ọ̀rọ̀ Jesu gbọ́, ó sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Jesus saith unto him—Be going thy way: thy son, liveth! And the man believed in the word which Jesus spake to him, and at once went his way.
51 Bí ó sì ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pàdé rẹ̀, wọ́n sì wí fún un pé, ọmọ rẹ ti yè.
And, when he was even now going down, his servants, met him, saying, that, his boy, was living.
52 Nígbà náà ni ó béèrè wákàtí tí ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í yá lọ́wọ́ wọn, wọ́n sì wí fún un pé, “Ní àná, ní wákàtí keje ni ibà náà fi í sílẹ̀.”
So he enquired the hour, from them, when he began, to amend. They said, therefore, unto him—Yesterday, at the seventh hour, the fever left him.
53 Bẹ́ẹ̀ ni baba náà mọ̀ pé ní wákàtí kan náà ni, nínú èyí tí Jesu wí fún un pé “Ọmọ rẹ̀ yè.” Òun tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́, àti gbogbo ilé rẹ̀.
So the father took note that it was, in that hour, wherein Jesus said unto him—Thy son, liveth! and he believed, he, and all his house.
54 Èyí ni iṣẹ́ àmì kejì tí Jesu ṣe nígbà tí ó ti Judea jáde wá sí Galili.
Now, this again, as, a second sign, Jesus did, after coming out of Judaea into Galilee.

< John 4 >