< Joel 2 >
1 Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
Zatrobite na šofar na Sionu in razglasite alarm na moji sveti gori. Naj vsi prebivalci dežele trepetajo, kajti dan Gospodov prihaja, kajti ta je blizu, pri roki;
2 Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
dan teme in mračnosti, dan oblakov in goste teme se kot jutro razširjajo nad gorami. Veliko ljudstvo in močno, nikoli ni bilo podobnega niti ga ne bo več za tem, celó do let mnogih rodov.
3 Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
Ogenj požira pred njimi in za njimi gori plamen. Dežela je pred njimi kakor edenski vrt in za njimi zapuščena divjina; da, in nič jim ne bo pobegnilo.
4 Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
Njihov videz je kakor videz konjev in kakor konjeniki, tako bodo tekli.
5 Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
Poskakovali bodo kakor hrup bojnih vozov na vrhovih gora, kakor hrup ognjenega plamena, ki požira strnišče, kakor močno ljudstvo, postavljeno v bojno razvrstitev.
6 Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Pred njihovim obrazom bo ljudstvo močno zaskrbljeno. Vsi obrazi bodo zbirali črnino.
7 Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Tekli bodo kakor mogočni možje, obzidje bodo preplezali kakor bojevniki in korakali bodo vsak po svojih poteh in svojih vrst ne bodo pretrgali.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Niti eden ne bo sunil drugega. Hodili bodo vsak po svoji stezi in ko padejo na meč, ne bodo ranjeni.
9 Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
Tekali bodo sem ter tja po mestu, tekli bodo na obzidje, splezali bodo na hiše, vstopili bodo pri oknih kakor tat.
10 Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Zemlja se bo tresla pred njimi, nebo bo trepetalo, sonce in luna bosta otemnela in zvezde bodo umaknile svoje svetlikanje.
11 Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
Gospod bo izustil svoj glas pred svojo vojsko, kajti njegov tabor je zelo velik, kajti on je močan, ki izvršuje svojo besedo, kajti dan Gospodov je velik in zelo strašen in kdo ga lahko prenese?
12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
»Zato se tudi sedaj, « govori Gospod, »obrnite celó k meni z vsem svojim srcem in s postom in z jokom in z žalovanjem
13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
in pretrgajte svoje srce, ne pa svojih oblačil in obrnite se h Gospodu, svojemu Bogu, kajti on je milostljiv in usmiljen, počasen za jezo in velike prijaznosti in se kesa zla.«
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
Kdo ve, če se bo vrnil in pokesal in pustil blagoslov za seboj, celó jedilno daritev in pitno daritev Gospodu, svojemu Bogu?
15 Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
Zatrobite na šofar na Sionu, posvetite post, skličite slovesen zbor,
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
zberite ljudstvo, posvetite skupnost, zberite starešine, naberite otroke in tiste, ki sesajo pri prsih. Naj pride ženin iz svoje sobe in nevesta iz svoje sobice.
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
Naj duhovniki, Gospodovi služabniki, jokajo med preddverjem in oltarjem in naj govorijo: »Prizanesi svojemu ljudstvu, oh Gospod in svoje dediščine ne izroči v zasmeh, da bi nad njimi vladali pogani. Zakaj bi med ljudstvom rekli: ›Kje je njihov Bog?‹«
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
Potem bo Gospod ljubosumen nad svojo deželo in se usmilil svojega ljudstva.
19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
Da, Gospod bo odgovoril in rekel svojemu ljudstvu: »Glejte, poslal vam bom žito, vino in olje in nasičeni boste s tem in ne bom vas več naredil v zasmeh med pogani,
20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
toda daleč od vas bom odstranil severno vojsko in pregnal jih bom v jalovo in zapuščeno deželo, s svojim obrazom proti vzhodnemu morju in s svojim zadnjim delom proti skrajnemu morju in njegov smrad se bo vzdignil in njegovo zaudarjanje se bo vzdignilo, ker je storil velike stvari.«
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
Ne boj se, oh dežela, bodi vesela in se raduj, kajti Gospod bo storil velike stvari.
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
Ne bodite prestrašene, ve poljske živali, kajti pašniki divjine poganjajo, kajti drevo rodi svoj sad, figovo drevo in trta predajata svojo moč.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
Bodite torej veseli, vi sionski otroci in veselite se v Gospodu, svojem Bogu, kajti dal vam je zmerno prvi dež in povzročil bo, da vam bo prišel dež, prvi dež in pozni dež v prvem mesecu.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
Tla bodo polna pšenice in kadi bodo prekipevale od vina in olja.
25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
»Povrnil vam bom leta, ki jih je požrla leteča kobilica, škodljiva gosenica, gosenica in kosmata gosenica, moja velika vojska, ki sem jo poslal med vas.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
Jedli boste v obilju in boste nasičeni in slavili ime Gospoda, svojega Boga, ki je z vami čudovito ravnal in moje ljudstvo nikoli ne bo osramočeno.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
Vedeli boste, da sem jaz v Izraelovi sredi in da sem jaz Gospod, vaš Bog in nihče drug, in moje ljudstvo nikoli ne bo osramočeno.
28 “Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
Potem se bo zgodilo, da bom svojega duha izlil na vse meso. Vaši sinovi in vaše hčere bodo prerokovali, vaši starci bodo sanjali sanje, vaši mladeniči bodo videli videnja.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
Tudi na služabnike in na pomočnice bom v tistih dneh izlil svojega Duha.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
Pokazal bom čudeže na nebu in na zemlji, kri in ogenj in stebre dima.
31 A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
Sonce se bo spremenilo v temo in luna v kri pred velikim in strašnim dnevom Gospodovega prihoda.«
32 Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.
In zgodilo se bo, da kdorkoli bo klical h Gospodovemu imenu, bo osvobojen, kajti osvoboditev bo na gori Sion in v Jeruzalemu, kakor je rekel Gospod in v ostanku, ki ga bo Gospod poklical.