< Job 4 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
Potem je Elifáz Temánec odgovoril in rekel:
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
» Če se poskušamo posvetovati s teboj, ali boš užaloščen? Toda kdo se lahko vzdrži pred govorjenjem?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Glej, mnoge si poučeval in okrepil si šibke roke.
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
Tvoje besede so podpirale tistega, ki je padal in krepil si slabotna kolena.
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
Toda sedaj je to prišlo nadte in ti slabiš; dotika se te in si zaskrbljen.
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
Mar ni to tvoj strah, tvoje zaupanje, tvoje upanje in poštenost tvojih poti?
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Spomni se, prosim te, kdo se je kdajkoli pogubil, pa je bil nedolžen? Ali kje so bili pravični odsekani?
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Celo kakor sem jaz videl, tisti, ki orjejo krivičnost in sejejo zlobnost, isto [tudi] požanjejo.
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
Z Božjim udarcem umrejo in z dihom njegovih nosnic so použiti.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
Rjovenje leva, glas krutega leva in zobje mladih levov so zlomljeni.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
Star lev gine zaradi pomanjkanja plena, mladiči arogantnega leva pa so razkropljeni naokoli.
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
Torej stvar je bila na skrivnem privedena k meni in moje uho je nekaj tega sprejelo.
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
V mislih od nočnih videnj, ko na človeka pade globoko spanje,
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
je strah prišel nadme in trepetanje, kar je vsem mojim kostem povzročilo, da so se tresle.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
Potem je duh zdrsnil mimo mojega obraza, dlake mojega mesa so se naježile.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
Ta je mirno stal, toda nisem mogel razločiti njegove oblike. Podoba je bila pred mojimi očmi, tam je bila tišina in zaslišal sem glas, rekoč:
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
›Ali bo smrten človek pravičnejši kakor Bog? Ali bo človek čistejši kakor njegov stvarnik?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
Glej, nobenega zaupanja ne polaga v svoje služabnike in njegovi angeli so zadolženi z neumnostjo.
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
Kako veliko manj v tiste, ki prebivajo v ilnatih hišah, katerih temelj je prah, ki so zdrobljene pred moljem?
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
Uničeni so od jutra do večera, pogubljajo se na veke, ne da bi se kdorkoli oziral na to.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’
Mar ni njihova odličnost, ki je v njih, odšla proč? Umirajo, celo brez modrosti.‹«

< Job 4 >